< Ézéchiel 32 >

1 Il advint, dans la douzième année, le premier jour du douzième mois, que la parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kejìlá, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 "Fils de l’homme, entonne une complainte sur Pharaon, roi d’Egypte, et dis-lui: Lion des nations, tu es perdu! Et pourtant tu étais comme le crocodile dans les mers, tu t’élançais avec tes fleuves, tu troublais les eaux de tes pieds et tu en agitais les flots."
“Ọmọ ènìyàn, ṣe ìpohùnréré ẹkún nítorí Farao ọba Ejibiti kí o sì wí fún un: “‘Ìwọ dàbí kìnnìún láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà; ìwọ dàbí ohun ẹ̀mí búburú inú àwọn omi okun to ń lọ káàkiri inú àwọn odò rẹ, ìwọ fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ omi láti mú kí àwọn odò ní ẹrẹ̀.
3 Ainsi parle le Seigneur Dieu: "J’Étendrai sur toi mon filet avec le concours de peuples nombreux qui te haleront dans ma nasse.
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ìpéjọ ènìyàn èmi yóò da àwọ̀n mi bò ọ́ wọn yóò sì fà ọ́ sókè nínú àwọ̀n mi.
4 Et je te laisserai là sur le sol, je te lancerai sur la surface des champs, je ferai s’abattre sur toi tous les oiseaux du ciel et je rassasierai de toi toutes les bêtes de la terre.
Èmi yóò jù ọ́ sí orí ilẹ̀ èmi yóò sì fà ọ́ sókè sí orí pápá gbangba. Èmi yóò jẹ́ kí gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ní orí rẹ. Gbogbo àwọn ẹranko ayé yóò fi ìwọra gbé ara wọn lórí rẹ.
5 J’Exposerai ta chair sur les montagnes, et je remplirai les vallées de ton cadavre.
Èmi yóò tan ẹran-ara rẹ ká sórí àwọn òkè gíga ìyókù ara rẹ ní wọn yóò fi kún àwọn àárín àwọn òkè gíga.
6 Le pays de tes ébats, je l’arroserai de ton sang jusqu’aux montagnes, et les ravins seront pleins de toi.
Ẹ̀jẹ̀ rẹ ti ń sàn ní èmi yóò sì fi rin ilẹ̀ náà gbogbo ọ̀nà sí orí àwọn òkè gíga, àwọn àlàfo jíjìn ní wọn yóò kún fún ẹran-ara rẹ.
7 Par suite de ton extinction, je voilerai les cieux et j’assombrirai leurs étoiles; le soleil, je le couvrirai de nuées et la lune ne fera plus briller son éclat.
Nígbà tí mo bá fọ́n ọ jáde, èmi yóò pa ọ̀run dé àwọn ìràwọ̀ wọn yóò sì ṣókùnkùn; èmi yóò sì fi ìkùùkuu bo oòrùn òṣùpá kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
8 Tous les flambeaux lumineux au ciel, je les obscurcirai à cause de toi et je répandrai les ténèbres sur ton pays, dit le Seigneur Dieu.
Gbogbo ìmọ́lẹ̀ títàn ní ojú ọ̀run ni èmi yóò mú ṣókùnkùn lórí rẹ; èmi yóò mú òkùnkùn wá sórí ilẹ̀ rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Je contristerai le coeur de peuples nombreux, quand je ferai parvenir l’annonce de ta ruine parmi les nations, dans des pays que tu ne connais point.
Èmi yóò da ọkàn ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn rú nígbà tí mo bá mú ìparun rẹ wá ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò í tí ì mọ̀.
10 A cause de toi, je frapperai de stupeur quantité de peuples: à cause de toi, leurs rois seront saisis d’horreur, quand je ferai voltiger mon glaive devant leur face. Ils trembleront à tout instant, chacun pour sa personne, au jour de ta chute."
Èmi yóò mú kí ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn dẹ́rùbà ọ́, àwọn ọba wọn yóò sì wárìrì fún ìbẹ̀rù pẹ̀lú ìpayà nítorí rẹ, nígbà tí mo bá ju idà mi ní iwájú wọn. Ní ọjọ́ ìṣubú rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú wọn yóò wárìrì ní gbogbo ìgbà fún ẹ̀mí rẹ.
11 Car ainsi parle le Seigneur Dieu: "Le glaive du roi de Babylone fondra sur toi.
“‘Nítorí èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Idà ọba Babeli yóò wá sí orí rẹ,
12 Sous les glaives des vaillants guerriers, tous gens terribles entre les nations, je ferai tomber ta multitude; ils ruineront l’orgueil de l’Egypte, et toute sa multitude périra.
Èmi yóò mú kí ìjọ ènìyàn rẹ kí ó tí ipa idà àwọn alágbára ènìyàn ṣubú àwọn orílẹ̀-èdè aláìláàánú jùlọ. Wọn yóò tú ìgbéraga Ejibiti ká, gbogbo ìjọ rẹ ní a yóò dá ojú wọn bolẹ̀.
13 J’Anéantirai tout son bétail auprès des grandes eaux, et celles-ci ne seront plus troublées par le pied de l’homme, elles ne seront plus troublées par les sabots des animaux.
Gbogbo ẹran ọ̀sìn rẹ ni èmi yóò parun ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kì i ṣe ẹsẹ̀ ènìyàn ní yóò tẹ ibẹ̀ ẹsẹ̀ ẹran ọ̀sìn kì yóò sì mú kí ibẹ̀ ni ẹrọ̀fọ̀.
14 Alors, je ferai rasseoir leurs flots, et les fleuves, je les ferai couler comme l’huile, dit le Seigneur Dieu.
Lẹ́yìn náà èmi yóò mú kí omi rẹ̀ tòrò kí àwọn odò rẹ̀ kí o sàn bí epo, ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 Quand je réduirai la terre d’Egypte en ruines, et que le pays sera dépouillé de ce qu’il contient, quand je frapperai tous ceux qui l’habitent, on saura que c’est moi l’Eternel.
Nígbà tí mo bá sọ Ejibiti di ahoro, tí mo sì kó gbogbo ohun tí ó wà ní orí ilẹ̀ náà kúrò. Nígbà tí mo bá gé àwọn olùgbé ibẹ̀ lulẹ̀, nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
16 C’Est là la complainte que l’on chantera, que chanteront les filles des nations. Elles la chanteront sur l’Egypte et sur toute sa multitude, dit le Seigneur Dieu."
“Èyí yìí ni ẹkún tí a yóò sun fún un. Àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè yóò sun ún; nítorí Ejibiti àti gbogbo ìjọ rẹ, wọn yóò sun ún, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
17 Il advint, dans la douzième année, le quinze du mois, que la parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mí wá:
18 "Fils de l’homme, consacre une lamentation à la multitude de l’Egypte et précipite-la, elle et les filles de nations puissantes, dans les régions souterraines avec ceux qui descendent dans la fosse.
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún lórí Ejibiti kí o sì ránṣẹ́ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ àti òun àti àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè alágbára, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ìsàlẹ̀, kòtò.
19 Qui dépasses-tu en agrément? Descends! Couche-toi avec des incirconcis!
Sọ fún wọn, ‘Ǹjẹ́ ìwọ ní ojúrere jù àwọn tí o kù lọ? Lọ sí ìsàlẹ̀ kí a sì tẹ́ ọ sí àárín àwọn aláìkọlà náà.’
20 Ils tombent parmi les victimes du glaive; au glaive elle est livrée; entraînez-la avec toutes ses multitudes!
Wọn yóò ṣubú láàrín àwọn tí a fi idà pa. A fa idà yọ; jẹ́ kí a wọ́ Ejibiti kúrò pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀.
21 Les puissants guerriers, du fond du Scheol, l’interpellent avec ses alliés: "Ils sont descendus disent-ils, ils se sont couchés les incirconcis, victimes du glaive!" (Sheol h7585)
Láti inú isà òkú alágbára tí í ṣe aṣáájú yóò sọ nípa Ejibiti àti àwọn àlejò rẹ̀, ‘Wọn ti wá sí ìsàlẹ̀, wọn sì sùn pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.’ (Sheol h7585)
22 Là est Achour avec toute sa troupe: autour de lui sont ses tombeaux; ce sont tous des victimes tombées sous le glaive,
“Asiria wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo jagunjagun rẹ̀; àwọn isà òkú àwọn tí a ti pa sì yí i ká, gbogbo àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú.
23 dont les sépulcres ont été placés au fond de la fosse, et la troupe rangée autour de son tombeau; ce sont tous des victimes tombées sous le glaive, eux qui avaient porté la terreur au pays des vivants.
Isà òkú wọn wà ní ibi tí ó jinlẹ̀ gan an nínú kòtò. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè ní a pa, tí ó ti ipa idà ṣubú.
24 Là est Elam avec toute sa multitude à l’entour de son sépulcre; ce sont tous des victimes tombées sous le glaive; ils sont descendus incirconcis dans les profondeurs souterraines, eux qui avaient porté la terreur au pays des vivants; ils subissent leur opprobre avec ceux qui sont descendus dans la fosse.
“Elamu wà níbẹ̀, o yí isà òkú rẹ̀ ká pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀. Gbogbo wọn ni a pa, àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè lọ sí ìsàlẹ̀ láìkọlà sí abẹ́ ilẹ̀. Wọ́n gba ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
25 Au milieu des cadavres, on lui a donné une couche, avec toute sa multitude dans des tombes tout autour; ce sont tous des incirconcis, victimes du glaive, car leur terreur s’est répandue dans le pays des vivants; ils subissent leur opprobre avec ceux qui sont descendus dans la fosse; au milieu des cadavres, elle a été placée.
A ṣe ibùsùn fún un láàrín àwọn tí a pa, pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀ tí ó yí isà òkú ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, tí a fi idà pa. Nítorí pé a tan ẹ̀rù wọn ká ilẹ̀ alààyè, wọn ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò; a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a pa.
26 Là est Méchec, là est Toubal et toute sa multitude; autour de lui ses tombeaux. Ce sont tous des incirconcis, victimes du glaive, car ils ont porté leur terreur au pays des vivants.
“Meṣeki àti Tubali wà níbẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ogun wọn yí isà òkú wọn ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, wọ́n fi idà pa wọ́n nítorí ẹ̀rù tiwọn tàn ká ilẹ̀ alààyè.
27 Mais ils ne reposent pas avec les héros qui sont tombés parmi les incirconcis, qui sont descendus au tombeau avec leur attirail de guerre, à qui on a mis leurs glaives sous la tête; leurs crimes sont restés sur leurs ossements, car la terreur des héros a été au pays des vivants. (Sheol h7585)
Wọn kì yóò sì dùbúlẹ̀ ti àwọn tí ó ṣubú nínú àwọn aláìkọlà, tí wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun wọn, wọ́n tí fi idà wọn rọ orí wọn. Ṣùgbọ́n àìṣedéédéé wọn yóò wà ní orí egungun wọn—bí wọ́n tilẹ̀ jẹ́ ẹ̀rù àwọn alágbára ní ilẹ̀ alààyè. (Sheol h7585)
28 Et toi, au milieu des incirconcis tu seras brisé, et tu te coucheras avec les victimes du glaive.
“Ìwọ náà, Farao, ní yóò ṣẹ, ti yóò dùbúlẹ̀ láàrín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.
29 Là est Edom, avec ses rois et tous ses princes qui ont été mis, en dépit de leur force, avec les victimes du glaive; ceux-là reposent avec les incirconcis et ceux qui sont descendus dans la fosse.
“Edomu wà níbẹ̀, àwọn ọba rẹ̀ àti gbogbo ọmọbìnrin ọba; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ní agbára, a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. Wọn dùbúlẹ̀ pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn ti o lọ sínú kòtò.
30 Là sont les princes du Nord au complet et tous les Sidoniens qui sont descendus avec les corps morts, confondus malgré la terreur que leur vigueur inspirait; ils se sont couchés, incirconcis, avec les victimes du glaive, et ils ont porté leur opprobre avec ceux qui sont descendus dans la fosse.
“Gbogbo àwọn ọmọ-aládé ilẹ̀ àríwá àti gbogbo àwọn ará Sidoni wà níbẹ̀; wọn lọ sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí a pa ní ìtìjú, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ṣe okùnfà ẹ̀rù pẹ̀lú agbára wọn. Wọn sùn ní àìkọlà pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa, wọn sì ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
31 Pharaon les verra et se consolera au sujet de toute sa multitude; ils seront victimes du glaive, Pharaon et toute son armée, dit le Seigneur Dieu.
“Farao, òun àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ yóò rí wọn, a yóò sì tù ú nínú nítorí gbogbo ogun rẹ̀ tí a fi idà pa, ní Olúwa Olódùmarè wí.
32 Car j’ai répandu ma terreur au pays des vivants; et il sera couché parmi les incirconcis, avec les victimes du glaive, Pharaon et toute sa multitude, dit le Seigneur Dieu."
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè, Farao àti gbogbo ogun rẹ̀ ni a yóò tẹ́ sí àárín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ézéchiel 32 >