< Isaïe 50 >

1 Ainsi parle l’Eternel: "Où est l’acte de divorce de votre mère, par lequel je l’aurais répudiée? Auquel de mes créanciers vous ai-je vendus? Ah! Si vous avez été vendus, c’est à cause de vos fautes; si votre mère a été chassée, c’est à cause de vos péchés.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Níbo ni ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ ìyá rẹ wà èyí tí mo fi lé e lọ? Tàbí èwo nínú àwọn olùyánilówó mi ni mo tà ọ́ fún? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni a fi tà ọ́; nítorí àìṣedéédéé rẹ ni a fi lé ìyá rẹ lọ.
2 Pourquoi suis-je venu et n’ai-je trouvé personne? Pourquoi ai-je appelé et nul n’a répondu? Mon bras est-il trop court pour la délivrance, et ne suis-je pas assez fort pour sauver? Par ma seule menace, je dessèche la mer, je change les fleuves en un sol aride, et les poissons pourrissent par manque d’eau, meurent par la sécheresse.
Nígbà tí mo wá, èéṣe tí a kò fi rí ẹnìkan? Nígbà tí mo pè, èéṣe tí kò fi sí ẹnìkan láti dáhùn? Ọwọ́ mi a kúrú láti gbà ọ́? Èmi kò ha ní agbára láti gbà ọ́ bí? Nípa ìbáwí lásán, Èmi gbẹ omi òkun, Èmi yí àwọn odò sí aṣálẹ̀; àwọn ẹja wọn rà fún àìsí omi wọ́n sì kú fún òǹgbẹ.
3 Je revêts les cieux d’un crêpe et je les drape du sombre cilice.
Èmi fi òkùnkùn bo sánmọ̀ mo sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ ṣe ìbòrí rẹ̀.”
4 Le Seigneur, l’Eternel, m’a doté du langage de ses disciples, pour que je sache relever par la parole les cœurs découragés; il dispose, matin après matin, il dispose mon oreille à écouter comme ses disciples.
Olúwa Olódùmarè ti fún mi ni ahọ́n tí a fi iṣẹ́ rán, láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lè gbé àwọn aláàárẹ̀ ró. O jí mi láràárọ̀, o jí etí mi láti gbọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni tí à ń kọ́.
5 Le Seigneur, l’Eternel, a ouvert mon oreille à sa parole; et moi je n’ai point regimbé, ni reculé d’un pas.
Olúwa Olódùmarè ti ṣí mi ní etí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ṣọ̀tẹ̀ rí; Èmi kò sì padà sẹ́yìn.
6 J’Ai livré mon dos aux coups et mes joues aux violences; je n’ai point dérobé mon visage aux insultes et aux crachats.
Mo ṣí ẹ̀yìn mi sílẹ̀ fún àwọn tí ó ń nà mí, àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irùngbọ̀n mi; Èmi kò fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́yà àti ìyọṣùtì sí.
7 Protégé par le Seigneur, l’Eternel, la honte ne pouvait m’atteindre! C’Est pourquoi, je me suis fait un visage dur comme le roc, je savais que je n’aurais point à rougir.
Nítorí Olúwa Olódùmarè ràn mí lọ́wọ́, a kì yóò dójútì mí. Nítorí náà ni mo ṣe gbé ojú mi ró bí òkúta akọ èmi sì mọ pé, ojú kò ní tì mí.
8 Celui qui défend mon droit est proche, qui osera plaider contre moi? Comparaissons ensemble: qui est ma partie adverse? Qu’elle s’avance contre moi!
Ẹni tí ó dá mi láre wà nítòsí. Ta ni ẹni náà tí yóò fẹ̀sùn kàn mí? Jẹ́ kí a kojú ara wa! Ta ni olùfisùn mi? Jẹ́ kí ó kò mí lójú!
9 Oui, le Seigneur, l’Eternel, est mon soutien, qui osera m’inculper? Certes, ils seront tous comme un vêtement usé, que la mite dévore.
Olúwa Olódùmarè ni ó ń ràn mí lọ́wọ́. Ta ni ẹni náà tí yóò dá mi lẹ́bi? Gbogbo wọn yóò gbó bí aṣọ; kòkòrò ni yóò sì jẹ wọn run.
10 Qui, parmi vous, révère l’Eternel, est attentif à la voix de son serviteur? Dût-il marcher dans les ténèbres, ne voir luire aucune lumière, qu’il se repose sur le nom du Seigneur, qu’il s’abandonne à son Dieu!
Ta ni nínú yín tí ó bẹ̀rù Olúwa tí ó sì ń gbọ́rọ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lẹ́nu? Jẹ́ kí ẹni tí ń rìn ní òkùnkùn tí kò ní ìmọ́lẹ̀, kí ó gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa kí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.
11 Mais vous tous qui attisez la flamme, qui vous armez de torches incendiaires, allez dans le feu de votre propre brasier, sous les torches allumées par vous-mêmes; c’est ma, main qui vous réserve ce sort, vous serez étendus sur une couche de douleurs.
Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gbogbo ẹ̀yin ti ń tanná tí ẹ sì ń fi pèsè iná ìléwọ́ fún ara yín, ẹ lọ, kí ẹ sì máa rìn nínú ìmọ́lẹ̀ iná yín, àti nínú ẹta iná tí ẹ ti dá. Èyí ni yóò jẹ́ tiyín láti ọwọ́ mi wá. Ẹ̀yin ó dùbúlẹ̀ nínú ìrora.

< Isaïe 50 >