< Jérémie 15 >

1 L’Eternel me dit: "Quand Moïse et Samuel se présenteraient devant moi, mon âme ne se tournerait pas vers ce peuple; renvoie-le hors de ma présence, qu’il s’en aille!
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
2 Que s’ils te demandent: "Où irons-nous?" Tu leur répondras: "Ainsi parle l’Eternel: A la mort ceux qui sont destinés à la mort; au glaive ceux qui appartiennent au glaive; à la famine ceux qu’attend la famine; à la captivité ceux qui sont réservés à la captivité!
Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
3 Je ferai appel contre eux à quatre genres de fléaux, dit l’Eternel, au glaive pour mettre à mort, aux chiens pour déchirer en lambeaux, aux oiseaux du ciel et aux bêtes de la terre, pour dévorer et détruire.
“Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
4 Et je ferai d’eux un objet d’épouvante pour tous les peuples de la terre, à cause de Manassé; fils d’Ezéchias, roi de Juda, et sa façon d’agir à Jérusalem.
N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
5 Qui donc aura pitié de toi, ô Jérusalem, et qui te plaindra? Qui se détournera de son chemin pour t’offrir le salut de paix?
“Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
6 Tu m’as abandonné, dit l’Eternel, tu t’es retirée en arrière! J’Ai, de mon côté, étendu la main sur toi pour te détruire; je suis las d’avoir compassion.
O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
7 Avec un tamis je les ai secoués sur les places publiques du pays; j’ai frappé mon peuple dans ses enfants, je l’ai ruiné: il n’est pas revenu de ses mauvaises voies!
Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
8 Autour de moi, ses veuves sont plus nombreuses que le sable des mers; pour le perdre, j’ai fait fondre sur la mère de jeunes guerriers les ravisseurs en plein midi à l’improviste, j’ai jeté sur elle le trouble et l’effroi.
Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
9 Elle est désespérée, la mère qui a donné le jour à sept fils, elle exhale son âme; dans sa déception et sa confusion, elle voit son soleil se coucher quand il fait encore grand jour; et ceux qui survivent parmi eux, je les livre au glaive sous l’oeil de leurs ennemis": telle est la déclaration de l’Eternel.
Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
10 Malheur à moi, ô ma mère! Pourquoi m’as-tu donné le jour, à moi homme de combat, en lutte avec tout le pays? Je ne suis pas créancier, je ne suis pas débiteur, et tous me maudissent!
Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
11 L’Eternel répondit: "Je fais le serment que ton avenir est marqué pour le bonheur, que je contraindrai l’ennemi, à l’heure de l’adversité et du danger, à se tourner suppliant vers toi.
Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
12 Se peut-il que le fer se brise, le fer venu du nord et l’airain?
“Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
13 Ta richesse et tes trésors, je les livrerai au pillage, sans aucune compensation, à cause de tous tes péchés, dans toutes tes provinces.
“Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
14 Et, avec tes ennemis, je te ferai passer dans un pays que tu ne connais point, car un feu s’est allumé dans ma colère; c’est vous qu’il consumera.
Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
15 Toi, tu me connais, ô Eternel! Souviens-toi de moi, prends-moi sous ta garde. Venge-moi de mes persécuteurs, ne me laisse pas disparaître par l’effet de ta longanimité; reconnais que c’est pour toi que je supporte l’opprobre.
Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
16 Dès que tés paroles me parvenaient, je les dévorais; oui, ta parole était mon délice et la joie de mon coeur, car ton nom est associé au mien, ô Eternel, Dieu-Cebaot.
Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
17 Je ne me surs point assis dans le cercle des railleurs pour me divertir; dominé par ta puissance, j’ai vécu isolé, car tu m’avais gonflé de colère.
Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
18 Pourquoi donc ma souffrance dure-t-elle toujours? Pourquoi ma plaie est-elle si cuisante? Elle ne veut pas se cicatriser. En vérité, tu es à mon égard comme un ruisseau perfide, comme des eaux sur lesquelles on ne peut compter.
Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
19 C’Est pourquoi voici ce que dit l’Eternel: "Si tu reprends ton oeuvre, je te reprendrai, tu auras ta place devant moi; et si tu extrais ce qu’il y a de précieux de ce qui est méprisable, tu me serviras encore d’interprète. C’Est à eux, alors, de revenir à toi, et non à toi de revenir à eux.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
20 Et je t’établirai à l’encontre de ce peuple comme une puissante muraille d’airain; on te combattra, mais on ne pourra te vaincre, car je serai avec toi pour t’assister et te sauver, dit l’Eternel.
Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
21 Je te délivrerai de la main des impies et t’affranchirai du pouvoir des violents."
“Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”

< Jérémie 15 >