< 2 Rois 3 >

1 Joram, fils d’Achab, monta sur le trône d’Israël, à Samarie, la dix-huitième année du règne de Josaphat, roi de Juda; il régna douze ans.
Jehoramu ọmọ Ahabu sì di ọba Israẹli ní Samaria ní ọdún kejìdínlógún ti Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjìlá.
2 Il fit ce qui déplaît aux yeux de l’Eternel, toutefois, moins que son père et que sa mère; c’est ainsi qu’il fit enlever la statue de Baal érigée par son père.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti baba rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Baali tí baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
3 Mais il suivit, sans s’en écarter, les voies perverses de Jéroboam, fils de Nebat, qui avait induit Israël au péché.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ti fi Israẹli bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.
4 Mécha, roi de Moab, était riche en troupeaux: il payait au roi d’Israël un tribut de cent, mille agneaux et de cent mille béliers pourvus de leur laine.
Nísinsin yìí Meṣa ọba Moabu ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Israẹli pẹ̀lú ọ̀kẹ́ márùn-ún ọ̀dọ́-àgùntàn àti pẹ̀lú irun ọ̀kẹ́ márùn-ún àgbò.
5 Mais à la mort d’Achab, le roi de Moab fit défection au roi d’Israël.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ikú Ahabu, ọba Moabu ṣọ̀tẹ̀ lórí ọba Israẹli.
6 Aussitôt, Joram quitta Samarie et passa en revue tout Israël.
Lásìkò ìgbà yìí ọba Jehoramu jáde kúrò ní Samaria ó sì yí gbogbo Israẹli ní ipò padà.
7 Puis il se décida à envoyer le message suivant à Josaphat, roi de Juda: "Le roi de Moab s’est révolté contre moi. Veux-tu aller en guerre avec moi contre Moab?" Il répondit: "J’Irai; toi et moi, ton peuple et mon peuple, tes chevaux et les miens, c’est tout un.
Ó sì ránṣẹ́ yìí sí Jehoṣafati ọba Juda pé, “Ọba Moabu sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi láti lọ bá Moabu jà?” Ọba Juda sì dáhùn pé, “Èmi yóò lọ pẹ̀lú rẹ. Èmi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà, ènìyàn rẹ bí ènìyàn mi, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
8 Quel chemin prendrons-nous? demanda Joram. La route du désert iduméen," répondit Josaphat.
“Nípa ọ̀nà wo ni àwa yóò gbà dojúkọ wọ́n?” Ó béèrè. “Lọ́nà aginjù Edomu,” ó dáhùn.
9 Le roi d’Israël, le roi de Juda et le roi d’Edom entrèrent donc en campagne. Mais, après sept jours de marche, l’eau manqua aux troupes et aux bêtes qui les suivaient.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli jáde lọ pẹ̀lú ọba Juda àti ọba Edomu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n yíká fún ọjọ́ méje. Àwọn ọmọ-ogun wọn kò ní omi púpọ̀ fún ara wọn tàbí fún ẹranko tí ó wà pẹ̀lú wọn.
10 Le roi d’Israël s’écria: "Hélas! Est-ce que l’Eternel aurait fait appel à ces trois rois pour les livrer aux mains de Moab!"
“Kí ni?” ọba Israẹli kígbe sókè. “Ṣé Olúwa pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́?”
11 Josaphat dit: "N’Y a-t-il point ici de prophète de Dieu auprès de qui nous puissions consulter le Seigneur?" Un des serviteurs du roi d’Israël répondit: "Il se trouve ici Elisée, fils de Chefat, qui a versé l’eau sur les mains d’Elie.
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?” Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Israẹli dáhùn pé, “Eliṣa ọmọ Ṣafati wà níbí. Ó máa sábà bu omi sí ọwọ́ Elijah.”
12 La parole divine est sur ses lèvres, dit Josaphat." Le roi d’Israël, Josaphat et le roi d’Edom se rendirent donc auprès de lui.
Jehoṣafati wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati àti ọba Edomu sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.
13 Mais Elisée apostropha ainsi le roi d’Israël: "Qu’y a-t-il de commun entre toi et moi? Adresse-toi aux prophètes de ton père et aux prophètes de ta mère." Le roi d’Israël répondit: "Laissons cela. Est-ce que l’Eternel a fait appel à ces trois rois pour les livrer aux mains de Moab?"
Eliṣa wí fún ọba Israẹli pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì baba rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.” Ọba Israẹli dá a lóhùn, “Rárá, nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́.”
14 Elisée reprit: "Vive l’Eternel-Cebaot, que je sers! Si je ne respectais la personne de Josaphat, roi de Juda, je ne t’accorderais pas même un regard.
Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jehoṣafati ọba Juda, èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ.
15 Eh bien! Amenez-moi un musicien." Tandis que celui-ci jouait de son instrument, l’esprit du Seigneur s’empara du prophète,
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú wá fún mi ohun èlò orin olókùn.” Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Eliṣa.
16 et il dit: "Ainsi a parlé l’Eternel: Creusez dans cette vallée fossés et fossés.
Ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Jẹ́ kí àfonífojì kún fún ọ̀gbun.’
17 Car (telle est la parole de l’Eternel), vous ne sentirez pas de vent et vous ne verrez pas de pluie, et cependant cette vallée sera remplie d’eau, et vous aurez à boire, vous, vos troupeaux et vos bêtes.
Nítorí èyí ni Olúwa wí, o kò ní í rí afẹ́fẹ́ tàbí òjò, bẹ́ẹ̀ ni àfonífojì yìí yóò kún pẹ̀lú omi, àti ìwọ àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹran yóò mu.
18 Mais c’est encore trop peu aux yeux de l’Eternel: il livrera aussi Moab en votre pouvoir.
Èyí jẹ́ ohun tí kò lágbára níwájú Olúwa, yóò sì fi Moabu lé e yín lọ́wọ́ pẹ̀lú.
19 Vous détruirez toute ville forte, toute ville de marque; vous abattrez tout arbre fruitier, vous comblerez toute source d’eau, et toute bonne terre, vous la ruinerez en la couvrant de pierres."
Ìwọ yóò sì bi gbogbo ìlú olódi àti gbogbo àgbà ìlú ṣubú. Ìwọ yóò sì gé gbogbo igi dáradára ṣubú, dá gbogbo orísun omi dúró, kí o sì pa gbogbo pápá dáradára pẹ̀lú òkúta run.”
20 Le lendemain matin, à l’heure de l’oblation, l’eau arriva tout à coup du côté d’Edom, et le sol en fut inondé.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ní àsìkò ẹbọ, níbẹ̀ ni omí sàn láti ọ̀kánkán Edomu! Ilé náà sì kún pẹ̀lú omi.
21 Tous les Moabites, ayant appris que les rois venaient porter la guerre chez eux, s’étaient rassemblés en armes, tous les hommes en âge de ceindre l’épée et au delà et s’étaient postés sur la frontière.
Nísinsin yìí gbogbo ará Moabu gbọ́ pé àwọn ọba tí dé láti bá wọn jà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn, ọmọdé àti àgbà tí ó lè ja ogun wọn pè wọ́n sókè wọ́n sì dúró ní etí ilẹ̀.
22 S’Étant levés au matin, comme le soleil brillait au-dessus des eaux, celles-ci apparurent dé loin aux Moabites rouges comme du sang.
Nígbà tí wọ́n dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, oòrùn ti tàn sí orí omi náà sí àwọn ará Moabu ní ìkọjá ọ̀nà, omi náà sì pupa bí ẹ̀jẹ̀.
23 Ils s’écrièrent: "C’Est du sang! Assurément, les rois se sont pris de querelle, ils se sont entr’égorgés: au butin donc, Moab!"
“Ẹ̀jẹ̀ ni èyí!” wọ́n wí pé, “Àwọn ọba wọ̀nyí lè ti jà kí wọn sì pa ara wọn ní ìpakúpa. Nísinsin yìí sí àwọn ìkógun Moabu!”
24 Ils se précipitèrent sur le camp des Israélites, mais ceux-ci se levèrent, battirent les Moabites, les mirent en fuite et en firent un grand carnage:
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ará Moabu dé sí ibùdó ti Israẹli, àwọn ará Israẹli dìde, wọ́n sì kọlù wọ́n títí tí wọ́n fi sálọ. Àwọn ará Israẹli gbógun sí ilẹ̀ náà wọ́n sì pa Moabu run.
25 Ils détruisirent les villes; chacun lança sa pierre sur les terres fertiles, qui en furent couvertes; ils comblèrent les sources et abattirent les arbres fruitiers. Il ne resta pierre sur pierre qu’à Kir-Haréset, qui fut assaillie, à son tour, de tous côtés par les frondeurs et ruinée.
Wọ́n sì wọ gbogbo ìlú náà olúkúlùkù ènìyàn, wọ́n ju òkúta sí gbogbo ohun dáradára orí pápá títí tí ó fi run. Wọ́n sì dá gbogbo orísun omi dúró wọ́n sì gé gbogbo orísun dáradára. Kiri-Hareseti nìkan ni wọ́n fi òkúta rẹ̀ sílẹ̀ ní ààyè rẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ológun pẹ̀lú kànnàkànnà yíká, wọ́n sì kọlù ìlú náà.
26 Le roi de Moab, se voyant trop faible pour lutter, se mit à la tête de sept cents hommes, l’épée nue, afin de se frayer un chemin jusqu’au roi d’Edom; mais ils n’y réussirent point.
Nígbà tí ọba Moabu rí i wí pé ogun náà le ju ti òun lọ, ó mú idà pẹ̀lú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ọkùnrin onídà láti jà pẹ̀lú ọba Edomu, ṣùgbọ́n wọn kò yege.
27 Alors il prit l’aîné de ses fils, l’héritier du trône, et l’immola en holocauste au haut des remparts. Aussitôt, une grande colère éclata contre Israël, qui dut se retirer et rentrer dans son pays.
Nígbà náà ó mú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀, tí kò bá jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọba, ó sì fi rú ẹbọ sísun ní orí ògiri ìlú. Wọ́n sì bínú lórí Israẹli púpọ̀púpọ̀; wọ́n yọ́ kúrò wọ́n sì padà sí ìlú wọn.

< 2 Rois 3 >