< Daniel 1 >

1 Dans la troisième année du règne de Joïakim, roi de Juda, Nabuchodonosor, roi de Babylone, marcha contre Jérusalem et l’assiégea.
Ní ọdún kẹta tí Jehoiakimu jẹ ọba Juda, Nebukadnessari ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kọlù ú pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
2 Le Seigneur livra en son pouvoir Joïakim, roi de Juda, et une partie des vases de la maison de Dieu, qu’il transporta au pays de Sennaar, dans le temple de sa divinité; c’est dans le trésor de son dieu qu’il déposa ces vases.
Olúwa sì fa Jehoiakimu ọba Juda lé e lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run. Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó lọ sí ilé òrìṣà ní Babeli, sí inú ilé ìṣúra òrìṣà rẹ̀.
3 Le roi ordonna à Achpenaz, chef de ses eunuques, d’amener, d’entre les enfants d’Israël, issus de la lignée royale et des familles nobles,
Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Aṣipenasi, olórí àwọn ìwẹ̀fà ààfin rẹ̀ pé, kí ó mú nínú àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n wá láti ìdílé ọba àti lára àwọn tí ó wá láti ilé ọlá.
4 des jeunes gens, exempts de tout défaut corporel, beaux de figure, initiés à toute sagesse, doués d’intelligence, versés dans les connaissances et qui pourraient être admis dans le palais du roi, et de leur enseigner l’écriture et la langue des Chaldéens.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí kò ní àbùkù ara, tí wọ́n rẹwà, tí wọ́n sì fi ìfẹ́ sí ẹ̀kọ́ hàn, tí wọ́n sì ní ìmọ̀, tí òye tètè ń yé àti àwọn tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ṣiṣẹ́ ní ààfin ọba kí ó kọ́ wọ́n ní èdè àti onírúurú ẹ̀kọ́ ìwé ti àwọn Babeli.
5 Le roi leur assigna pour leur entretien journalier des plats de la table royale et du vin qui lui servait de boisson, de façon à les éduquer durant trois années, puis à en attacher quelques-uns au service du roi.
Ọba pèsè oúnjẹ ojoojúmọ́ àti wáìnì láti orí tábìlì i rẹ̀ fún wọn, ó sì kọ́ wọn fún ọdún mẹ́ta. Lẹ́yìn náà ni wọn yóò bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiṣẹ́ fún ọba.
6 Au nombre des enfants de Juda qui se trouvaient parmi eux figuraient Daniel, Hanania, Misaël et Azaria.
Lára àwọn wọ̀nyí ni àwọn tó wá láti Juda: Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah.
7 Le chef des eunuques leur attribua de nouveaux noms; il appela Daniel Beltchaçar, Hanania Chadrac, Misaël Mêchac et Azaria Abêd-Nego.
Olórí àwọn ìwẹ̀fà fún wọn ní orúkọ tuntun: Ó fún Daniẹli ní Belteṣassari, ó fún Hananiah ní Ṣadraki, ó fún Miṣaeli ní Meṣaki àti Asariah ní Abednego.
8 Or Daniel prit la résolution de ne pas se souiller par les plats du roi et le vin qui lui servait de boisson; il insista donc auprès du chef des eunuques pour n’avoir pas à se souiller.
Ṣùgbọ́n Daniẹli pinnu ní ọkàn ara rẹ̀ pé òun kò ní ba ara òun jẹ́ pẹ̀lú oúnjẹ àti wáìnì ọba, nígbà náà ni ó gba ààyè lọ́wọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà wí pé òun kò fẹ́ ba ara òun jẹ́ ní ọ̀nà yìí.
9 Dieu fit trouver à Daniel grâce et mansuétude auprès du chef des eunuques.
Ọlọ́run mú kí Daniẹli rí ojúrere àti àánú gbà láti ọwọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà,
10 Le chef des eunuques dit à Daniel: "Je redoute le roi, mon maître, qui a réglé votre nourriture et votre boisson car s’il devait trouver votre mine plus chétive que celle des autres jeunes gens dans votre condition, vous m’en feriez responsable sur ma tête aux yeux du roi."
ṣùgbọ́n olórí àwọn ìwẹ̀fà sọ fún Daniẹli pé, “Mo bẹ̀rù olúwa mi, ẹni tí o ti pèsè oúnjẹ àti ohun mímu rẹ. Báwo ni ìrísí rẹ yóò ṣe burú jù ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ẹlẹgbẹ́ ẹ̀ rẹ lọ? Nígbà náà ni èmi yóò fi orí mi wéwu lọ́dọ̀ ọba.”
11 Daniel répliqua au gouverneur que le chef des eunuques avait préposé à Daniel, Hanania, Misaël et Azaria:
Nígbà náà ni Daniẹli sọ fún olùṣọ́ tí olórí àwọn ìwẹ̀fà yàn lórí i Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah pé,
12 "De grâce, mets tes serviteurs à l’épreuve pendant une dizaine de jours: qu’on ne nous donne que des légumes secs à manger et de l’eau à boire.
“Jọ̀wọ́ dán àwa ìránṣẹ́ rẹ wò fún ọjọ́ mẹ́wàá. Má ṣe fún wa ní ohun kankan, àfi ewébẹ̀ láti jẹ àti omi láti mu.
13 Puis, tu examineras notre mine et la mine des jeunes gens nourris des mets du roi, et, selon ce que tu verras, tu agiras à l’égard de tes serviteurs."
Nígbà náà ni kí o fi ìrísí i wa wé ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba, kí o sì ṣe àwa ìránṣẹ́ rẹ ní ìbámu pẹ̀lú u bí o bá ṣe rí i sí.”
14 II leur céda sur ce point et les mit à l’épreuve pendant dix jours.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì gbà láti dán wọn wò fún ọjọ́ mẹ́wàá.
15 Au bout de ces dix jours, leur mine parut meilleure et leur embonpoint plus marqué que ceux de tous les jeunes gens nourris des mets du roi.
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹwàá ara wọn le, wọ́n sì sanra ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba lọ.
16 Dès lors, le gouverneur enlevait leurs plats et le vin qu’on leur servait à boire, et leur donnait des légumes secs.
Bẹ́ẹ̀ ni olùṣọ́ mú oúnjẹ àdídùn àti wáìnì tí ó yẹ kí wọ́n mu kúrò, ó sì fún wọn ní ewébẹ̀ dípò rẹ̀.
17 Et à ces jeunes gens, à tous les quatre, Dieu avait accordé le savoir et la faculté de comprendre toute écriture et toute science; quant à Daniel, il possédait l’intelligence de toute vision et des songes.
Ọlọ́run fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ní ìmọ̀ àti òye nínú gbogbo onírúurú ìwé àti ẹ̀kọ́ ọ wọn: Daniẹli sì ní òye ìran àti àlá ní oríṣìíríṣìí.
18 Au terme du délai que le roi avait fixé pour les lui amener, le chef des eunuques les introduisit auprès de Nabuchodonosor.
Ní òpin ìgbà tí ọba dá, pé kí a mú wọn wá sínú ààfin, olórí àwọn ìwẹ̀fà mú wọn wá síwájú ọba Nebukadnessari.
19 Le roi s’entretint avec eux: parmi tous les jeunes gens il ne s’en trouvait pas de comparables à Daniel, Hanania, Misaël et Azaria; ils furent donc attachés au service du roi.
Ọba sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì rí i pé kò sí ẹni tí ó dàbí i Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah; nítorí náà wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣe iṣẹ́ ọba.
20 Et sur toute question d’ingénieuse sagesse que le roi leur posait, il les trouvait dix fois supérieurs à tous les devins et magiciens qui vivaient dans tout son royaume.
Nínú gbogbo ọ̀ràn ọgbọ́n àti òye tí ọba ń béèrè lọ́wọ́ wọn, ó rí i pé wọ́n sàn ní ìlọ́po mẹ́wàá ju gbogbo àwọn amòye àti ọlọ́gbọ́n tí ó wà ní gbogbo ìjọba rẹ̀.
21 Daniel alla ainsi jusqu’à la première année de Cyrus.
Daniẹli sì wà níbẹ̀ títí di ọdún kìn-ín-ní ọba Kirusi.

< Daniel 1 >