< Ézéchiel 23 >
1 La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 "Fils de l’homme, il y avait deux femmes, filles d’une même mère.
“Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
3 Elles se prostituèrent en Egypte, dans leur jeunesse elles s’y prostituèrent; là furent pressées leurs mamelles, là on étreignit leur sein virginal.
Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
4 Elles s’appelaient, l’aînée, Ohola, et sa sœur, Oholiba; elles m’appartinrent et enfantèrent des fils et des filles: leurs noms, c’étaient Samarie pour Ohola et Jérusalem pour Oholiba.
Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
5 Ohola se débaucha, alors qu’elle était en ma puissance; elle s’engoua de ceux qui la courtisaient, des Assyriens qui l’approchaient,
“Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
6 gens habillés d’azur, gouverneurs et seigneurs, tous jouvenceaux séduisants, cavaliers montant des chevaux.
Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
7 Elle leur prodigua ses faveurs impures, à tous ces fils distingués d’Achour, et à cause de tous ceux dont elle était éprise elle se souilla par leurs idoles.
O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
8 Pourtant elle ne renonça point à ses dérèglements datant de l’Egypte; car ils avaient eu commerce avec elle dans sa jeunesse, ils avaient étreint son sein virginal et répandu leur impudicité sur elle.
kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
9 C’Est pourquoi je l’ai livrée entre les mains de ses amants, entre les mains des fils d’Achour, dont elle s’était éprise.
“Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
10 Ceux-ci découvrirent sa nudité, prirent ses fils et ses filles, et elle-même, ils la firent périr par l’épée. Elle devint un exemple mémorable pour les femmes, et on lui infligea de justes châtiments.
Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
11 Or, sa soeur Oholiba en avait été témoin; et elle s’adonna à des amours encore plus coupables, à un dévergondage pire que celui de sa soeur.
“Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
12 Elle s’éprit des fils d’Achour, des gouverneurs et seigneurs qui l’approchaient, vêtus magnifiquement, cavaliers montant des chevaux, tous jouvenceaux séduisants.
Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
13 Je constatai qu’elle s’était souillée: même conduite chez toutes deux.
Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
14 Elle enchérit sur son inconduite, quand elle vit des hommes dessinés sur la muraille, des images de Chaldéens peintes en vermillon,
“Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
15 portant des ceintures attachées aux reins, des turbans étalés sur leur tête, ayant tous l’apparence de capitaines, fidèle peinture des fils de Babel, dont la Chaldée est le pays natal.
pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
16 Elle se prit d’amour pour eux, fascinée par ce qu’elle voyait, et elle leur dépêcha des messagers en Chaldée.
Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
17 Les fils de Babel vinrent à elle pour un commerce d’amour, et la souillèrent par leur luxure; elle reçut d’eux une souillure, puis son âme se détacha d’eux.
Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
18 Elle étala ses débauches, elle découvrit sa honte, et mon âme se détacha d’elle comme mon âme s’était détachée de sa soeur.
Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
19 Elle redoubla ses dérèglements, en souvenir des jours de sa jeunesse, où elle s’était prostituée dans le pays d’Egypte.
Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
20 Elle s’engoua de leurs compagnons de débauche, qui ont une chair comme celle des ânes et dont la lubricité égale celle des chevaux.
Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
21 Et ainsi tu ravivas la mémoire de la débauche de ta jeunesse, quand les Egyptiens pressaient tes mamelles, à cause de ton sein virginal.
Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
22 C’Est pourquoi, Oholiba, ainsi parle le Seigneur Dieu: Voici que je vais exciter contre toi tes amants, ceux dont s’était détaché ton coeur, et les amener de toutes parts contre toi:
“Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
23 les fils de Babel et tous les Chaldéens, Pekod et Choa et Koa, et tous les fils d’Achour avec eux, ces jeunes hommes séduisants, tous gouverneurs et seigneurs, officiers et dignitaires, tous montant des chevaux.
àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
24 Ils viendront contre toi avec armes, chars et roues, avec une multitude de peuples; ils t’envelopperont d’un cercle de boucliers, d’écus et de casques. Je leur exposerai la cause, et ils te jugeront selon leurs coutumes.
Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
25 Je dirigerai mon zèle jaloux contre toi, et ils te traiteront avec fureur, ils t’arracheront le nez et les oreilles, et ce qui restera de toi tombera par l’épée; ils te prendront tes fils et tes filles, et ton reste sera consumé par le feu.
Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
26 Ils te dépouilleront de tes 'vêtements et s’empareront de tes objets de parure.
Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
27 Ainsi Je mettrai fin à ton infamie et à tes débauches originaires du pays d’Egypte; tu ne lèveras plus les yeux vers eux, et de l’Egypte tu ne te souviendras plus."
Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
28 C’Est que le Seigneur Dieu parle de la sorte: "Je vais te livrer dans la main de ceux que tu détestes, dans la main de ceux dont s’est détachée ton âme.
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
29 Ils te traiteront avec haine, prendront tout le fruit de ton labeur et te laisseront là, nue et dépouillée; la honte de tes luxures sera découverte, ton infamie et tes dérèglements.
Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
30 On en agira ainsi avec toi, parce que tu t’es prostituée aux nations, parce que tu t’es souillée par leurs idoles.
Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
31 Tu as suivi la voie de ta soeur; je mettrai donc sa coupe dans ta main."
Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
32 Ainsi parle le Seigneur Dieu: "Tu boiras la coupe de ta soeur, si profonde et si large; elle sera une cause de risée et de moquerie, cette coupe au grand contenu.
“Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
33 Tu seras remplie d’ivresse et de peine; c’est une coupe de ruine et de désolation, la coupe de ta soeur Samarie.
Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
34 Tu la boiras jusqu’à la dernière goutte, tu en rongeras les tessons et tu te déchireras les seins, car c’est moi qui parle", dit le Seigneur Dieu.
Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
35 Oui certes, ainsi parle le Seigneur Dieu: "Puisque tu m’as oublié et que tu m’as rejeté derrière ton dos, porte donc, toi aussi, la peine de ton infamie et de tes dérèglements."
“Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
36 L’Eternel me dit: "Fils de l’homme, veux-tu faire le procès de Ohola et de Oholiba? Expose-leur leurs abominations.
Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
37 Elles ont forniqué, il y a du sang sur leurs mains; elles ont forniqué avec leurs idoles et sont allées jusqu’à leur livrer en pâture leurs fils, qu’elles m’avaient enfantés.
nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
38 Elles m’ont fait ceci encore: elles ont souillé mon sanctuaire ce même jour et profané mes sabbats.
Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
39 Oui, lorsqu’elles immolaient leurs fils à leurs idoles, elles entraient le même jour dans mon sanctuaire pour le profaner; voilà comme elles en ont agi dans ma maison.
Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
40 Bien plus, elles envoyaient chercher des hommes qui venaient de loin; un ambassadeur leur était dépêché, et ils arrivaient ceux pour qui tu t’étais baignée, tu t’étais enduit les yeux de fard, et tu avais revêtu tes atours.
“Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
41 Et tu prenais place sur un lit d’apparat, devant lequel une table était dressée, où tu posais mon encens et mon huile.
Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
42 On entendait chez elle le bruit d’une multitude paisible, et aux gens d’une nombreuse foule venaient encore s’ajouter des buveurs amenés du désert; alors elles mettaient des bracelets à leurs bras et une couronne magnifique sur leur tête.
“Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
43 Et j’ai dit de celle qui est flétrie par son inconduite: Encore maintenant on se livre avec elle aux débauches habituelles.
Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
44 On venait vers elle comme on vient vers une femme prostituée; ainsi on est venu vers Ohola et Oholiba, femmes de mauvaises moeurs.
Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
45 Or ce seront des hommes justes qui leur appliqueront la peine des adultères et 'la peine de celles qui versent le sang; car elles sont adultères et il y a du sang sur leurs mains."
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
46 En effet, ainsi parle le Seigneur Dieu: "Qu’on fasse monter contre elles une grande foule et qu’on les livre à la terreur et au pillage!
“Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
47 Que cette Moule les accable sous les pierres et les transperce par les glaives, qu’on fasse périr leurs fils et leurs filles et mettre le feu à leurs maisons!
Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
48 Ainsi je purgerai le pays de la débauche, toutes les femmes recevront une leçon et elles n’imiteront point votre inconduite.
“Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
49 On vous chargera du poids de votre débauche, vous porterez la peine de vos odieuses idoles, et vous reconnaîtrez que je suis le Seigneur Dieu."
Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”