< 2 Chroniques 7 >

1 Lorsque Salomon eut terminé sa prière, le feu descendit du ciel, consuma l’holocauste et les autres sacrifices, et la gloire de l’Eternel remplit la maison.
Nígbà tí Solomoni sì ti parí àdúrà, iná sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó ẹbọ sísun àti ẹbọ, ògo Ọlọ́run sì kún ilé Olúwa.
2 Les prêtres ne purent entrer dans la maison du Seigneur, parce que la majesté divine remplissait cette maison du Seigneur.
Àwọn àlùfáà kò sì le wo ilé Olúwa náà nítorí pé ògo Olúwa kún un.
3 Tous les enfants d’Israël, à la vue du feu descendu du ciel et de la gloire de l’Eternel reposant sur la maison, se mirent à genoux sur les dalles, la face contre terre, se prosternèrent et rendirent hommage au Seigneur, en chantant: "Car il est bon, car sa grâce est éternelle!"
Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí iná tí ó ń sọ̀kalẹ̀ àti ògo Olúwa lórí ilé Olúwa náà, wọ́n sì kúnlẹ̀ lórí eékún wọn pẹ̀lú ojú ni dídàbolẹ̀, wọ́n sì sin Olúwa, wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa wí pé, “Nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ sì dúró títí láéláé.”
4 Le roi Salomon et tout le peuple offrirent des sacrifices devant le Seigneur.
Nígbà náà ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn sì rú ẹbọ níwájú Olúwa.
5 Quant aux sacrifices qu’immola le roi Salomon, ils consistèrent en vingt-deux mille taureaux et cent vingt mille brebis. Ainsi fut inaugurée la maison de Dieu par le roi et tout le peuple.
Ọba Solomoni sì rú ẹbọ ti ẹgbẹ̀rún méjìlélógún, orí màlúù àti àgùntàn àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn àti ẹranko. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn ya ilé Ọlọ́run sí mímọ́.
6 Les prêtres se tenaient à leur poste ainsi que les Lévites, qui étaient munis des instruments de musique sacrée, créés par le roi David, et rendaient hommage au Seigneur, en chantant: "Car sa grâce est éternelle!" d’après le cantique de David confié à leurs soins. Les prêtres sonnaient de la trompette en face d’eux, et tous les Israélites étaient debout.
Àwọn àlùfáà dúró ní ààyè wọn, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi ti ṣe pẹ̀lú ohun èlò orin Olúwa, tí ọba Dafidi ti ṣe fún ìyìn Olúwa àti tí á lò nígbà tí ó dúpẹ́, wí pé, “Àánú rẹ̀ sì dúró láéláé,” níwájú àwọn ọmọ Lefi, àwọn àlùfáà sì fọn ìpè, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dúró.
7 Salomon consacra l’intérieur du parvis, qui s’étend devant la maison du Seigneur, pour qu’on pût y offrir les holocaustes et les parties grasses des rémunératoires; car l’autel de cuivre construit par Salomon ne pouvait contenir à la fois holocaustes, oblations et graisses.
Solomoni sì yà àgbàlá níwájú ilé Olúwa sọ́tọ̀, níbẹ̀ sì ni ó ti ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àti ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ó ti ṣe kò lè gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọ̀rá náà.
8 En ce temps-là, Salomon célébra la fête de Souccot durant sept jours, tout Israël étant avec lui, une assemblée extrêmement nombreuse accourue, depuis Hemath jusqu’au torrent d’Egypte.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àsè ní àkókò náà fún ọjọ́ méje àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ àti ìjọ ènìyàn ńlá, àwọn ènìyàn láti Lebo-Hamati títí dé odò Ejibiti.
9 Le huitième jour on fit une fête de clôture. En effet, on avait procédé à la dédicace de l’autel pendant sept jours et célébré la fête de Souccot pendant sept jours.
Ní ọjọ́ kẹjọ, wọ́n sì pe ìjọ ènìyàn jọ nítorí tí wọ́n pe àpèjẹ ìyàsímímọ́ ti orí pẹpẹ fún ọjọ́ méje àti àsè náà fún ọjọ́ méje sí i.
10 Le vingt-troisième jour du septième mois, Salomon renvoya dans ses foyers le peuple, heureux et le cœur réjoui de toutes les grâces dont le Seigneur avait comblé David, Salomon et Israël, son peuple.
Ní ọjọ́ kẹtàlélógún tí oṣù keje, ó sì rán àwọn ènìyàn padà sí ilé wọn, pẹ̀lú ayọ̀ àti ìdùnnú nínú wọn fún ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi àti Solomoni, àti fún àwọn ènìyàn Israẹli.
11 Salomon acheva ainsi la maison du Seigneur et la demeure royale; il accomplit heureusement tout ce qu’il avait projeté de faire pour la maison du Seigneur et pour son propre palais.
Nígbà tí Solomoni ti parí ilé Olúwa àti ibi ilé ọba, nígbà tí ó sì ti ṣe àṣeyọrí láti gbé jáde gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn láti ṣe nínú ilé Olúwa àti nínú ilé òun tìkára rẹ̀,
12 Alors le Seigneur apparut à Salomon pendant la nuit, et lui dit: "J’Accueille ta prière, et je fais choix de cette maison comme d’un lieu de sacrifices.
Olúwa sì farahàn Solomoni ní òru ó sì wí pé: “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti yàn ibí yìí fún ara mi gẹ́gẹ́ bí ilé fún ẹbọ.
13 S’Il arrive que je ferme le ciel pour qu’il n’y ait point de pluie, que j’ordonne aux sauterelles de ravager le pays ou que je déchaîne une épidémie contre mon peuple,
“Nígbà tí mo bá sé ọ̀run kí ó ma bá à sí òjò, tàbí láti pàṣẹ fún eṣú láti jẹ ilẹ̀ náà run tàbí rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín àwọn ènìyàn mi,
14 et qu’alors mon peuple, auquel mon nom se trouve associé, s’humilie, m’adresse des prières, recherche ma présence et abandonne ses mauvaises voies, à mon tour je l’exaucerai du haut du ciel, lui pardonnerai ses péchés et réparerai les ruines de son pays.
tí àwọn ènìyàn, tí a fi orúkọ mi pè, tí wọ́n bá rẹ ara wọn sílẹ̀, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì rí ojú mi, tí wọ́n sì yí kúrò nínú ọ̀nà búburú wọn, nígbà náà, èmi yóò gbọ́ láti ọ̀run, èmi yóò sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n èmi yóò sì wo ilẹ̀ wọn sàn.
15 Dès à présent, mes yeux seront ouverts et mes oreilles attentives aux prières prononcées en ce lieu.
Nísinsin yìí, ojú mi yóò sì là etí mi yóò sì là, sí àdúrà ọrẹ níbí yìí.
16 Dès à présent aussi, je choisis et sanctifie cette maison en y faisant régner mon nom à jamais, en y dirigeant constamment mes yeux et ma pensée.
Èmi sì ti yàn, èmi sì ti ya ilé yìí sí mímọ́ bẹ́ẹ̀ ni kí orúkọ mi kí ó le wà níbẹ̀ títí láéláé.
17 Pour toi, si tu marches devant moi comme a marché David, ton père, en te conformant à tout ce que je t’ai prescrit, en gardant mes lois et mes statuts,
“Ní ti bí ìwọ bá rìn níwájú mi gẹ́gẹ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, tí o sì ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ, tí ìwọ sì ṣe àkíyèsí àṣẹ mi láti ọ̀run,
18 je maintiendrai le trône de ta royauté, en vertu du pacte que j’ai fait avec ton père David, en disant: "Jamais il ne manquera un des tiens pour régner sur Israël."
Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe pẹ̀lú Dafidi baba rẹ nígbà tí mo bá a dá májẹ̀mú wí pé, ìwọ kò ní fẹ́ ẹnìkan kù láti ṣe alákòóso lórí Israẹli.
19 Mais si vous vous égarez, si vous délaissez mes lois et mes préceptes que je vous ai donnés, et que vous alliez servir des dieux étrangers et vous prosterner devant eux,
“Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá yípadà tí o sì kọ òfin mi sílẹ̀ àti àṣẹ tí mo ti fi fún yín tí ẹ sì lọ sókè láti lọ sin ọlọ́run mìíràn tí ẹ sì bọ wọ́n,
20 je vous arracherai du pays que je vous avais donné; cette maison, que j’ai consacrée à mon nom, je la répudierai et j’en ferai la fable et la risée de toutes les nations;
nígbà náà ni èmi yóò fa Israẹli tu kúrò láti ilẹ̀ mi, èyí tí èmi ti fi fún wọn, èmi yóò sì kọ̀ ilé náà sílẹ̀ èyí tí èmi ti yà sọ́tọ̀ fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ṣe ọ̀rọ̀ òwe, n ó fi ṣe ẹlẹ́yà láàrín gbogbo ènìyàn,
21 et cette maison placée à un si haut rang ne produira plus que stupeur chez tout venant; et quand on dira: "Pourquoi le Seigneur a-t-il traité ainsi ce pays et ce temple?"
àti ní gbogbo àyíká ilé yìí nísinsin yìí, bẹ́ẹ̀ ni yóò di ohun ìtànjẹ; gbogbo àwọn tí ó bá sì kọjá níbẹ̀ ni yóò jáláyà, wọn yóò sì wí pé, ‘Kí ni ó dé tí Olúwa fì ṣe irú èyí sí ilẹ̀ yí àti sí ilé yìí?’
22 On répondra: "Parce qu’ils ont abandonné le Seigneur, Dieu de leurs pères, qui les avait délivrés de l’Egypte, ont adopté des divinités étrangères, les ont servies et adorées, c’est pour cela que le Seigneur a fait fondre sur eux tous ces malheurs."
Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run baba wọn ẹni tí ó mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti fi ọwọ́ gba ọlọ́run mìíràn mọ́ra, wọ́n bọ wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyí tí ó fi mú gbogbo ìjàǹbá náà wá sórí wọn.’”

< 2 Chroniques 7 >