< Ézéchiel 44 >

1 Puis, il me ramena du côté de la porte extérieure du Sanctuaire, qui est tournée vers l’Est; mais elle était fermée.
Lẹ́yìn náà ni ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí ibi mímọ́, èyí tí ó kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, ó sì wà ní títì.
2 Et l’Eternel me dit: "Cette porte restera fermée, on ne l’ouvrira point, et personne n’entrera par elle, car l’Eternel Dieu d’Israël, est entré par elle: elle restera donc fermée.
Olúwa sọ fún mi, “Ẹnu-ọ̀nà yìí ni kí ó wà ní títì. A kò gbọdọ̀ ṣí i sílẹ̀; kò sí ẹni tí o gbọdọ̀ gba ibẹ̀ wọlé. Ó gbọdọ̀ wà ní títì nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí gbà ibẹ̀ wọlé.
3 C’Est le prince, en sa qualité de prince, qui s’y asseoira pour manger le pain devant l’Eternel; c’est par la voie du vestibule de la porte qu’il entrera et par cette voie qu’il sortira."
Ọmọ-aládé fúnra rẹ̀ ní o lè jókòó ní ẹnu-ọ̀nà náà kí o sì jẹun níwájú Olúwa. Ó gbọdọ̀ gba ọ̀nà ìloro ẹnu-ọ̀nà wọlé kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.”
4 Puis, il me conduisit par la porte du Nord jusqu’au front de l’édifice, et je vis soudain la gloire de l’Eternel remplir le temple de l’Eternel, et je tombai sur ma face.
Lẹ́yìn náà, ọkùnrin náà mú mi gba ẹnu-ọ̀nà àríwá lọ sí iwájú ilé Ọlọ́run. Mo wò ó mo sì rí ògo Olúwa tí ó kún inú ilé Olúwa, mo sì dojúkọ ilẹ̀.
5 L’Eternel me dit: "Fils de l’homme, applique ton attention, vois de tes yeux, et écoute de tes oreilles tout ce que je vais te dire touchant les ordonnances de la maison de l’Eternel et toutes ses lois; dirige ton attention sur l’accès de l’édifice ainsi que sur toutes les issues du Sanctuaire.
Olúwa sì sọ fún mì pé, “Ọmọ ènìyàn, wò dáradára, fetísílẹ̀ dáradára kí o sì fiyèsí ohun gbogbo tí mo sọ fún ọ nípa òfin lórí ilé Olúwa náà. Fiyèsí ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run náà àti gbogbo àbájáde ibi mímọ́.
6 Et tu diras à la rébellion, à la maison d’Israël: Ainsi parle le Seigneur Dieu: C’En est assez de toutes vos turpitudes, maison d’Israël!
Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwà ìríra rẹ tí tó gẹ́ẹ́, ìwọ ilé Israẹli!
7 Car vous avez introduit des enfants de l’étranger, incirconcis de coeur et incirconcis de chair, dans mon sanctuaire, pour profaner ma maison, quand vous me présentiez mon pain, graisse et sang et portiez atteinte à mon alliance à côté de toutes vos autres turpitudes.
Ní àfikún pẹ̀lú gbogbo àwọn ìwà ìríra rẹ tí ó kù, ìwọ mú àwọn àjèjì aláìkọlà àyà àti ara wá sí inú ibi mímọ́ mi, ní lílo ilé mi ní ìlòkulò nígbà tí ìwọ fi oúnjẹ fún mi, ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ìwọ sì ba májẹ̀mú mi jẹ́.
8 Et vous n’avez pas veillé à la garde de mes choses saintes, mais vous les avez chargés, eux, d’assurer le service de mon sanctuaire à votre intention."
Dípò kí ìwọ pa òfin mi mọ́, ìwọ fi àwọn mìíràn sí ibi mímọ́ mi.
9 Ainsi parle le Seigneur Dieu: "Aucun fils d’étranger, incirconcis de coeur et incirconcis de chair, n’entrera dans mon sanctuaire, aucun fils d’étranger se trouvant parmi les enfants d’Israël.
Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Àjèjì aláìkọlà àyà àti ara kò gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi, àti pẹ̀lú àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli.
10 Mais les Lévites eux-mêmes, qui s’étaient éloignés de moi quand Israël faisait fausse route, qui m’avaient abandonné pour suivre leurs idoles, ils porteront la peine de leur faute.
“‘Àwọn Lefi tí wọn rìn jìnnà kúrò lọ́dọ̀ mi nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ṣìnà, ti wọ́n sì ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi láti tọ àwọn ère wọn lẹ́yìn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
11 Ils seront dans mon sanctuaire des serviteurs, des surveillants préposés aux portes de l’édifice, et feront la corvée de la maison; ce sont eux qui immoleront l’holocauste et les sacrifices pour le peuple et qui se tiendront devant eux pour les servir.
Wọn le sìn mi ní ibi mímọ́ mi, kí wọn ṣe ìtọ́jú àwọn ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run, kí wọn sì ṣe ìránṣẹ́ nínú rẹ̀; wọn le pa ẹbọ sísun, ki wọn sì rú ẹbọ fún àwọn ènìyàn, kí wọn sì dúró níwájú àwọn ènìyàn, kí wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
12 Parce qu’ils les ont servis devant leurs idoles et ont été pour la maison d’Israël une cause de péché, c’est pourquoi j’ai levé ma main contre eux, dit le Seigneur Dieu, et ils porteront la peine de leur faute.
Ṣùgbọ́n nítorí pé wọn ṣe ìránṣẹ́ fún wọn níwájú àwọn ère wọn, tí wọn sì mu ilé Israẹli ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀, nítorí náà, Èmi tí búra nípa nína ọwọ́ sókè pé, wọn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.
13 Ils ne s’approcheront pas de moi pour exercer mon sacerdoce, ils ne s’approcheront d’aucune de mes saintetés, des objets tout à fait saints: ainsi ils porteront leur opprobre et la peine de leurs abominations, qu’ils ont commises.
Wọn kò gbọdọ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi láti ṣe ìránṣẹ́ fún mi, gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí súnmọ́ nǹkan kan nínú àwọn ohun mímọ́ mi tàbí ẹbọ mi mímọ́ jùlọ; wọn gbọdọ̀ gba ìtìjú ìwà ìríra wọn.
14 Je ferai d’eux des préposés à la surveillance de la maison, en ce qui en concerne la corvée et tout ce qui s’y fait.
Síbẹ̀ èmi yóò mu wọn sí ìtọ́jú ilé Ọlọ́run àti gbogbo iṣẹ́ tí a gbọdọ̀ ṣe níbẹ̀.
15 Quant aux pontifes Lévites, descendants de Çadok, qui ont veillé à la garde de mon sanctuaire, tandis que les enfants d’Israël s’égaraient loin de moi, ce sont eux qui s’approcheront de moi pour me servir et se tiendront en ma présence pour m’offrir la graisse et le sang, dit le Seigneur Dieu.
“‘Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi àti àwọn ìran Sadoku tí fi tọkàntọkàn ṣe iṣẹ́ ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn Israẹli ṣáko lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn gbọdọ̀ súnmọ́ iwájú láti ṣe ìránṣẹ́ ní iwájú mi, láti rú ẹbọ ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
16 Ce sont eux qui auront accès dans mon sanctuaire, eux qui s’approcheront de ma table pour me servir et veilleront à mon observance.
Àwọn nìkan ni ó gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi; àwọn nìkan ní o gbọdọ̀ súnmọ́ tábìlì mi láti ṣe ìránṣẹ́ ni iwájú mi, ki wọn sì ṣe iṣẹ́ ìsìn mi.
17 Lorsqu’ils franchiront les portes du parvis intérieur, ils se vêtiront d’habillements de lin; ils ne porteront pas de laine pendant qu’ils fonctionneront aux portes du parvis intérieur et dans le temple.
“‘Nígbà ti wọ́n wọ àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú, wọn yóò wọ ẹ̀wù ọ̀gbọ̀, wọn kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú tàbí ni inú ilé Ọlọ́run.
18 Des turbans de lin entoureront leur tête, des caleçons de lin leurs reins: ils ne se ceindront d’aucune étoffe échauffante.
Wọ́n yóò sì dé fìlà ọ̀gbọ̀ sí orí wọn àti ṣòkòtò ọ̀gbọ̀ sí ìdí wọn. Wọn kò sì gbọdọ̀ wọ ohunkóhun tí yóò mú wọn làágùn.
19 Et quand ils passeront dans le parvis extérieur, dans le parvis extérieur où se tient le peuple, ils ôteront les vêtements dans lesquels ils fonctionnent, les déposeront dans les salles consacrées et en mettront d’autres, pour ne pas sanctifier le peuple par leurs vêtements.
Nígbà tí wọ́n bá lọ sì àgbàlá òde níbi tí àwọn ènìyàn wà, wọn gbọdọ̀ bọ́ ẹ̀wù tí wọ́n fi ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́, ki wọn sì fi wọn sílẹ̀ sí àwọn yàrá mímọ́ náà, kí wọn kí ó sì wọ ẹ̀wù mìíràn, wọn kì yóò sì fi ẹ̀wù wọn sọ àwọn ènìyàn di mímọ́.
20 Ils ne devront ni raser leur chevelure, ni la laisser croître inculte, ils devront la tailler.
“‘Wọn kò gbọdọ̀ fá irun, wọn kò sì gbọdọ̀ jẹ́ kí irun wọn gùn, ṣùgbọ́n wọn gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí wọn wà ní gígẹ̀.
21 Le vin, aucun prêtre n’en boira, quand il aura à pénétrer au parvis intérieur.
Àlùfáà kankan kò gbọdọ̀ mu ọtí nígbà tí ó bá wọ àgbàlá tí inú.
22 Ils ne prendront pour épouse ni veuve ni femme répudiée; ils n’épouseront que des vierges issues de la maison d’Israël, ou une veuve, si c’est la veuve d’un pontife.
Wọn ko gbọdọ̀ fẹ́ opó ni ìyàwó, wọn kò sì gbọdọ̀ kọ ìyàwó wọn sílẹ̀, wọ́n lè fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ti kò tí i mọ ọkùnrin rí, tí ó sì jẹ́ ìran àwọn ọmọ Israẹli, tàbí kí wọn fẹ́ àwọn opó àlùfáà.
23 Ils enseigneront à mon peuple à discerner le sacré du profane, ils lui feront connaître la distinction de l’impur et du pur.
Wọn yóò sì fi ìyàtọ̀ tí ó wà láàrín mímọ́ àti àìmọ́ kọ́ àwọn ènìyàn mi, wọn yóò sì fihàn wọ́n bi wọn yóò ṣe dá aláìmọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí mímọ́.
24 Dans les litiges, ce sont eux qui exerceront la justice, et ils prononceront d’après mes lois; ils observeront mes doctrines et mes statuts pour toutes mes solennités et ils sanctifieront mes sabbats.
“‘Nínú èyíkéyìí èdè-àìyedè, àwọn àlùfáà ní yóò dúró gẹ́gẹ́ bí onídàájọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin mi. Wọ́n ní láti pa àwọn òfin àti àṣẹ mi mọ́ ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn, wọn sì gbọdọ̀ ya ọjọ́ ìsinmi mi ní mímọ́.
25 Ils ne s’approcheront pas d’un cadavre humain, qui les souillerait; c’est seulement pour un père ou une mère, un fils ou une fille, un frère ou une sœur non mariée qu’ils pourront se souiller.
“‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nípa sísún mọ́ òkú ènìyàn; ṣùgbọ́n ti òkú ènìyàn yẹn bá jẹ́ baba tàbí ìyá rẹ̀, àbúrò rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin ti kò i ti lọ́kọ, nígbà náà o le sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
26 Après sa purification, l’on comptera au pontife sept jours.
Lẹ́yìn ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, ki òun kí ó dúró fún ọjọ́ méje.
27 Et le jour où il entrera au saint lieu, dans le parvis intérieur, pour le ministère sacré, il offrira son expiatoire, dit le Seigneur Dieu.
Ní ọjọ́ ti yóò wọ àgbàlá ti inú ni ibi mímọ́ láti ṣe ìránṣẹ́ ibi mímọ́, ni kí òun kí ó rú ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
28 Quant à ce qui doit être leur héritage, c’est moi qui serai leur héritage; de possession, vous ne leur en donnerez point en Israël: moi, je serai leur possession.
“‘Èmi ni yóò jẹ́ ogún kan ṣoṣo tí àwọn àlùfáà yóò ní. Ẹ kì yóò fún wọn ni ìpín kankan ní Israẹli, Èmi ni yóò jẹ́ ìní wọn.
29 L’Oblation, l’expiatoire et le délictif, eux seuls pourront les consommer; toute chose vouée en Israël leur appartiendra.
Wọn yóò jẹ ọrẹ ẹbọ jíjẹ, ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ ìrékọjá; gbogbo ohun tí a bá yà sọ́tọ̀ fún Olúwa ni Israẹli ni yóò jẹ́ tiwọn.
30 Les prémices de toute primeur quelle qu’elle soit, tout prélèvement quelconque que vous aurez à faire, appartiendront aux pontifes; de même la première part de vos pâtes, vous la donnerez au pontife, pour que la bénédiction repose sur votre maison.
Èyí tí ó dára jùlọ nínú gbogbo àkọ́so èso àti ọrẹ yín yóò jẹ́ ti àwọn àlùfáà. Ẹ ó sì fi àkọ́pò ìyẹ̀fun yín fún wọn kí ìbùkún lè wà lórí gbogbo ilé yín.
31 D’Aucun animal mort ou déchiré, soit volatile, soit quadrupède, les pontifes ne pourront manger.
Àwọn àlùfáà kì yóò jẹ́ ohunkóhun bí i ẹyẹ tàbí ẹranko, tí ó ti kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí ti ẹranko ńlá fàya.

< Ézéchiel 44 >