< Esdras 2 >

1 Voici les gens de la province, parmi les captifs exilés que Nabuchodonosor, roi de Babylone, avait déportés à Babylone, qui partirent pour retourner à Jérusalem et en Judée, chacun dans sa ville.
Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
2 Ils revinrent avec Zorobabel, Yêchoua, Nehémia, Seraïa, Reêlaïa, Mardochée, Bilchân, Mispar, Bigvaï, Rehoum et Baana. Ainsi se chiffraient les hommes du peuple d’Israël:
Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
3 les enfants de Paroch: deux mille cent soixante-douze;
Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
4 les enfants de Chefatia: trois cent soixante-douze;
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
5 les enfants d’Arah: sept cent soixante-quinze;
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
6 les enfants de Pahat-Moab, de la famille de Yêchoua et Joab: deux mille huit cent douze;
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
7 les enfants d’Elam: mille deux cents cinquante-quatre;
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
8 les enfants de Zattou: neuf cent quarante-cinq;
Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
9 les enfants de Zaccaï: sept cent soixante;
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
10 les enfants de Bani: six cent quarante-deux;
Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
11 les enfants de Bêbaï: six cent vingt-trois;
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
12 les enfants d’Azgad: mille deux cent vingt-deux;
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
13 les enfants d’Adonikâm: six cent soixante-six;
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
14 les enfants de Bigvaï: deux mille cinquante-six;
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
15 les enfants d’Adîn: quatre cent cinquante-quatre;
Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
16 les enfants d’Atêr de la famille de Yehiskia: quatre-vingt dix-huit;
Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
17 les enfants de Bêçaï: trois cent vingt-trois;
Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
18 les enfants de Yora: cent douze;
Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
19 les enfants de Hachoum: deux cent vingt-trois;
Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
20 les enfants de Ghibbar: quatre-vingt-quinze;
Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
21 les enfants de Bethléem cent vingt-trois;
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
22 les enfants de Netofa: cinquante-six;
Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
23 les enfants d’Anatot: cent vingt-huit;
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
24 les enfants d’Azmaveth quarante-deux;
Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
25 les enfants de Kiriat-Arim, Kefira et Beèrot sept cent quarante-trois;
Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
26 les enfants de Rama et Ghéba: six cent vingt et un;
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
27 les enfants de Mikhmas: cent vingt-deux;
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
28 les enfants de Béthel et Aï: deux cent vingt-trois;
Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
29 les enfants de Nebo: cinquante-deux;
Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
30 les enfants de Magbich cent cinquante-six;
Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
31 les enfants d’un autre Elam: mille deux cent cinquante-quatre;
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
32 les enfants de Harîm: trois cent vingt;
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
33 les enfants de Lod, Hadid et Ono: sept cent vingt-cinq;
Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
34 les enfants de Jéricho: trois cent quarante-cinq;
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
35 les enfants de Senaa: trois mille six cent trente.
Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
36 Les prêtres: les fils de Yedaïa, de la famille de Yêchoua: neuf cent soixante-treize;
Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
37 les enfants d’Immêr: mille cinquante-deux;
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
38 les enfants de Pachhour: mille deux cent quarante-sept;
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
39 les enfants de Harîm: mille dix-sept.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
40 Les Lévites: les enfants de Yêchoua et Kadmiêl, descendants de Hodavia: soixante-quatorze.
Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
41 Les chantres: les fils d’Assaph: cent vingt-huit.
Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
42 Les descendants des portiers: les enfants de Challoum, les enfants d’Atêr, les enfants de Talmôn, les enfants d’Akkoub, les enfants de Hatita, les enfants de Chobaï; ensemble cent trente-neuf.
Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
43 Les serviteurs du temple: les enfants de Ciha, les enfants de Hassoufa, les enfants de Tabaot,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
44 les enfants de Kêrôs, les enfants de Siaha, les enfants de Padôn,
Kerosi, Siaha, Padoni,
45 les enfants de Lebana, les enfants de Hagaba, les enfants d’Akkoub,
Lebana, Hagaba, Akkubu,
46 les enfants de Hagab, les enfants de Samlaï, les enfants de Hanan,
Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
47 les enfants de Ghiddêl, les enfants de Gahar, les enfants de Reaïa,
Giddeli, Gahari, Reaiah,
48 les enfants de Recin, les enfants de Nekoda, les enfants de Gazzâm,
Resini, Nekoda, Gassamu,
49 les enfants d’Ouzza, les enfants de Passêah, les enfants de Bessaï,
Ussa, Pasea, Besai,
50 les enfants d’Asna, les enfants de Meounim, les enfants de Nefoussîm,
Asna, Mehuni, Nefisimu,
51 les enfants de Bakbouk, les enfants de Hakoufa, les enfants de Harhour,
Bakbu, Hakufa, Harhuri.
52 les enfants de Baçlout, les enfants de Mehida, les enfants de Harcha,
Basluti, Mehida, Harṣa,
53 les enfants de Barkôs, les enfants de Sissera, les enfants de Témah,
Barkosi, Sisera, Tema,
54 les enfants de Neciah, les enfants de Hatifa.
Nesia àti Hatifa.
55 Les descendants des esclaves de Salomon: les enfants de Sotaï, les enfants de Hassoféret, les enfants de Perouda:
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
56 les enfants de Yaala, les enfants de Darkôn, les enfants de Ghiddêl;
Jaala, Darkoni, Giddeli,
57 les enfants de Chefatia, les enfants de Hattil, les enfants de Pokhéret-Hacebaïm, les enfants d’Ami.
Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
58 Tous les serviteurs du temple et les descendants des esclaves de Salomon s’élevaient au nombre de trois cent quatre-vingt-douze.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
59 Et voici ceux qui partirent de Têl-Mélah, de Têl-Harcha, Keroub, Addân, Immêr, et qui ne purent indiquer leur famille et leur filiation pour établir qu’ils faisaient partie d’Israël:
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
60 les enfants de Delaïa, les enfants de Tobie, les enfants de Nekoda, au nombre de six cent cinquante-deux.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
61 Et parmi les descendants des prêtres: les enfants de Hobaïa, les enfants de Hakoç, les enfants de Barzillaï, qui avait pris pour femme une des filles de Barzillaï le Galaadite et en avait adopté le nom.
Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
62 Ceux-là recherchèrent leurs tables de généalogie, mais elles ne purent être retrouvées; aussi furent-ils déchus du sacerdoce.
Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
63 Le gouverneur leur défendit de manger des choses éminemment saintes, jusqu’au jour où officierait de nouveau un prêtre portant les Ourim et les Toumim.
Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
64 Toute la communauté réunie comptait quarante-deux mille trois cent soixante individus,
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
65 sans compter leurs esclaves et leurs servantes, au nombre de sept mille trois cent trente-sept, auxquels s’ajoutaient des chanteurs et des chanteuses, au nombre de deux cents.
Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
66 Ils avaient sept cent trente-six chevaux, deux cent quarante-cinq mulets,
Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
67 quatre cent trente-cinq chameaux, six mille sept cent vingt ânes.
ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
68 Un certain nombre des chefs de famille, dès qu’ils arrivèrent près du temple de l’Eternel, qui est à Jérusalem, firent des dons volontaires au temple de Dieu, en vue de le rétablir sur son emplacement.
Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
69 Suivant leurs moyens, ils versèrent à la caisse des travaux: en or, soixante et un mille dariques, et en argent, cinq mille mines, ainsi que cent tuniques de prêtres.
Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
70 Les prêtres et les Lévites ainsi que ceux du peuple, les chantres, les portiers, les esclaves du temple s’établirent dans leurs villes respectives; et tout Israël s’installa dans ses villes.
Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.

< Esdras 2 >