< Esdras 6 >

1 Alors le roi Darius donna l’ordre de faire des recherches dans le dépôt des livres où l’on mettait les archives, là-bas, en Babylonie,
Nígbà náà ni ọba Dariusi pàṣẹ, wọ́n sì wá inú ilé ìfí nǹkan pamọ́ sí ní ilé ìṣúra ní Babeli.
2 et l’on trouva à Ahmeta, capitale de la province de Médie, un rouleau qui portait la mention suivante:
A rí ìwé kíká kan ní Ekbatana ibi kíkó ìwé sí ní ilé olódi agbègbè Media, wọ̀nyí ni ohun tí a kọ sínú rẹ̀. Ìwé ìrántí.
3 "Dans la première année du roi Cyrus, le roi Cyrus rendit ce décret: Le temple de Dieu à Jérusalem, l’édifice où l’on immole des sacrifices, sera reconstruit, et ses fondements solidement établis; il aura soixante coudées de haut, soixante coudées de large.
Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba ọba Kirusi, ọba pa àṣẹ kan nípa tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu. Jẹ́ kí a tún tẹmpili ibi tí a ti ń rú onírúurú ẹbọ kọ́, kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ ni gíga àti fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ àádọ́rùn-ún ẹsẹ̀ bàtà,
4 Il y aura trois assises de pierres de taille et une assise de bois. La dépense sera couverte par la maison du roi.
pẹ̀lú ipele òkúta ńlá ńlá mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àti ipele pákó kan, kí a san owó rẹ̀ láti inú ilé ìṣúra ọba.
5 En outre, les ustensiles du temple de Dieu, en or et en argent, que Nabuchodonosor a enlevés du sanctuaire de Jérusalem et transportés à Babylone, qu’ils soient restitués pour être remis à leur place dans le sanctuaire de Jérusalem et déposés dans la maison de Dieu."
Sì jẹ́ kí wúrà àti àwọn ohun èlò fàdákà ti ilé Ọlọ́run, tí Nebukadnessari kó láti ilé Olúwa ní Jerusalẹmu tí ó sì kó lọ sí Babeli, di dídápadà sí ààyè wọn nínú tẹmpili ní Jerusalẹmu; kí a kó wọn sí inú ilé Ọlọ́run.
6 "Donc, mandait le roi, vous, Tattenaï, gouverneur des pays de l’autre côté du fleuve, Chetar Bozenaï et consorts, originaires d’Afarsak, résidant de l’autre côté du fleuve, tenez-vous à l’écart.
Nítorí náà, kí ìwọ, Tatenai baálẹ̀ agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ yín, àwọn ìjòyè ti agbègbè náà kúrò níbẹ̀.
7 Laissez se poursuivre les travaux de ce temple; que le gouverneur des Judéens et les anciens parmi eux rebâtissent ce temple sur son emplacement.
Ẹ fi iṣẹ́ ilé Ọlọ́run yìí lọ́rùn sílẹ̀ láì dí i lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ kí baálẹ̀ àwọn Júù àti àwọn àgbàgbà Júù tún ilé Ọlọ́run yín kọ́ sí ipò rẹ̀.
8 J’Ordonne, en outre, que vous preniez des dispositions à l’égard de ces anciens parmi les Judéens, en vue de la reconstruction de ce temple: sur les recettes royales provenant du tribut des pays de l’autre côté du fleuve, il doit être pourvu aux dépenses de ces hommes, ponctuellement et sans aucun retard.
Síwájú sí i, mo pàṣẹ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe fún àwọn àgbàgbà Júù wọ̀nyí lórí kíkọ́ ilé Ọlọ́run yìí. Gbogbo ìnáwó àwọn ọkùnrin yìí ni kí ẹ san lẹ́kùnrẹ́rẹ́ lára ìṣúra ti ọba, láti ibi àkójọpọ̀ owó ìlú ti agbègbè Eufurate kí iṣẹ́ náà má bà dúró.
9 Et ce qui est nécessaire tant en taureaux, béliers, agneaux pour les holocaustes au Dieu du ciel qu’en froment, sel, vin et huile, que tout soit fourni jour par jour aux prêtres de Jérusalem, suivant leurs indications et sans faute,
Ohunkóhun tí wọ́n bá fẹ́—àwọn ọ̀dọ́ akọ màlúù, àwọn àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun sí Ọlọ́run ọ̀run, àti jéró, iyọ̀, wáìnì àti òróró, bí àwọn àlùfáà ní Jerusalẹmu ti béèrè ni ẹ gbọdọ̀ fún wọn lójoojúmọ́ láìyẹ̀.
10 afin qu’ils offrent des sacrifices agréables au Dieu du ciel et prient pour la vie du roi et de ses fils.
Kí wọn lè rú àwọn ẹbọ tí ó tẹ́ Ọlọ́run ọ̀run lọ́rùn kí wọ́n sì gbàdúrà fún àlàáfíà ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀.
11 Je décrète encore que, s’il est quelqu’un qui ose transgresser cet ordre, une poutre soit détachée de sa maison pour l’y pendre haut et court, et que sa maison soit changée en cloaque.
Síwájú sí i, mo pàṣẹ pé tí ẹnikẹ́ni bá yí àṣẹ yìí padà, kí fa igi àjà ilé rẹ̀ yọ jáde, kí a sì gbe dúró, kí a sì fi òun náà kọ́ sí orí rẹ̀ kí ó wo ilé rẹ̀ palẹ̀ a ó sì sọ ọ́ di ààtàn.
12 Que le Dieu qui a choisi ce lieu comme résidence de son nom renverse tout roi et tout peuple qui se permettra de modifier ces instructions au détriment de ce temple de Dieu, à Jérusalem. Moi, Darius, je rends cette ordonnance, qui doit s’exécuter sans retard."
Kí Ọlọ́run, tí ó ti jẹ́ kí orúkọ rẹ̀ máa gbé ibẹ̀, kí ó pa gbogbo ọba àti orílẹ̀-èdè rún tí ó bá gbé ọwọ́ sókè láti yí àṣẹ yìí padà tàbí láti wó tẹmpili yìí tí ó wà ní Jerusalẹmu run. Èmi Dariusi n pàṣẹ rẹ̀, jẹ́ kí ó di mímúṣẹ láìyí ohunkóhun padà.
13 Aussitôt Tattenaï, gouverneur des pays de l’autre côté du fleuve, Chetar Bozenaï et consorts se conformèrent avec diligence aux instructions envoyées par le roi Darius.
Nígbà náà, nítorí àṣẹ tí ọba Dariusi pa, Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate, àti Ṣetar-bosnai pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn pa á mọ́ láìyí ọ̀kan padà.
14 Les anciens parmi les Judéens continuèrent avec succès les travaux de construction, encouragés par les prédications du prophète Haggaï et de Zacharie, fils d’Iddo. Ils bâtirent jusqu’à complet achèvement, par la volonté du Dieu d’Israël et celle de Cyrus, de Darius et d’Artahchasta, roi de Perse.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà Júù tẹ̀síwájú wọ́n sì ń gbèrú sí i lábẹ́ ìwàásù wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, ìran Iddo. Wọ́n parí kíkọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Ọlọ́run Israẹli àti àwọn àṣẹ Kirusi, Dariusi àti Artasasta àwọn ọba Persia pọ̀.
15 Le temple fut terminé le troisième jour du mois d’Adar, dans la sixième année du règne du roi Darius.
A parí ilé Olúwa ní ọjọ́ kẹta, oṣù Addari tí í se oṣù kejì ní ọdún kẹfà ti ìjọba ọba Dariusi.
16 Et les enfants d’Israël, les prêtres, les Lévites, et tous ceux qui étaient revenus de l’exil procédèrent avec allégresse à l’inauguration du temple de Dieu.
Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Israẹli—àwọn àlùfáà, àwọn Lefi àti àwọn ìgbèkùn tí ó padà, ṣe ayẹyẹ yíya ilé Ọlọ́run sí mímọ́ pẹ̀lú ayọ̀.
17 Ils offrirent, pour cette inauguration du temple de Dieu, cent taureaux, deux cents béliers, quatre cents agneaux et douze boucs comme sacrifices expiatoires pour tout Israël, selon le nombre des tribus d’Israël.
Fún yíya ilé Ọlọ́run yìí sí mímọ́, wọ́n pa ọgọ́rùn-ún akọ màlúù, igba àgbò àti irinwó akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, àti gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli, àgbò méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún olúkúlùkù àwọn ẹ̀yà Israẹli.
18 On préposa au service de Dieu à Jérusalem les prêtres d’après leurs divisions, et les Lévites d’après leur classement, conformément aux prescriptions du livre de Moïse.
Wọ́n sì fi àwọn àlùfáà sí àwọn ìpín wọ́n àti àwọn Lefi sì ẹgbẹẹgbẹ́ wọn fún ìsin ti Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí a kọ sínú ìwé Mose.
19 Les anciens exilés célébrèrent la Pâque le quatorzième jour du premier mois;
Ní ọjọ́ kẹrìnlá ti oṣù Nisani, àwọn tí a kó ní ìgbèkùn ṣe ayẹyẹ àjọ ìrékọjá.
20 car les prêtres et les Lévites s’étaient purifiés simultanément, ils étaient tous purs. Ils immolèrent donc le sacrifice pascal pour tous les anciens exilés ainsi que pour leurs frères, les prêtres, et pour eux-mêmes.
Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì jẹ́ mímọ́. Àwọn ará Lefi pa ọ̀dọ́-àgùntàn ti àjọ ìrékọjá fún gbogbo àwọn tí a kó ní ìgbèkùn, fún àwọn àlùfáà arákùnrin wọn àti fún ara wọn.
21 Les enfants d’Israël revenus de l’exil en mangèrent; de même tous ceux qui s’étaient détachés des souillures des autres populations du pays et ralliés à eux, pour rechercher l’Eternel, Dieu d’Israël.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó ti dé láti ìgbèkùn jẹ ẹ́ lápapọ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ti ya ara wọn kúrò nínú gbogbo iṣẹ́ àìmọ́ ti àwọn kèfèrí aládùúgbò wọn láti wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
22 Ils célébrèrent joyeusement la fête des azymes durant sept jours, car l’Eternel leur avait donné de la joie en disposant, en leur faveur, le cœur du roi d’Assyrie, de façon à les seconder dans les travaux du temple de Dieu, du Dieu d’Israël.
Fún ọjọ́ méje, wọ́n ṣe ayẹyẹ àkàrà àìwú pẹ̀lú àjẹtì àkàrà. Nítorí tí Olúwa ti kún wọn pẹ̀lú ayọ̀ nípa yíyí ọkàn ọba Asiria padà, tí ó fi ràn wọ́n lọ́wọ́ lórí iṣẹ́ ilé Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.

< Esdras 6 >