< Osée 13 >

1 Quand Ephraïm élevait la voix, on tremblait; il était grand en Israël. Il a prévariqué en adorant Baal, et il a péri.
Nígbà ti Efraimu bá ń sọ̀rọ̀, àwọn ènìyàn máa ń wárìrì, a gbé e ga ní Israẹli ṣùgbọ́n ó jẹ̀bi ẹ̀sùn pé ó ń sin òrìṣà Baali, ó sì kú.
2 Et maintenant, ils redoublent leurs fautes; ils se sont fait des idoles avec leur argent, et avec leur industrie, des images; tout cela c’est œuvre d’artiste. C’Est à elles qu’ils s’adressent; et pour rendre hommage à des veaux, ils immolent des hommes.
Báyìí, wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀; wọn fi fàdákà ṣe ère òrìṣà fúnra wọn; ère tí a fi ọgbọ́n dá àrà sí, gbogbo wọn jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ oníṣọ̀nà. Wọn ń sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Pé, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn tí ń rú ẹbọ fi ẹnu, ko àwọn ẹgbọrọ màlúù ni ẹnu.”
3 Eh bien! ils seront comme la brume du matin et comme la rosée qui se dissipe de bonne heure; comme le fétu tourbillonne hors de l’aire, comme la fumée s’échappe par une lucarne.
Nítorí náà wọn yóò dàbí ìkùùkuu òwúrọ̀, bí ìrì òwúrọ̀ kùtùkùtù tó máa ń parẹ́, bí i èèpo ìyẹ̀fun tí afẹ́fẹ́ gbé láti ibi ìpakà bí èéfín tó rú jáde gba ojú fèrèsé.
4 C’Est pourtant moi, l’Eternel, qui fus ton Dieu dès le pays d’Egypte; tout autre Dieu que moi devait t’être inconnu, et il n’est pas de libérateur en dehors de moi.
“Ṣùgbọ́n Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ẹni tó mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá. Ìwọ̀ kì yóò sì mọ ọlọ́run mìíràn àfi èmi kò sí olùgbàlà mìíràn lẹ́yìn mi.
5 C’Est moi qui ai veillé sur toi dans le désert, sur les plages brûlantes.
Mo ṣe ìtọ́jú rẹ ní aginjù, ní ilẹ̀ tí ó gbẹ tí kò ní omi.
6 Comme ils recevaient la pâture, ils la consommaient; une fois repus, leur cœur s’enfla, et alors ils m’oublièrent.
Wọn ni ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí mo fún wọn ní oúnjẹ, Nígbà tí wọ́n ní ìtẹ́lọ́rùn tan wọ́n di agbéraga. Nígbà náà ni wọ́n sì gbàgbé mi.
7 Aussi suis-je devenu pour eux comme un lion; comme un tigre, je guette au bord du chemin.
Nítorí náà, Èmi yóò dìde sí wọn bí i kìnnìún, Èmi yóò fi ara pamọ́ dè wọ́n lọ́nà bí i ẹkùn.
8 Je fondrai sur eux comme une ourse privée de ses petits, je déchirerai l’enveloppe de leur cœur, et je m’en repaîtrai comme un léopard: les animaux des champs les mettront en pièces.
Beari igbó tí a já ọmọ rẹ̀ gbà, Èmi yóò bá wọn jà bí? Èmi yóò sì fà wọ́n ya bí ìgbà tí ẹkùn bá fa ara wọn ya bi ẹranko búburú ni èmi yóò fa wọn ya.
9 Ce qui t’a perdu, ô Israël, c’est que tu t’es insurgé contre moi, contre ton protecteur.
“A ti pa ọ́ run, ìwọ Israẹli, nítorí pé ìwọ lòdì sí mi, ìwọ lòdì sí olùrànlọ́wọ́ rẹ.
10 Où donc est ton roi? Qu’il te défende contre tant d’ennemis! Où sont tes juges, puisque tu disais "Donne-moi un roi et des chefs!"
Níbo ni ọba rẹ gbé wà nísinsin yìí kí ó bá à le gbà ọ là? Níbo ni àwọn olórí ìlú yín wà, àwọn tí ẹ sọ pé, ‘Fún wa ní ọba àti ọmọ-aládé’?
11 Je te donne un roi dans ma colère, et je le reprends dans mon indignation.
Nítorí èyí nínú ìbínú mi ni mo fún un yín ní ọba, nínú ìbínú gbígbóná mi, mo sì mú un kúrò.
12 Les méfaits d’Ephraïm sont fixés dans mon esprit, ses péchés sont mis en réserve.
Ẹ̀bi Efraimu ni a tí ko jọ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ wà nínú àkọsílẹ̀.
13 Les douleurs d’une femme en travail lui arrivent; enfant qu’il est, il n’a point de raison, autrement il ne resterait pas attaché au siège de l’enfantement.
Ìrora bí obìnrin tó fẹ́ bímọ ti dé bá a, ṣùgbọ́n ó jẹ́ ọmọ tí kò lọ́gbọ́n, nígbà tí àsìkò tó, ó kọ̀ láti jáde síta láti inú.
14 Et je les délivrerais du sépulcre! je les sauverais de la mort! Où sont tes fléaux, ô Mort? Où est ton œuvre de destruction, ô Sépulcre? Que la clémence se dérobe à ma vue! (Sheol h7585)
“Èmi yóò rà wọ́n padà kúrò lọ́wọ́ agbára isà òkú. Èmi yóò rà wọ́n padà lọ́wọ́ ikú, ikú, àjàkálẹ̀-ààrùn rẹ dà? Isà òkú, ìparun rẹ dà? “Èmi kò ní ṣàánú mọ́. (Sheol h7585)
15 Dût-il porter des fruits abondants parmi ses frères, il viendra le vent d’Orient, le vent de l’Eternel, montant du fond du désert, qui tarira sa source et mettra à sec sa fontaine. Il enlèvera ce dépôt de tous les objets précieux.
Bí ó tilẹ̀ gbilẹ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀ afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀dọ̀ Olúwa yóò wá, yóò fẹ́ wá láti inú aginjù orísun omi rẹ̀ yóò gbẹ kànga rẹ̀ yóò gbẹ pẹ̀lú olè yóò fọ́ ilé ẹrù àti gbogbo ilé ìṣúra rẹ̀.
16 Périsse Samarie, puisqu’elle a trahi son Dieu! Ils tomberont sous le glaive, leurs jeunes enfants seront mis en pièces, leurs femmes enceintes éventrées.
Ará Samaria gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn, nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí Ọlọ́run wọn. Wọn ó ti ipa idà ṣubú; a ó fọ́ àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀, a ó sì la àwọn aboyún wọn nínú.”

< Osée 13 >