< Ézéchiel 17 >
1 La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ní wá wí pé:
2 "Fils de l’homme, propose une énigme et imagine une parabole à l’adresse de la maison d’Israël.
“Ọmọ ènìyàn pa àlọ́ kan, sì pa òwe kan fún ilé Israẹli.
3 Tu diras: Ainsi parle le Seigneur Dieu: L’Aigle géant, aux grandes ailes, aux longues pennes, au plumage épais, aux nuances variées, vint vers le Liban et enleva la cime du cèdre.
Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, idì ńlá kan tó ní apá títóbi àti ìyẹ́ gígùn tó kún fún àwọ̀ oríṣìíríṣìí wa si Lebanoni, ó sì mu ẹ̀ka igi kedari tó ga jùlọ,
4 Il arracha l’extrémité de ses branches, l’apporta dans un pays marchand et la plaça dans une ville de commerçants.
ó gé ọ̀mùnú orí ẹ̀ka yìí kúrò, ó mú un lọ sí ilẹ̀ oníṣòwò, ó sì gbìn ín sí ìlú àwọn oníṣòwò.
5 Il prit de la semence du pays et la déposa dans un champ de culture; l’ayant ainsi prise, il la mit près des grandes eaux, en un lieu bien arrosé.
“‘Ó mú lára irúgbìn ilẹ̀ náà, ó gbìn ín sí ilẹ̀ ọlọ́ràá, lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi, ó gbìn ín bí igi wílóò.
6 Elle poussa et devint une vigne plantureuse, de peu de hauteur, de sorte que ses rameaux se tournaient vers lui (l’aigle) et que ses racines s’étendaient sous lui; devenue une vigne, elle produisit dès branches et projeta des rameaux.
Ó dàgbà, ó sì di àjàrà tó kúrú ṣùgbọ́n to bolẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kọjú sí i, gbòǹgbò rẹ̀ sì dúró lábẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó di àjàrà, ó sì mu ẹ̀ka àti ewé jáde.
7 Mais il y eut un autre grand aigle aux grandes ailes et au plumage abondant, et alors cette vigne inclina ses racines vers lui et projeta ses sarments de son côté, afin qu’il l’abreuvât de préférence aux plates-bandes où elle était plantée.
“‘Ṣùgbọ́n ẹyẹ idì ńlá mìíràn tún wá, tó ní apá títóbi pẹ̀lú ìyẹ́ púpọ̀. Gbòǹgbò àjàrà náà sì ta lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti orí ilẹ̀ tí wọn gbìn ín sí, ó wá pẹ̀ka lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ kí ó le fún un ni omi.
8 Elle était plantée dans un champ excellent près d’eaux abondantes, de façon é produire des branches, à porter des fruits et devenir une vigne splendide.
Orí ilẹ̀ tó dára lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi ni a gbìn ín sí, kí ó bá à le pẹ̀ka, kò sì so èso, ó sì wá di igi àjàrà tó lọ́lá púpọ̀.’
9 Dis: Ainsi parie le Seigneur Dieu: Prospérera-t-elle? N’Arrachera-t-il pas ses racines, ne coupera-t-il pas son fruit de sorte qu’il se dessèche; toutes les feuilles produites par elles ne seront-elles pas fanées? Et il n’aura pas besoin d’un bras puissant ni d’un peuple nombreux pour l’arracher de ses racines.
“Sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyí, yóò wá gbilẹ̀ bí? A kò wá ní i wú gbòǹgbò rẹ̀, ki a si gé èso rẹ̀ kúrò kí ó bá à le rọ? Gbogbo ewé rẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ ni yóò rẹ̀. Kò sì nígbà agbára tàbí ènìyàn púpọ̀ láti fà gbòǹgbò rẹ̀ tu.
10 La voilà plantée, réussira-t-elle? Quand l’aura atteinte le vent d’est, ne se desséchera-t-elle pas? Oui, elle se desséchera, sur les plates-bandes où elle croissait!"
Bí a tilẹ̀ tún un gbìn, yóò wa gbilẹ̀ bí? Kò wá ní i rọ pátápátá nígbà ti afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn bá kọlù ú. Gbogbo ewé rẹ̀ yóò rẹ̀ lórí ilẹ̀ tó ti dàgbà?’”
11 La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
Nígbà náà, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá pé:
12 "Eh bien! Dis à la maison de rébellion: Ne savez-vous pas ce que signifient ces choses? Dis: Voici qu’est venu le roi de Babel à Jérusalem; il a pris son roi et ses princes et les a amenés chez lui à Babylone.
“Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé yìí, ‘Ǹjẹ́ ẹ mọ ìtumọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?’ Sọ fún wọn: ‘Ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó ọba àti àwọn ìjòyè ọmọ-aládé ibẹ̀ lọ sí Babeli lọ́dọ̀ rẹ̀.
13 II a pris un rejeton de race royale, il a contracté une alliance avec lui, il l’a engagé par un serment, mais il a emmené les grands du pays,
Lẹ́yìn èyí, ó bá ọ̀kan nínú ọmọ ọba dá májẹ̀mú, ó mú un ìbúra, ó tún kó àwọn alágbára ilẹ̀ náà lọ.
14 pour que le royaume fût abaissé et ne se relevât plus, et qu’il gardât son alliance et en assurât la durée.
Kí ìjọba ilẹ̀ náà le rẹ ilẹ̀, kí ó má lè gbé ara rẹ̀ sókè, kí ó lè dúró nípa pípa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
15 Mais il se révolta contre lui, envoyant des messagers en Egypte pour qu’on lui fournît des chevaux et de grandes troupes. Peut-il réussir et se sauver, celui qui agit de la sorte? II romprait l’alliance et se sauverait!
Ṣùgbọ́n ọba ṣọ̀tẹ̀ sí i nípa ríran àwọn ikọ̀ rẹ̀ lọ sí Ejibiti, kí wọn bá à lè fún un ni ẹṣin àti àwọn ọmọ-ogun púpọ̀. Yóò ha ṣe àṣeyọrí? Ṣe ẹni tó ṣe irú nǹkan yìí yóò sì bọ́ níbẹ̀? Yóò ha dalẹ̀ tán kí ó sì bọ́ níbẹ̀ bí?
16 Je le jure par ma vie, dit le Seigneur Dieu, c’est au pays du roi qui l’a appelé au pouvoir et dont il a méprisé le serment et rompu le pacte, c’est chez lui, à Babel, qu’il périra!
“‘Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, òun yóò kú ní Babeli, ní ilẹ̀ ọba tó fi sórí oyè, ìbúra ẹni tí ó kẹ́gàn àti májẹ̀mú ẹni tí ó dà.
17 Et ce n’est pas avec de grandes forces et une multitude nombreuse que Pharaon agira pour lui dans la guerre, quand on élèvera des chaussées et qu’on bâtira des ouvrages, pour massacrer beaucoup de monde.
Farao pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun àti àjọ ńlá rẹ̀ kò ní lè ṣe ìrànwọ́ fún un lójú ogun. Nígbà tí wọ́n bá pa bùdó ogun tì í, tí wọ́n sì mọ odi láti pa ọ̀pọ̀ ènìyàn.
18 Il a méprisé le serment en rompant le pacte; or il avait donné sa main, et il a fait tout cela! Il ne se sauvera pas.
Nítorí pé ó kẹ́gàn ìbúra nípa dída májẹ̀mú, àti pé ó juwọ́ sílẹ̀ nínú ṣíṣe ìlérí, kì yóò bọ níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn nǹkan tí ó ṣe yìí.
19 C’Est pourquoi, ainsi parle le Seigneur Dieu. Par ma vie, je le jure, mon serment qu’il a méprisé et mon pacte qu’il a rompu, je le ferai retomber sur sa tête.
“‘Nítorí náà Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà láààyè, Èmi yóò mú ẹ̀san ẹ̀jẹ́ mi tó kẹ́gàn àti májẹ̀mú mi tó dà wa sórí rẹ̀.
20 J’Étendrai sur lui mon réseau, et il sera pris dans mon filet; je l’amènerai à Babel et là je lui demanderai compte de l’infidélité qu’il a commise envers moi.
Èmi yóò ta àwọ̀n mi sórí rẹ̀, yóò sì bọ sínú okùn mi, Èmi yóò mú ọ lọ Babeli láti ṣe ìdájọ́ ìwà ọ̀dàlẹ̀ tó hù sí mi.
21 Et tous ses fugitifs, dans toutes ses troupes, tomberont sous le glaive, et les survivants se disperseront en tous sens, et vous saurez que moi, l’Eternel, j’ai parlé."
Gbogbo ìgbèkùn àti ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ ni yóò kú pẹ̀lú idà, èmi yóò sì fọn àwọn ìyókù ká sínú afẹ́fẹ́ káàkiri. Nígbà náà ni yóò mọ̀ pé, “Èmi Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.”
22 Ainsi parle le Seigneur Dieu: "Je détacherai, moi, un peu de la cime élevée du cèdre et le mettrai en terre, je trancherai un rameau tendre de l’extrémité de ses branches et je le planterai, moi, sur une montagne haute et élancée.
“‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi fúnra mi yóò mú ọ̀kan lára ẹ̀ka tí ó ga jùlọ lórí igi kedari gíga, tí èmi yóò sì gbìn ín, èmi yóò sì gé ọ̀mùnú tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ láti òkè, èmi yóò sì gbìn ín sórí òkè tó ga tó sì lókìkí.
23 Sur la montagne la plus élevée d’Israël je le planterai; il portera des branches, produira des fruits et deviendra un cèdre majestueux; sous lui habiteront tous les oiseaux de tout plumage, ils habiteront à l’ombre de ses rameaux,
Ní ibi gíga òkè Israẹli ni èmi yóò gbìn ín sí; yóò pẹ̀ka, yóò sì so èso, yóò wa di igi kedari tí ó lọ́lá. Oríṣìíríṣìí ẹyẹ yóò sì fi òjìji abẹ ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé; wọn yóò ṣe ibùgbé si abẹ́ òjìji ẹ̀ka rẹ̀.
24 Et tous les arbres des champs sauront que moi, l’Eternel, j’ai humilié un arbre élevé et élevé un arbre humble, j’ai desséché un arbre vert et lait fleurir un arbre sec; moi l’Eternel, j’ai parlé et agi."
Gbogbo igi inú oko yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó mú igi gíga walẹ̀, tí mo sì mú kúkúrú ga sókè, tí mo mu igi tútù gbẹ, tí mo sì mú igi gbígbẹ rúwé. “‘Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì ṣe e.’”