< Ézéchiel 22 >

1 La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 "O toi, fils de l’homme! Veux-tu faire le procès, le procès de cette ville de sang? Expose-lui toutes ses abominations.
“Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
3 Tu diras: Ainsi parle le Seigneur Dieu: Ville qui verses le sang dans tes murs pour hâter ton heure, qui te couvres d’idoles dont tu reçois la souillure!
Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
4 Le sang que tu as versé te condamne, les idoles que tu as faites t’ont souillée; tu as accéléré ta fin, rapproché le terme de tes années. C’Est pourquoi je te rends l’opprobre des nations et la risée de toutes les contrées.
Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
5 Proches ou éloignées, elles se railleront de toi, ô ville perdue de réputation, fertile en désordres!
Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
6 Vois, les princes d’Israël qui étaient dans ton sein, tous hommes de violence, n’ont aspiré qu’à verser le sang.
“‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
7 Chez toi, l’on a outragé père et mère; chez toi on a pressuré durement l’étranger, spolié l’orphelin et la veuve.
Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
8 Mes saintetés, tu les as méprisées; mes sabbats, profanés.
Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
9 Chez toi, il s’est trouvé des délateurs, provoquant l’effusion du sang; chez toi, on a mangé sur les montagnes; on a pratiqué la débauche dans ton sein.
Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
10 On a découvert, chez toi, la nudité de son père; chez toi, on a fait violence à la femme qu’isolait son impureté.
Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
11 L’Un a eu avec la femme de son prochain un commerce abominable; l’autre a déshonoré sa bru par l’inceste; un autre a fait, chez toi, violence à sa soeur, à la fille de son père.
Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
12 On a accepté chez toi des dons corrupteurs pour faire couler le sang; tu as pris de l’intérêt, un profit illicite, exploité ton prochain par la rapine, et tu m’as oublié, moi, dit le Seigneur Dieu!
Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
13 Mais voici que j’ai frappé des mains à cause des rapines que tu as exercées et du sang qui s’est versé au milieu de toi.
“‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
14 Ton coeur tiendra-t-il bon, tes mains demeureront-elles fermes quand viendront les jours que je te prépare? Moi, l’Eternel, je l’ai dit et je l’accomplirai:
Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
15 je te disperserai parmi les nations, je t’éparpillerai par les pays, et j’extirperai la souillure qui s’est attachée à toi.
Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
16 Tu seras avilie par ta faute aux yeux des nations, et tu reconnaîtras que je suis l’Eternel."
Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
17 La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
18 "Fils de l’homme, les gens de la maison d’Israël sont devenus pour moi des scories; tous pareils au cuivre, à l’étain, au fer et au plomb dans le creuset: ils sont des scories de l’argent.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
19 En conséquence, ainsi parle le Seigneur Dieu: puisque vous êtes devenus tous des scories, c’est pourquoi je vais vous réunir au sein de Jérusalem.
Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
20 Comme l’on réunit argent, cuivre, fer, plomb et étain au fond d’un creuset, pour les soumettre à l’action du feu et en opérer la fusion, ainsi dans ma colère et clans mon courroux je vous réunirai, je vous introduirai dans le creuset et vous ferai fondre.
Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
21 Oui, je vous assemblerai, j’attiserai contre vous le feu de mon indignation et vous y fondrez.
Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
22 Comme l’argent entre en fusion au fond d’un creuset, ainsi vous y fondrez; et vous saurez que moi, l’Eternel, j’aurai déversé mon courroux sur vous."
Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
23 La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
24 "Fils de l’homme, dis-lui: Tu es une terre non purifiée, non trempée par la pluie, au jour de la colère.
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
25 Ses prophètes s’y coalisent; comme un lion rugissant qui déchire la proie, ils dévorent les gens, s’emparent des biens et des objets de prix et multiplient les veuves sur son sol.
Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
26 Ses prêtres font violence à ma loi, profanent mes choses saintes; ils ne font pas de différence entre le sacré et le profane et n’enseignent pas à discerner ce qui est impur de ce qui est pur. De mes sabbats Ils détournent les yeux, de sorte que je me trouve abaissé au milieu d’eux.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
27 Ses chefs y sont comme des loups qui déchirent la proie, ne pensant qu’à verser le sang, qu’à ruiner des existences pour servir leur intérêt.
Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
28 Quant à ses prophètes, ils composent à leur usage un léger badigeon, ils ont de fausses visions, leur débitent des oracles mensongers, en disant: "Ainsi parle le Seigneur Dieu!" alors que le Seigneur n’a point parlé.
Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
29 Les gens du pays exercent des violences, commettent des rapines, spolient le pauvre et l’indigent et oppriment l’étranger contre tout droit.
Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
30 J’Ai cherché parmi eux un homme capable d’élever un mur de défense, de se tenir sur la brèche devant moi en faveur de ce pays, en vue d’en prévenir la ruine, et je ne l’ai point trouvé.
“Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
31 Aussi ai-je déversé ma colère sur eux; dans le feu de mon courroux j’ai voulu en finir avec eux: j’ai fait retomber leur conduite sur leur tête," dit le Seigneur Dieu.
Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ézéchiel 22 >