< Ézéchiel 13 >

1 La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 "Fils de l’homme, prophétise à l’adresse des prophètes d’Israël qui prophétisent, et dis à ceux qui s’intitulent prophètes: Ecoutez la parole de l’Eternel.
“Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
3 Ainsi parle le Seigneur Dieu: Malheur aux prophètes indignes qui suivent leur propre inspiration et des visions qu’ils n’ont pas eues.
Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
4 Comme des renards parmi des décombres étaient tes prophètes; ô Israël
Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
5 Vous n’êtes pas montés sur les brèches, vous n’avez pas élevé de clôture autour de la maison d’Israël, afin de tenir bon pendant le combat, au jour de l’Eternel.
Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
6 Ils ont annoncé des visions fausses et des oracles mensongers, eux qui disaient: "Parole de l’Eternel!" alors que Dieu ne les avait pas envoyés, et qui se flattaient que la prédiction s’accomplirait.
Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
7 Ne sont-ce pas des visions fausses que vous avez annoncées et des oracles de mensonge que vous avez proclamés, en disant: "Parole de l’Eternel!" alors que je n’avais pas parlé?
Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
8 C’Est pourquoi, ainsi parle le Seigneur Dieu, parce que vous avez parlé faussement et annoncé des visions mensongères, c’est pourquoi je vais m’en prendre à vous, dit le Seigneur Dieu.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Et ma main pèsera sur les prophètes qui annoncent des visions fausses et des oracles mensongers; ils ne seront pas du conseil de mon peuple, ils ne seront pas inscrits sur les rôles de la maison d’Israël, et ils ne viendront pas sur le territoire d’Israël, et vous saurez que je suis le Seigneur Dieu.
Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
10 Parce que, oui parce qu’ils ont égaré mon peuple en disant: "Paix!" quand il n’y a point de paix, et qu’alors qu’il bâtit un mur, eux l’enduisent d’un léger badigeon.
“‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
11 Dis à ceux qui l’enduisent d’un léger badigeon qu’il tombera; il y aura une pluie torrentielle, et vous, les pierres de grêle, vous tomberez, et un vent de tempête éclatera.
nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
12 Et voici que le mur s’écroule; ne vous dira-t-on pas: "Où est l’enduit que vous avez répandu?"
Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
13 C’Est pourquoi, ainsi parle le Seigneur Dieu, je ferai éclater un vent de tempête dans ma fureur, une pluie torrentielle tombera par ma colère, et des grêlons par ma fureur pour amener la ruine.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
14 Je démolirai le mur que vous avez couvert de badigeon, je le raserai jusqu’au sol et ses fondations seront mises à nu, il tombera et vous y périrez et vous saurez que je suis l’Eternel.
Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
15 J’Épuiserai ma fureur sur le mur et sur ceux qui l’ont enduit de mortier et je vous dirai: Il n’est plus, le mur, ils ne sont plus, ceux qui l’ont enduit,
Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
16 ô vous, prophètes d’Israël qui prophétisez sur Jérusalem, et qui lui révélez des visions de paix, quand il n’y a point de paix, dit le Seigneur Dieu!
Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
17 Et toi, fils de l’homme, tourne ton visage vers les filles de ton peuple, qui s’érigent en prophétesses de leur chef, et prophétise contre elles.
“Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
18 Tu diras: Ainsi parle le Seigneur Dieu: Malheur à celles qui cousent des coussinets pour toutes les articulations des mains, et confectionnent des coiffes pour les têtes de toute taille afin de capter les âmes; vous iriez à la chasse des âmes dans mon peuple et vos âmes à vous, vous les feriez vivre?
wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
19 Et vous m’avez déshonoré auprès de mon peuple pour des poignées d’orge et pour des morceaux de pain en vue de faire mourir les âmes qui ne devaient pas mourir et de faire vivre les âmes qui ne devaient point vivre, en mentant à mon peuple, qui écoute des mensonges.
Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
20 C’Est pourquoi, ainsi parle le Seigneur Dieu: Me voici contre vos coussinets, par lesquels vous faites la chasse aux âmes comme à des oiseaux; je les déchirerai de dessus vos bras et je ferai évader les âmes auxquelles vous donnez la chasse comme à des oiseaux.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
21 Je lacérerai vos coiffes, et je sauverai mon peuple de vos mains; ils ne seront plus entre vos mains comme un gibier et vous saurez que je suis l’Eternel.
Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
22 Parce que vous avez contristé le coeur du juste par le mensonge, tandis que moi, je ne l’ai pas affligé, et que vous avez affermi le courage du méchant, pour l’empêcher de se repentir de sa mauvaise voie et de sauver sa vie.
Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
23 Aussi ne révélerez-vous plus de fausses visions ni ne prononcerez plus d’oracles; je sauverai mon peuple de votre main, et vous saurez que je suis l’Eternel."
nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”

< Ézéchiel 13 >