< Aggée 2 >

1 Le septième mois, le vingt-et-unième jour du mois, la parole de Dieu arriva par l’organe du prophète Haggaï en ces termes:
Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù keje, ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai wí pé,
2 "Adresse donc à Zorobabel, fils de Chaltiël, gouverneur de Judée, à Josué, fils de Joçadak, le grand-prêtre, et au reste du peuple les paroles que voici:
“Sọ fún Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn yòókù. Béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
3 "Est-II encore parmi vous quelqu’un qui ait vu ce temple dans sa splendeur primitive? Et comment le considérez-vous à présent? N’Est-il pas vrai qu’il est comme rien à vos yeux?
‘Ta ni nínú yín tí ó kù tí ó sì ti rí ilé yìí ní ògo rẹ̀ àkọ́kọ́? Báwo ni ó ṣe ri sí yín nísinsin yìí? Ǹjẹ́ kò dàbí asán lójú yín?
4 Toutefois, prends courage, Zorobabel, dit le Seigneur, prends courage, Josué, fils de Joçadak, toi le grand-prêtre, prenez courage, vous les gens de ce pays, dit l’Eternel, et agissez en conséquence, car je suis avec vous, dit l’Eternel-Cebaot.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, múra gírí, ìwọ Serubbabeli,’ ni Olúwa wí. ‘Múra gírí, ìwọ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà. Ẹ sì múra gírí gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ilẹ̀ náà,’ ni Olúwa wí, ‘kí ẹ sì ṣiṣẹ́. Nítorí èmi wà pẹ̀lú yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
5 Aux termes de l’alliance que j’ai contractée avec vous lors de votre sortie de l’Egypte, mon esprit réside au milieu de vous: ne craignez rien!"
‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’
6 "Oui, ainsi parle l’Eternel-Cebaot, encore un court délai, et je mettrai en mouvement le ciel et la terre, la mer et le continent;
“Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
7 je mettrai en mouvement tous les peuples, pour qu’affluent ici les biens les plus précieux de tous ces peuples, et ainsi je remplirai cette maison de splendeur, dit l’Eternel-Cebaot.
Èmi yóò mi gbogbo orílẹ̀-èdè, ìfẹ́ gbogbo orílẹ̀-èdè yóò fà sí tẹmpili yìí, Èmi yóò sì kún ilé yìí pẹ̀lú ògo,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
8 A moi appartient l’argent, à moi l’or, dit l’Eternel-Cebaot.
‘Tèmi ni fàdákà àti wúrà,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
9 Plus grande sera la splendeur de ce second temple que celle du premier, dit l’Eternel-Cebaot, et en ce lieu je ferai régner la paix, dit l’Eternel-Cebaot."
‘Ògo ìkẹyìn ilé yìí yóò pọ̀ ju ti ìṣáájú lọ,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Àti ní ìhín yìí ni Èmi ó sì fi àlàáfíà fún ni,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
10 Le vingt-quatrième jour du neuvième mois, dans la deuxième année de Darius, la parole de Dieu arriva par l’organe du prophète Haggaï en ces termes:
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Hagai wá pé,
11 "Ainsi parle l’Eternel-Cebaot: Interroge donc les prêtres sur le point de doctrine que voici:
“Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà ohun tí òfin wí pé:
12 S’Il arrive que quelqu’un transporte de la chair consacrée dans le pan de son habit, et qu’il mette ce pan de vêtement en contact avec du pain, un légume, du vin, de l’huile ou tout autre comestible, ceux-ci contracteront-ils la sainteté?" Les prêtres répondirent en disant: "Non!"
Bí ẹnìkan bá gbé ẹran mímọ́ ní ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, tí ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀ kan àkàrà tàbí ọbẹ̀, wáìnì, òróró tàbí oúnjẹ mìíràn, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ mímọ́ bí?’” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
13 Haggaï reprit: "Si une personne devenue impure par le contact d’un mort touche ces objets, seront-ils impurs?" Les prêtres répondirent en disant: "Ils seront impurs."
Nígbà náà ni Hagai wí pé, “Bí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífi ara kan òkú bá fi ara kan ọ̀kan lára nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ aláìmọ́?” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, yóò jẹ́ aláìmọ́.”
14 Alors Haggaï prit la parole et dit: "Il en est ainsi de ce peuple: voilà comme il paraît à mes yeux, ce peuple, dit l’Eternel, lui et toutes les œuvres de ses mains. Ce qu’ils me présentent là comme offrande est impur!
Nígbà náà ni Hagai dáhùn ó sì wí pé, “‘Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn wọ̀nyí rí, bẹ́ẹ̀ sì ni orílẹ̀-èdè yìí rí níwájú mi,’ ni Olúwa wí. ‘Bẹ́ẹ̀ sì ni olúkúlùkù iṣẹ́ ọwọ́ wọn; èyí tí wọ́n sì fi rú ẹbọ níbẹ̀ jẹ́ aláìmọ́.
15 Or ça, observez attentivement ce qui va se passer dans la suite, à partir de ce jour; car jusqu’aujourd’hui on n’avait pas posé pierre sur pierre au sanctuaire de l’Eternel.
“‘Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ ro èyí dáradára láti òní yìí lọ, ẹ kíyèsi bí nǹkan ṣe rí tẹ́lẹ̀, a to òkúta kan lé orí èkejì ní tẹmpili Olúwa.
16 Jadis, on se rendait auprès d’un monceau de vingt gerbes, et il n’y en avait que dix; on se rendait auprès d’une cuve de vin dans l’attente d’y puiser cinquante mesures et elles se réduisaient à vingt.
Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi òkìtì òsùwọ̀n ogun, mẹ́wàá péré ni yóò ba níbẹ̀. Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi ìfúntí wáìnì láti wọn àádọ́ta ìwọ̀n, ogún péré ni yóò ba níbẹ̀.
17 Je vous avais éprouvés par la rouille, la nielle et la grêle, s’attaquant à toute l’ouvre de vos mains, mais cela ne vous a pas ramenés à moi, dit l’Eternel.
Mo fi ìrẹ̀dànù, ìmúwòdù àti yìnyín bá gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín jẹ; síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí ọ̀dọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
18 Observez donc avec soin ce qui va se passer, à dater de ce jour et ultérieurement, à dater de ce jour qui est le vingt-quatrième du neuvième mois, jour où ont été jetés les fondements du sanctuaire de l’Eternel. Oui, prenez-le bien à cœur!
‘Láti òní lọ, láti ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán yìí kí ẹ kíyèsi, kí ẹ sì rò ó dáradára, ọjọ́ ti a fi ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa lélẹ̀, rò ó dáradára.
19 Avez-vous encore des grains dans le grenier? N’Est-ce pas que ni vigne, ni figuier, ni grenadier, ni olivier n’ont rien donné? Mais à partir de ce jour je vous comblerai de mes bénédictions."
Ǹjẹ́ èso ha wà nínú abà bí? Títí di àkókò yìí, àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pomegiranate, àti igi olifi kò ì tí ì so èso kankan. “‘Láti òní lọ ni èmi yóò bùkún fún un yin.’”
20 La parole de l’Eternel s’adressa une seconde fois à Haggaï, le vingt-quatrième jour du mois, en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ Hagai wá nígbà kejì, ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù náà pé,
21 "Dis à Zorobabel, gouverneur de Judée, ce qui suit: Je vais faire trembler le ciel et la terre.
“Sọ fún Serubbabeli baálẹ̀ Juda pé èmi yóò mi àwọn ọ̀run àti ayé.
22 Je mettrai sens dessus dessous le trône des royaumes, je détruirai la puissance des empires des nations; je renverserai les chars de guerre et ceux qui y siègent, les coursiers et leurs cavaliers tomberont à terre, frappés les uns par le glaive des autres.
Èmi yóò bi ìtẹ́ àwọn ìjọba ṣubú, Èmi yóò sì pa agbára àwọn aláìkọlà run, Èmi yóò sì dojú àwọn kẹ̀kẹ́ ogun dé, àti àwọn tí ń gùn wọ́n; ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin yóò ṣubú; olúkúlùkù nípa idà arákùnrin rẹ̀.”
23 En ce jour, dit l’Eternel-Cebaot, je te prendrai, ô Zorobabel, fils de Chaltiël, toi mon serviteur, dit l’Eternel, et je te considérerai comma un anneau sigillaire, car c’est toi que j’ai élu, dit l’Eternel-Cebaot."
Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní ọjọ́ náà, ìwọ ìránṣẹ́ mi Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Èmi yóò mú ọ, Èmi yóò sì sọ ọ di bí òrùka èdìdì mi, nítorí mo ti yan ọ, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”

< Aggée 2 >