< 2 Samuel 19 >

1 On annonça à Joab que le roi pleurait et se lamentait sur Absalon.
A sì rò fún Joabu pe, “Wò ó, ọba ń sọkún, ó sì ń gbààwẹ̀ fún Absalomu.”
2 La victoire de ce jour se transforma en deuil pour tout le peuple, celui-ci ayant appris ce jour-là que le roi se désolait à cause de son fils.
Ìṣẹ́gun ọjọ́ náà sì di àwẹ̀ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, nítorí àwọn ènìyàn náà gbọ́ ní ọjọ́ náà bí inú ọba ti bàjẹ́ nítorí ọmọ rẹ̀.
3 Et le peuple, ce jour-là, rentra furtivement à la ville, comme se glisse une troupe honteuse, mise en déroute dans une bataille.
Àwọn ènìyàn náà sì yọ́ lọ sí ìlú ní ọjọ́ náà gẹ́gẹ́ bí àwọn bí ènìyàn tí a dójútì ṣe máa ń yọ́ lọ nígbà tí wọ́n bá sá lójú ìjà.
4 Le roi s’était voilé la face et répétait à grands cris: "Mon fils Absalon! Absalon, mon fils, ô mon fils!"
Ọba sì bo ojú rẹ̀, ọba sì kígbe ní ohùn rara pé, “Á à! Ọmọ mi Absalomu! Absalomu ọmọ mi, ọmọ mi!”
5 Joab entra chez le roi et lui dit: "Tu as fait honte aujourd’hui à tous tes serviteurs, qui ont sauvé en ce jour ton existence, celle de tes fils et de tes filles, celle de tes femmes et de tes concubines,
Joabu sì wọ inú ilé tọ ọba lọ, ó sì wí pé, “Ìwọ dójúti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ lónìí, àwọn tí ó gba ẹ̀mí rẹ̀ là lónìí, àti ẹ̀mí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti ti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, àti àwọn aya rẹ̀, àti ẹ̀mí àwọn obìnrin rẹ.
6 et cela, en aimant tes ennemis et en haïssant ceux qui t’aiment! Oui, tu as déclaré aujourd’hui que tu n’as point d’officiers, point de serviteurs, et je vois bien à présent que si Absalon était vivant et que nous tous fussions morts, tu trouverais cela bon.
Nítorí pé ìwọ fẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ sì kórìíra àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Nítorí tí ìwọ wí lónìí pé, Ìwọ kò náání àwọn ọmọ ọba tàbí àwọn ìránṣẹ́; èmi sì rí lónìí pé, ìbá ṣe pé Absalomu wà láààyè, kí gbogbo wa sì kú lónìí, ǹjẹ́ ìbá dùn mọ́ ọ gidigidi.
7 Et maintenant, debout! Montre-toi, parle au cœur de tes serviteurs; car si tu ne te montres pas, j’en jure par l’Eternel, pas un homme ne restera cette nuit avec toi, et ce sera pour toi un pire malheur que tous ceux qui te sont arrivés depuis ta jeunesse jusqu’à ce jour!"
Sì dìde nísinsin yìí, lọ, kí o sì sọ̀rọ̀ ìtùnú fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, nítorí pé èmi fi Olúwa búra, bí ìwọ kò bá lọ, ẹnìkan kì yóò bá ọ dúró ni alẹ́ yìí, èyí ni yóò sì burú fún ọ ju gbogbo ibi tí ojú rẹ ti ń rí láti ìgbà èwe rẹ wá títí ó fi di ìsinsin yìí.”
8 Le roi se leva et prit place à la porte. On fit savoir à tout le peuple que le roi était assis à la porte; et tout le peuple se présenta alors devant le roi, tandis que ceux d’Israël fuyaient chacun dans leurs tentes.
Ọba sì dìde, ó sì jókòó ní ẹnu-ọ̀nà, wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Wò ó, ọba jókòó ní ẹnu-ọ̀nà.” Gbogbo ènìyàn sì wá sí iwájú ọba. Nítorí pé, Israẹli ti sá, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀.
9 Et tout le peuple discutait, dans toutes les tribus d’Israël, disant: "Le roi nous a sauvés de la main de nos ennemis, il nous a délivrés de la puissance des Philistins, et maintenant il a dû s’enfuir du pays à cause d’Absalon.
Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì ń bà ara wọn jà nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, pé, “Ọba ti gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, ó sì ti gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini; òun sì wá sá kúrò ní ìlú nítorí Absalomu.
10 Or Absalon, que nous avions installé à notre tête, est mort à la guerre… Qu’attendons-nous donc pour réintégrer le roi?"
Absalomu, tí àwa fi jẹ ọba lórí wa sì kú ní ogun, ǹjẹ́ èéṣe tí ẹ̀yin fi dákẹ́ tí ẹ̀yin kò sì sọ̀rọ̀ kan láti mú ọba padà wá?”
11 Le roi David, de son côté, envoya dire aux pontifes Çadok et Ebiathar: "Parlez aux anciens de Juda en ces termes: Pourquoi seriez-vous les derniers à ramener le roi dans sa maison, alors que le propos de tout Israël est parvenu au roi, jusque chez lui?
Dafidi ọba sì ránṣẹ́ sí Sadoku, àti sí Abiatari àwọn àlùfáà pé, “Sọ fún àwọn àgbàgbà Juda, pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi kẹ́yìn láti mú ọba padà wá sí ilé rẹ̀? Ọ̀rọ̀ gbogbo Israẹli sì ti dé ọ̀dọ̀ ọba àní ní ilé rẹ̀.
12 Vous êtes mes frères, vous êtes mes os et ma chair; pourquoi donc seriez-vous les derniers à ramener le roi?
Ẹ̀yin ni ara mi, ẹ̀yin ni egungun mi, àti ẹran-ara mi: èéṣì ti ṣe tí ẹ̀yin fi kẹ́yìn láti mú ọba padà wá.’
13 Pour Amasa, vous lui direz: Certes, tu es comme mes os et ma chair; que Dieu me punisse autant et plus, si tu ne deviens à jamais mon chef d’armée à la place de Joab!"
Kí ẹ̀yin sì wí fún Amasa pé, ‘Egungun àti ẹran-ara mi kọ́ ni ìwọ jẹ́ bí? Kí Ọlọ́run ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí ìwọ kò ba ṣe olórí ogun níwájú mi títí, ní ipò Joabu.’”
14 Il amena le cœur de tous les gens de Juda à se prononcer comme un seul homme, et ils firent dire au roi: "Reviens avec tous tes serviteurs."
Òun sì yí gbogbo àwọn ọkùnrin Juda lọ́kàn padà àní bí ọkàn ènìyàn kan; wọ́n sì ránṣẹ́ sí ọba, pé, “Ìwọ padà àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ.”
15 Le roi revint, et il atteignait le Jourdain lorsque Juda arriva à Ghilgal pour aller au-devant du roi et l’aider à traverser le Jourdain.
Ọba sì padà, o sì wá sí odò Jordani. Juda sì wá sí Gilgali láti lọ pàdé ọba, àti láti mú ọba kọjá odò Jordani.
16 Séméi, fils de Ghêra, le Benjamite, de Bahourim, se hâta de descendre avec les hommes de Juda, à la rencontre du roi David.
Ṣimei ọmọ Gera, ará Benjamini ti Bahurimu, ó yára ó sì bá àwọn ọkùnrin Juda sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Dafidi ọba.
17 Avec lui étaient venus mille hommes de Benjamin, plus Ciba, serviteur de la maison de Saül, avec ses quinze enfants et ses vingt esclaves; et ils traversèrent le Jourdain en présence du roi.
Ẹgbẹ̀rún ọmọkùnrin sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nínú àwọn ọmọkùnrin Benjamini, Ṣiba ìránṣẹ́ ilé Saulu, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́ sì pẹ̀lú rẹ̀; wọ́n sì gòkè odò Jordani ṣáájú ọba.
18 Alors le bac s’avança pour faire passer la maison du roi, dans le but de lui complaire; et Séméi, fils de Ghêra, se jeta aux pieds du roi tandis qu’il passait le Jourdain,
Ọkọ̀ èrò kan ti rékọjá láti kó àwọn ènìyàn ilé ọba sí òkè, àti láti ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ̀. Ṣimei ọmọ Gera wólẹ̀. Ó sì dojúbolẹ̀ níwájú ọba, bí ó tí gòkè odò Jordani.
19 et il dit au roi: "Que mon seigneur ne m’impute pas à crime et ne se rappelle plus la mauvaise conduite de ton serviteur, le jour où mon seigneur le roi est sorti de Jérusalem; que le roi ne le prenne pas à cœur!
Ó sì wí fún ọba pé, “Kí olúwa mi ó má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ sí mi lọ́rùn, má sì ṣe rántí àfojúdi tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣe ni ọjọ́ tí olúwa mi ọba jáde ní Jerusalẹmu, kí ọba má sì fi sí inú.
20 J’Ai reconnu, moi ton serviteur, que j’étais coupable, et je suis venu aujourd’hui, le premier de toute la maison de Joseph, pour descendre à la rencontre du roi mon maître."
Nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ mọ̀ pé èmi ti ṣẹ̀; sì wò ó, mo wá lónìí yìí, ẹni àkọ́kọ́ ní gbogbo ìdílé Josẹfu tí yóò sọ̀kalẹ̀ wá pàdé olúwa mi ọba.”
21 Abisaï, fils de Cerouya, prit la parole et dit: "Pour cette raison, Séméi ne doit-il pas être mis à mort, lui qui a insulté l’élu de l’Eternel?"
Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah dáhùn ó sì wí pé, “Kò ha tọ́ kí a pa Ṣimei nítorí èyí? Nítorí pé òun ti bú ẹni àmì òróró Olúwa.”
22 David répondit: "Qu’ai-je affaire de vous, enfants de Cerouya, qui agissez à mon égard comme ferait un ennemi? Aujourd’hui, un homme serait mis à mort en Israël, aujourd’hui que je me vois redevenu roi d’Israël!"
Dafidi sì wí pé, “Kí ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah tí ẹ dàbí ọ̀tá fún mi lónìí? A ha lè pa ènìyàn kan lónìí ní Israẹli? Tàbí èmi kò ha mọ̀ pé lónìí èmi ni ọba Israẹli.”
23 Et le roi dit à Séméi: "Tu ne mourras pas", et le roi le lui jura.
Ọba sì wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ kì yóò kú!” Ọba sì búra fún un.
24 Mephiboseth, fils de Saül, descendit au-devant du roi; il n’avait point soigné ses pieds ni fait sa barbe, il n’avait pas nettoyé ses vêtements depuis le départ du roi jusqu’au jour où il revenait en paix.
Mefiboṣeti ọmọ Saulu sì sọ̀kalẹ̀ láti wá pàdé ọba, kò wẹ ẹsẹ̀ rẹ̀, kò sí tọ́ irùngbọ̀n rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fọ aṣọ rẹ̀ láti ọjọ́ tí ọba ti jáde títí ó fi di ọjọ́ tí ó fi padà ní àlàáfíà.
25 Quand il vint de Jérusalem au-devant du roi, celui-ci lui dit: "Pourquoi ne m’as-tu pas accompagné, Mephiboseth?
Nígbà tí òun sì wá sí Jerusalẹmu láti pàdé ọba, ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ kò fi bá mi lọ, Mefiboṣeti?”
26 Seigneur, répondit-il, mon serviteur m’a trompé. En effet, j’avais dit: Je vais faire sangler l’ânesse et la monter, et marcher avec le roi, car ton serviteur est boiteux;
Òun sì dáhùn wí pé, “Olúwa mi, ọba, ìránṣẹ́ mi ni ó tàn mí, nítorí ìránṣẹ́ rẹ wí fún un pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi èmi ó gùn ún, èmi ó sì tọ ọba lọ.’ Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ yarọ.
27 mais il a calomnié ton serviteur auprès de mon seigneur le roi, qui est pourtant comme un ange de Dieu! Agis donc comme il te semblera bon.
Ó sì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí ìránṣẹ́ rẹ, fún olúwa mi ọba, ṣùgbọ́n bí angẹli Ọlọ́run ni olúwa mi ọba rí, nítorí náà ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ.
28 Car tous les membres de la famille de mon père pouvaient être sans exception voués à la mort par mon seigneur le roi, et pourtant tu as admis ton serviteur parmi tes convives; quel droit donc aurais-je encore d’adresser une plainte au roi?"
Nítorí pé gbogbo ilé baba mi bí òkú ènìyàn ni wọ́n sá à rí níwájú olúwa mi ọba, ìwọ sì fi ipò fún ìránṣẹ́ rẹ láàrín àwọn tí ó ń jẹun ní ibi oúnjẹ. Nítorí náà àre kín ni èmi ní tí èmi yóò fi máa ké pe ọba síbẹ̀.”
29 Le roi lui dit: "Pourquoi discourir davantage? Je déclare que toi et Ciba vous vous partagerez les terres.
Ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń sọ ọ̀ràn ara rẹ fún mi èmi sá à ti wí pé, kí ìwọ àti Ṣiba pín ilẹ̀ náà.”
30 Qu’il prenne même le tout, reprit Mephiboseth, maintenant que le roi mon maître est rentré en paix dans sa demeure."
Mefiboṣeti sì wí fún ọba pé, “Jẹ́ kí ó mú gbogbo rẹ̀, kí olúwa mi ọba sá à ti padà bọ̀ wá ilé rẹ̀ ni àlàáfíà.”
31 Barzillaï, le Galaadite, était venu de Roghelim pour traverser avec le roi le Jourdain, sur lequel il voulait l’accompagner.
Barsillai ará Gileadi sì sọ̀kalẹ̀ láti Rogelimu wá, ó sì bá ọba gòkè odò Jordani, láti ṣe ìkẹ́ rẹ̀ sí ìkọjá odò Jordani.
32 Or, Barzillaï était très vieux, il avait quatre-vingts ans; c’est lui qui avait sustenté le roi pendant son séjour à Mahanaïm, c’était un très grand personnage.
Barsillai sì jẹ́ arúgbó ọkùnrin gidigidi, ẹni ogbó ọgọ́rin ọdún sì ni, ó sì pèsè ohun jíjẹ fún ọba nígbà tí ó ti wà ní Mahanaimu; nítorí pé ọkùnrin ọlọ́lá ni òun ń ṣe.
33 Le roi lui dit: "Fais route avec moi; je veux t’entretenir auprès de moi à Jérusalem."
Ọba sì wí fún Barsillai pé, “Ìwọ wá bá mi gòkè odò, èmi ó sì máa pèsè fún ọ ní Jerusalẹmu.”
34 Barzillaï lui répondit: "Combien ai-je encore de jours à vivre, pour monter avec le roi à Jérusalem?
Barsillai sì wí fún ọba pé, “Ọjọ́ mélòó ni ọdún ẹ̀mí mi kù, tí èmi ó fi bá ọba gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
35 J’Ai aujourd’hui quatre-vingts ans; puis-je encore distinguer le bien du mal, connaître le goût de ce que je mange et de ce que je bois, apprécier la voix des chanteurs et des chanteuses? Pourquoi ton serviteur serait-il maintenant à charge à mon seigneur le roi?
Ẹni ogbó ọgọ́rin ọdún sá à ni èmi lónìí, ǹjẹ́ èmi mọ ìyàtọ̀ nínú rere àti búburú? Ǹjẹ́ ìránṣẹ́ rẹ le mọ adùn ohun tí òun ń jẹ tàbí ohun ti òun ń mu bí? Èmi tún lè mọ adùn ohùn àwọn ọkùnrin tí ń kọrin àti àwọn obìnrin tí ń kọrin bí, ǹjẹ́ nítorí kín ni ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe jẹ́ ìyọnu síbẹ̀ fún olúwa mi ọba.
36 Ton serviteur avancera un peu au delà du Jourdain avec le roi; mais pourquoi le roi veut-il m’accorder une telle rémunération?
Ìránṣẹ́ rẹ yóò sì sin ọba lọ díẹ̀ gòkè odò Jordani; èéṣì ṣe tí ọba yóò fi san ẹ̀san yìí fún mi.
37 Permets que moi, ton serviteur, je revienne mourir dans ma ville, près du tombeau de mon père et de ma mère. D’Ailleurs, ton serviteur Kimham peut aller avec mon seigneur le roi; traite-le comme il te semblera bon."
Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ padà, èmi ó sì kú ní ìlú mi, a ó sì sin mí ní ibojì baba àti ìyá mi. Sì wo Kimhamu ìránṣẹ́ rẹ, yóò bá olúwa mi ọba gòkè; ìwọ ó sì ṣe ohun tí ó bá tọ́ lójú rẹ fún un.”
38 Le roi répondit: "Kimham m’accompagnera, et je le traiterai comme toi-même le trouveras bon; et tout ce que tu préféreras que je fasse, je le ferai pour toi."
Ọba sì dáhùn wí pé, “Kimhamu yóò bá mi gòkè, èmi ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ̀ fún un; ohunkóhun tí ìwọ bá sì béèrè lọ́wọ́ mi, èmi ó ṣe é fún ọ.”
39 Toute la troupe traversa le Jourdain. Quand le roi l’eut passé, il embrassa et bénit Barzillaï, qui s’en retourna chez lui.
Gbogbo àwọn ènìyàn sì gòkè odò Jordani ọba sì gòkè; ọba sì fi ẹnu ko Barsillai lẹ́nu, ó sì súre fún un; òun sì padà sí ilé rẹ̀.
40 Le roi avança vers Ghilgal, Kimham y alla avec lui, et tout le peuple de Juda accompagna le roi, avec la moitié du peuple d’Israël.
Ọba sì ń lọ́ sí Gilgali, Kimhamu sì ń bà a lọ, gbogbo àwọn ènìyàn Juda sì ń ṣe ìkẹ́ ọba, àti ààbọ̀ àwọn ènìyàn Israẹli.
41 Or, tous ceux d’Israël, en arrivant auprès du roi, lui dirent: "Pourquoi nos frères, les hommes de Juda, se sont-ils emparés furtivement de toi, et ont-ils fait passer le Jourdain au roi, à sa maison, à tous les gens de David avec lui?"
Sì wò ó, gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì tọ ọba wá, wọ́n sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí àwọn arákùnrin wa àwọn ọkùnrin Juda fi jí ọ kúrò, tí wọ́n sì fi mú ọba àti àwọn ará ilé rẹ̀ gòkè odò Jordani, àti gbogbo àwọn ènìyàn Dafidi pẹ̀lú rẹ?”
42 Les hommes de Juda répondirent ensemble à ceux d’Israël: "C’Est que le roi nous est plus proche; pourquoi donc la chose vous fâche-t-elle? Avons-nous rien mangé de lui? Nous a-t-il fait quelque libéralité?"
Gbogbo ọkùnrin Juda sì dá àwọn ọkùnrin Israẹli lóhùn pé, “Nítorí pé ọba bá wa tan ni; èéṣe tí ẹ̀yin fi bínú nítorí ọ̀ràn yìí? Àwa jẹ nínú oúnjẹ ọba rárá bí? Tàbí ó fi ẹ̀bùn kan fún wa bí?”
43 Et ceux d’Israël répliquèrent à ceux de Juda: "Nous avons dix fois plus de droits que vous sur le roi et sur David lui-même; pourquoi donc nous avez-vous traités avec dédain, et notre parole, qui a été la première, ne nous a-t-elle pas valu de ramener le roi?…" Mais les discours des hommes de Juda furent plus violents encore que ceux des hommes d’Israël.
Àwọn ọkùnrin Israẹli náà sì dá àwọn ọkùnrin Juda lóhùn pé, “Àwa ní ipá mẹ́wàá nínú ọba, àwa sì ní nínú Dafidi jù yín lọ, èéṣì ṣe tí ẹ̀yin kò fi kà wá sí, tí ìmọ̀ wa kò fi ṣáájú láti mú ọba wa padà?” Ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Juda sì le ju ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Israẹli.

< 2 Samuel 19 >