< Isaïe 41 >

1 Iles, faites silence pour m’entendre! Que les peuples renouvellent leurs forces, qu’ils approchent et ensuite prennent la parole! Ensemble, nous allons comparaître en justice.
“Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú mi ẹ̀yin erékùṣù! Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè tún agbára wọn ṣe! Jẹ́ kí wọn wá síwájú kí wọn sọ̀rọ̀, jẹ́ kí a pàdé pọ̀ ní ibi ìdájọ́.
2 Qui l’a suscité de l’Orient, celui qui appelle le droit à suivre ses pas? Qui lui livre les nations? Qui lui soumet les rois? Son glaive réduit les choses en poussière, son arc fait de tout une paille qui s’envole.
“Ta ni ó ti ru ẹnìkan sókè láti ìlà-oòrùn wá, tí ó pè é ní olódodo sí iṣẹ́ tirẹ̀? Ó gbé àwọn orílẹ̀-èdè lé e lọ́wọ́ ó sì ṣẹ́gun àwọn ọba níwájú rẹ̀. Ó sọ wọ́n di erùpẹ̀ pẹ̀lú idà rẹ̀, láti kù ú ní ìyàngbò pẹ̀lú ọrun rẹ̀.
3 Il les poursuit, il avance sain et sauf sur une route que ses pieds n’avaient point foulée.
Ó ń lépa wọn ó sì ń kọjá ní àlàáfíà, ní ojú ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò rìn rí.
4 Qui a fait, qui a exécuté tout cela? Celui qui, dès le commencement, appelle les générations à l’être, moi, l’Eternel, qui suis le Premier et demeure encore avec les derniers.
Ta ni ó ti ṣe èyí tí ó sì ti jẹ́ kí ó wáyé, tí ó ti pe ìran-ìran láti àtètèkọ́ṣe? Èmi Olúwa pẹ̀lú ẹni kìn-ín-ní wọn àti ẹni tí ó gbẹ̀yìn, Èmi náà ni.”
5 Les îles le voient et prennent peur, les confins de la terre tremblent. On se rapproche, on accourt.
Àwọn erékùṣù ti rí i wọ́n bẹ̀rù; ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé wárìrì. Wọ́n súnmọ́ tòsí wọ́n sì wá síwájú;
6 L’Un prête assistance à l’autre et chacun dit à son frère: "Courage!"
èkínní ran èkejì lọ́wọ́ ó sì sọ fún arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára!”
7 Le sculpteur encourage l’orfèvre, celui qui polit au marteau réconforte l’ouvrier qui frappe l’enclume et dit de la soudure: "C’Est bien!" Puis on consolide l’idole avec des clous, pour qu’elle ne branle pas.
Oníṣọ̀nà gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjú, àti ẹni tí ó fi òòlù dán mú òun lọ́kàn le, àní ẹni tí ó ń lu owú. Ó sọ nípa àjópọ̀ náà pé, “Ó dára.” Ó fi ìṣó kan ère náà mọ́lẹ̀ kí ó má ba à wó lulẹ̀.
8 Mais toi, Israël, mon serviteur, Jacob, mon élu, postérité d’Abraham qui m’aimait,
“Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ Israẹli, ìránṣẹ́ mi, Jakọbu, ẹni tí mo ti yàn, ẹ̀yin ìran Abrahamu, ọ̀rẹ́ mi,
9 toi que j’ai ramené comme par la main des extrémités de la terre, que j’ai rappelé de ses zones les plus lointaines, toi à qui j’ai dit: "Tu es mon serviteur, je t’ai choisi et je ne te rejette plus,"
mo mú ọ láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé, láti kọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ó jìnnà jùlọ ni mo ti pè ọ́. Èmi wí pé, ‘Ìwọ ni ìránṣẹ́ mi’; Èmi ti yàn ọ́ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì tí ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
10 eh bien! Ne crains rien, car je suis avec toi; ne sois point affolé, car je suis ton Dieu. Je t’affermis, je t’assiste et te soutiens par ma droite, armée de justice.
Nítorí náà má bẹ̀rù, nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; má ṣe jẹ́ kí àyà kí ó fò ọ́, nítorí èmi ni Ọlọ́run rẹ. Èmi yóò fún ọ lókun èmi ó sì ràn ọ́ lọ́wọ́. Èmi ó gbé ọ ró pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi.
11 En vérité, ils connaîtront la honte et la confusion, tous ceux qui sont enflammés contre toi; ils seront réduits à néant, ils périront, tous ceux qui te cherchent querelle.
“Gbogbo àwọn tí ó bínú sí ọ ni ojú yóò tì, tí wọn yóò sì di ẹlẹ́yà; àwọn tó ń bá ọ jà yóò dàbí asán, wọn yóò ṣègbé.
12 Tu les chercheras et tu ne les trouveras plus les gens qui se déclarent tes adversaires; ils seront comme le néant et le vide, les gens qui te font la guerre.
Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yóò wá àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ kì yóò rí wọn. Gbogbo àwọn tí ó gbóguntì ọ́ yóò dàbí ohun tí kò sí.
13 Car moi, l’Eternel, ton Dieu, je soutiens ta droite et je te dis: "Ne crains pas, je viens à ton secours."
Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mú tí ó sì sọ fún ọ pé, má ṣe bẹ̀rù; Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.
14 Ne crains rien, vermisseau de Jacob, faible reste d’Israël! C’Est moi qui te prête secours, dit le Seigneur, le Saint d’Israël est ton libérateur.
Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu kòkòrò, ìwọ Israẹli kékeré, nítorí Èmi fúnra mi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́,” ni Olúwa wí, olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
15 Voici, je fais de toi une herse à dents, toute neuve, et garnie de tranchants: tu fouleras les montagnes à les broyer, et les coteaux, tu les réduiras en menue paille.
“Kíyèsi, Èmi yóò sọ ọ́ di òòlù ìpakà tuntun, tí ó mú ti eyín rẹ̀ mú, ìwọ yóò lu àwọn òkè ńlá, ìwọ yóò fọ́ wọn túútúú, a ó sì sọ òkè kékeré di ìyàngbò.
16 Tu les vanneras et le vent les emportera, la tempête les dispersera, tandis que toi, tu te réjouiras en l’Eternel, tu te glorifieras par le Saint d’Israël.
Ìwọ yóò fẹ́ wọn, afẹ́fẹ́ yóò sì gbá wọn mú, àti ẹ̀fúùfù yóò sì fẹ́ wọn dànù. Ṣùgbọ́n ìwọ yóò yọ̀ nínú Olúwa ìwọ yóò sì ṣògo nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
17 Les affligés et les malheureux réclament de l’eau et n’en trouvent pas; leur langue est desséchée par la soif. Eh bien! Moi, l’Eternel, je les exaucerai; Dieu d’Israël, je ne les abandonnerai pas.
“Àwọn tálákà àti aláìní wá omi, ṣùgbọ́n kò sí; ahọ́n wọn gbẹ fún òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n Èmi Olúwa yóò dá wọn lóhùn; Èmi, Ọlọ́run Israẹli, kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
18 Je ferai sourdre des rivières sur les hauteurs dénudées, des fontaines dans les vallons; du désert je ferai un lac, de la terre aride des sources d’eau jaillissantes.
Èmi yóò mú kí odò kí ó sàn ní ibi gíga àti orísun omi ní àárín àfonífojì. Èmi yóò sọ aṣálẹ̀ di adágún omi, àti ilẹ̀ tí ó gbẹ gidigidi di orísun omi.
19 Dans le désert je ferai croître le cèdre, l’acacia, le myrte et l’olivier, dans la campagne stérile je planterai, avec le cyprès, l’orme et le buis,
Èmi yóò fi sínú aṣálẹ̀ igi kedari àti kasia, maritili àti olifi. Èmi yóò gbin junifa sí inú aginjù, igi firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀
20 pour qu’ils voient et sachent, réfléchissent et comprennent tous ensemble que c’est la main de l’Eternel qui l’a fait, que c’est le Saint d’Israël qui en est l’auteur.
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn yóò fi rí i tí wọn yóò sì fi mọ̀, kí wọn ṣàkíyèsí kí ó sì yé wọn, pé ọwọ́ Olúwa ni ó ti ṣe èyí, àti pé, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ó ti dá èyí.
21 Présentez votre cause, dit l’Eternel, produisez vos arguments, dit le Roi de Jacob.
“Mú ẹjọ́ wá,” ni Olúwa wí. “Tẹ́ àwọn àwíjàre rẹ sílẹ̀,” ni ọba Jakọbu wí,
22 Qu’ils les produisent donc et qu’ils nous exposent ce qui doit arriver! Dites seulement les choses du passé dans leur réalité, pour que nous examinions et en apprenions les suites, ou faites-nous connaître les événements futurs.
“Mú àwọn ère òrìṣà rẹ wọlé láti sọ fún wa ohun tí yóò ṣẹlẹ̀. Sọ fún wa ohun tí àwọn nǹkan àtijọ́ jẹ́, kí àwa lè ṣe àgbéyẹ̀wò wọn kí àwa sì mọ àbájáde wọn ní ìparí. Tàbí kí o sọ fún wa ohun tí ó ń bọ̀ wá,
23 Racontez ce qui va se passer dans l’avenir, pour que nous sachions que vous êtes des dieux; agissez donc en bien ou en mal, et tous nous admirerons en regardant.
ẹ sọ fún wa ohun ti ọjọ́ iwájú mú dání kí àwa kí ó lè mọ̀ pé ọlọ́run ni yín. Ẹ ṣe nǹkan kan, ìbá à ṣe rere tàbí búburú, tó bẹ́ẹ̀ tí àyà yóò fi fò wá tí ẹ̀rù yóò sì fi kún inú wa.
24 Allons! Vous êtes néant, et votre œuvre est néant. Qui s’attache à vous est un objet d’horreur!
Ṣùgbọ́n ẹ̀yìn ko jásí nǹkan kan iṣẹ́ yín ni kò sì wúlò fún ohunkóhun; ẹni tí ó yàn yín jẹ́ ẹni ìríra.
25 Je l’ai suscité du Nord et il est venu; depuis le Levant, il proclame mon nom. II marche sur les princes comme sur de la boue, tel le potier foule l’argile.
“Èmi ti ru ẹnìkan sókè láti àríwá, òun sì ń bọ ẹnìkan láti ìlà-oòrùn tí ó pe orúkọ mi. Òun gun àwọn aláṣẹ mọ́lẹ̀ bí ẹni pé odò ni wọ́n, àfi bí ẹni pé amọ̀kòkò nì ti ń gún amọ̀.
26 Qui a annoncé tout cela dès le premier jour, pour que nous sachions? Dès les temps passés, pour que nous disions: "C’Est juste!" Mais nul ne l’a annoncé, nul ne l’a proclamé, personne n’a même entendu une parole de vous!
Ta ni ó sọ èyí láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, tí àwa kò bá fi mọ̀, tàbí ṣáájú àkókò, tí àwa kò bá fi wí pé, ‘Òun sọ òtítọ́’? Ẹnikẹ́ni kò sọ nípa èyí, ẹnikẹ́ni kò sàsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
27 Moi, le premier, j’ai dit à Sion: "Les voici, les voici!" Et à Jérusalem j’ai envoyé un messager de bonnes nouvelles.
Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Wò ó, àwọn nìyìí!’ Mo fún Jerusalẹmu ní ìránṣẹ́ ìrò ìròyìn ayọ̀ kan.
28 J’Avais regardé pas un homme! Parmi tous ceux-là, pas un conseiller! Comment les consulter pour qu’ils donnent un avis?
Èmi wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan— kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó lè mú ìmọ̀ràn wá, kò sí ẹnìkan tí ó lè dáhùn nígbà tí mo bi wọ́n.
29 Vraiment, tous ils sont mensonge, et vaine est leur œuvre; leurs idoles ne sont que vent et néant.
Kíyèsi i, irọ́ ni gbogbo wọn! Gbogbo ìṣe wọn jásí asán; àwọn ère wọn kò ṣé kò yà fún afẹ́fẹ́ àti dàrúdàpọ̀.

< Isaïe 41 >