< 2 Rois 10 >

1 Or, Achab avait soixante-dix fils à Samarie. Jéhu écrivit des lettres qu’il envoya à Samarie, aux chefs de Jezreël, aux anciens et aux précepteurs des enfants d’Achab, et qui étaient ainsi conçues:
Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
2 "Donc, à l’arrivée de cette épître, comme vous avez avec vous les fils de votre maître, les chars, la cavalerie, une ville fortifiée et des armes,
“Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
3 choisissez parmi les fils de votre maître le meilleur et le plus digne, placez-le sur le trône de son père et combattez pour la maison de votre seigneur."
yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
4 Ces gens furent saisis d’une extrême frayeur et se dirent: "Eh quoi! Les deux rois n’ont pu lui résister, comment lui résisterions-nous?"
Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
5 Le préfet du palais, celui de la ville, les anciens et les précepteurs mandèrent à Jéhu: "Nous sommes tes serviteurs, et tout ce que tu diras, nous l’exécuterons; nous n’élirons aucun roi: fais ce que bon te semble."
Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
6 Il leur écrivit une seconde lettre, contenant ces mots: "Si vous êtes pour moi et voulez m’obéir, prenez les têtes des fils de votre maître et rendez-vous près de moi, demain, à Jezreël". Or, les fils du roi étaient au nombre de soixante-dix, et c’étaient les grands de la ville qui les élevaient.
Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
7 Au reçu de cette lettre, ils s’emparèrent des fils du roi et égorgèrent tous les soixante-dix. Puis ils mirent leurs têtes dans des paniers et les lui envoyèrent à Jezreël.
Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
8 Un émissaire étant venu lui annoncer qu’on avait apporté les têtes des princes, il commanda: "Mettez-les en deux tas, à l’entrée de la porte, jusqu’au matin."
Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
9 Le matin, étant sorti, il s’approcha et dit à tout le peuple: "Vous êtes sans reproche. Voici, je me suis révolté contre mon maître et l’ai tué; mais tous ceux-là, qui les a frappés?
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
10 Sachez donc qu’il ne tombera à terre aucune des paroles prononcées par le Seigneur contre la maison d’Achab. C’Est le Seigneur qui a accompli ce qu’il avait déclaré par l’intermédiaire de son serviteur Elie."
Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
11 Jéhu frappa ensuite tous ceux qui restaient à Jezreël de la famille d’Achab, tous ses grands, ses familiers et ses prêtres; il n’en laissa pas échapper un seul.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
12 Puis il se mit en route et se dirigea vers Samarie. A Beth-Eked-Haroïm, qui se trouvait sur la route,
Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
13 Jéhu rencontra les frères d’Achazia, roi de Juda, et leur demanda: "Qui êtes-vous?" Ils répondirent: "Nous sommes les frères d’Achazia, roi de Juda, nous sommes venus pour saluer les fils du roi et de la reine".
Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
14 Alors il commanda: "Qu’on les saisisse vivants!" et on les saisit vivants. Puis, on les jeta, égorgés, dans la citerne de Beth-Eked au nombre de quarante-deux; il n’en laissa subsister aucun.
“Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
15 Parti de là, il rencontra Jonadab, fils de Rêkhab, venant à lui; il le salua et lui dit: "As-tu pour moi d’aussi bons sentiments que j’en ai pour toi? Tout autant, répondit Jonadab. Donne-moi ta main." Jonadab lui tendit la main, et Jéhu le fit monter près de lui sur le char:
Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
16 "Viens avec moi, dit-il, et reconnais mon zèle pour le Seigneur." Et il le fit asseoir dans son char.
Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
17 Arrivé à Samarie, il fit exécuter tous ceux qui étaient restés de la famille d’Achab à Samarie, jusqu’à extinction complète, accomplissant ainsi la parole du Seigneur adressée à Elie.
Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
18 Jéhu assembla ensuite tout le peuple et lui dit: "Achab a adoré un peu Baal; Jéhu l’adorera beaucoup.
Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
19 Donc, qu’on me convoque tous les prophètes de Baal, tous ses adorateurs et tous ses prêtres; que personne ne manque, car, sur mon ordre, il y aura grand sacrifice en l’honneur de Baal; quiconque y manquera périra." Jéhu agissait ainsi par ruse, pour exterminer tous les adorateurs de Baal.
Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
20 Jéhu ayant ainsi fait proclamer une fête en l’honneur de Baal, on fit les convocations.
Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
21 Jéhu envoya des émissaires dans tout Israël, et tous les adorateurs de Baal arrivèrent; il n’en resta pas un qui ne vînt. Ils pénétrèrent dans le temple de Baal, qui fut rempli de toutes parts.
Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
22 Alors il dit au préposé du vestiaire: "Sors des vêtements pour tous les adorateurs de Baal." L’Homme sortit les vêtements.
Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
23 Puis Jéhu et Jonadab, fils de Rêkhab, entrèrent dans le temple de Baal. Jéhu dit aux adorateurs de Baal: "Enquérez-vous et voyez s’il n’y a pas avec vous de serviteurs de l’Eternel, car seuls les adorateurs de Baal doivent se trouver ici."
Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
24 Ils se mirent à offrir des sacrifices et des holocaustes. Or, Jéhu avait posté au dehors quatre-vingts hommes, disant: "Quiconque échappera de ceux que je livre en vos mains, votre vie sera la rançon de la sienne."
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
25 Lorsqu’on eut terminé l’offrande des sacrifices, Jéhu dit aux gardes et aux officiers: "Entrez, tuez-les, que personne ne sorte!" Et ils les firent passer au fil de l’épée. Après avoir jeté leurs cadavres, les gardes et les officiers poussèrent jusqu’à la ville du temple de Baal.
Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
26 Ils firent sortir les cippes du temple de Baal et les brûlèrent.
Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
27 Ils abattirent aussi la statue de Baal, renversèrent le temple de Baal et le convertirent en cloaque, lequel existe encore aujourd’hui.
Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
28 Jéhu extirpa ainsi Baal des rangs d’Israël.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
29 Seulement Jéhu ne répudia pas les péchés de Jéroboam, fils de Nebat, qui avait entraîné à l’idolâtrie Israël, à savoir les veaux d’or qui étaient à Béthel et à Dan.
Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
30 Le Seigneur dit à Jéhu: "Pour ta bonne pensée d’avoir accompli ce qui me plaisait et pour avoir fait à Achab tout ce que j’avais décidé, quatre générations de tes enfants siégeront sur le trône d’Israël."
Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
31 Toutefois, Jéhu ne prit pas garde de suivre de tout son cœur la loi de l’Eternel, Dieu d’Israël; il n’évita pas les fautes de Jéroboam, qui avait fait pécher Israël.
Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
32 En ce temps, l’Eternel commença à amoindrir Israël. Hazaël les mit en déroute sur toute la frontière d’Israël,
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
33 enlevant, depuis le Jourdain à l’est, tout le pays du Galaad, les territoires de Gad, Ruben et Manassé, depuis Aroër sur le torrent d’Arnôn, le Galaad et le Basan.
Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
34 Le reste de l’histoire de Jéhu, toutes ses actions et ses exploits, tout cela est consigné dans le livre des annales des rois d’Israël.
Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
35 Jéhu s’endormit avec ses pères, et on l’ensevelit à Samarie. A sa place régna Joachaz, son fils.
Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
36 La durée du règne de Jéhu sur Israël à Samarie avait été de vingt-huit ans.
Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.

< 2 Rois 10 >