< 2 Chroniques 32 >

1 Après ces événements et ces preuves de zèle, Sennachérib, roi d’Assyrie, vint envahir Juda, assiégea les villes fortes et prétendit les forcer pour s’en emparer.
Lẹ́yìn gbogbo èyí ti Hesekiah ti fi òtítọ́ ṣe, Sennakeribu ọba Asiria wá ó sì gbógun ti Juda. Ó gbógun ti àwọn ìlú ààbò, ó ń ronú láti ṣẹ́gun wọn fún ara rẹ̀.
2 Ezéchias, voyant que Sennachérib était venu avec l’intention d’attaquer Jérusalem,
Nígbà tí Hesekiah rí i pé Sennakeribu ti wá, àti pé ó fẹ́ láti dá ogun sílẹ̀ lórí Jerusalẹmu,
3 consulta ses chefs et ses héros sur l’idée de boucher les sources d’eau qui se trouvaient en dehors de la ville, et ils l’appuyèrent.
Ó gbèrò pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ láti di orísun omi ní ìta ìlú ńlá, wọ́n sì ràn án lọ́wọ́.
4 Alors ils se rassemblèrent en grand nombre et bouchèrent toutes les sources, ainsi que le torrent qui coulait dans le pays, en disant: "Pourquoi les rois d’Assyrie trouveraient-ils à leur arrivée quantité d’eau?"
Ọ̀pọ̀ ogun ọkùnrin péjọ, wọ́n sì dí gbogbo àwọn orísun àti àwọn omi tó ń sàn tí ó ń sàn gba ti ilẹ̀ náà. “Kí ni ó dé tí àwọn ọba Asiria fi wá tí wọ́n sì rí ọ̀pọ̀ omi?” Wọ́n wí.
5 Il s’enhardit et rebâtit toutes les brèches de la muraille; il suréleva les tours et l’autre muraille extérieure; il fortifia le Millo dans la cité de David et fabriqua un grand nombre d’armes de trait et des boucliers.
Nígbà náà ó ṣiṣẹ́ gidigidi ní títún gbogbo ara ògiri tí ó ti bàjẹ́ ṣe, ó sì ń kọ́ àwọn ilé ìṣọ́ gíga sókè rẹ̀. Ó kọ́ ògiri mìíràn sí ìta. Ó sì tún pẹ̀lú ibi ìtẹ́jú ilé ní ti ìlú ńlá Dafidi. Ó ṣe ọ̀pọ̀ iye ohun ìjà àti àwọn àpáta.
6 Il établit des chefs militaires à la tête du peuple, les assembla autour de lui sur la place à la porte de la ville et les encouragea en ces termes:
Ó yan àwọn ìjòyè ológun sórí àwọn ènìyàn, ó sì pè wọ́n jọ, níwájú rẹ̀ ní ìbámu ní ìlú ńlá ti Dafidi. Ó sì ki wọ́n láyà pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí:
7 "Soyez forts et courageux, n’ayez crainte et ne vous laissez point effrayer par le roi d’Assyrie et toute la foule qui raccompagne, car il y a avec nous quelqu’un de plus grand qu’avec lui.
“Ẹ jẹ́ alágbára, àti kí ẹ sì ní ìgboyà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí ní ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn nítorí tí ọba Asiria àti ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí agbára ńlá wà pẹ̀lú wa ju òun lọ.
8 Avec lui est un bras de chair; avec nous est l’Eternel, notre Dieu, pour nous assister et combattre nos combats", et le peuple s’en rapporta aux paroles d’Ezéchias, roi de Juda.
Agbára ẹran-ara nìkan ni ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ṣùgbọ́n, Olúwa Ọlọ́run wa pẹ̀lú wa láti ràn wá lọ́wọ́ àti láti ja ìjà wa.” Àwọn ènìyàn sì ní ìgboyà láti ara ohun tí Hesekiah ọba Juda wí.
9 Après cela Sennachérib, roi d’Assyrie, envoya ses serviteurs à Jérusalem, tandis qu’il était lui-même devant Lakhich avec toutes ses forces, vers Ezéchias, roi de Juda, et vers tous ceux de Juda qui se trouvaient à Jérusalem pour leur dire:
Lẹ́yìn ìgbà tí Sennakeribu ọba Asiria àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ ń gbógun sí Lakiṣi. Ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú iṣẹ́ yí fún Hesekiah ọba Juda àti fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda tí ó wà níbẹ̀:
10 "Ainsi parle Sennachérib, roi d’Assyrie: En quoi mettez-vous votre confiance pour rester ainsi bloqués dans Jérusalem?
“Èyí ni ohun tí Sennakeribu ọba Asiria wí, ‘Lórí kí ni ẹ̀yin gbé ìgbẹ́kẹ̀lé yín lé, tí ẹ̀yin fi dúró sí Jerusalẹmu lábẹ́ ìgbógun sí?’
11 Ne voyez-vous pas qu’Ezéchias vous abuse pour vous livrer à la mort par la famine et par la soif, quand il vous dit: L’Eternel, notre Dieu, nous sauvera de la main du roi d’Assyrie?
Nígbà tí Hesekiah wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run wa yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria,’ ó ń ṣì yín tọ́ ṣọ́nà, kí ẹ bá lè kú fún ebi àti òǹgbẹ.
12 N’Est-ce pas lui, Ezéchias, qui a fait disparaître ses hauts lieux et ses autels et qui a parlé en ces termes à Juda et à Jérusalem: Devant un seul autel vous vous prosternerez et ferez fumer l’encens?
Ṣé Hesekiah fúnra rẹ̀ kò mú àwọn ọlọ́run ibi gíga àti àwọn pẹpẹ kúrò, tí ó ń wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ kan àti láti sun àwọn ẹbọ lórí rẹ̀’?
13 Ne savez-vous pas ce que j’ai fait, moi et mes pères, à tous les peuples des diverses contrées? Est-ce que les dieux des nations de ces contrées ont jamais pu soustraire leur pays à mon pouvoir?
“Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ ohun tí èmi àti àwọn baba mi ti ṣe sí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn? Ǹjẹ́ àwọn Ọlọ́run tí àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn ní agbára láti gba ilẹ̀ wọn kúrò lọ́wọ́ mi?
14 De tous les dieux de ces nations qu’ont anéanties mes pères, quel est celui qui a pu soustraire son peuple à mon pouvoir? Et votre Dieu pourrait vous arracher à ma domination!
Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí tí àwọn baba mi ti parun, tí ó le gbà ènìyàn rẹ̀ lọ́wọ́ mi, tí Ọlọ́run yín yóò fi le gbà yín lọ́wọ́ mi?
15 Et maintenant, ne vous laissez pas abuser par Ezéchias ni séduire ainsi, ne croyez pas en lui, car aucun dieu d’aucune nation et royaume ne pourra soustraire son peuple à ma domination et à celle de mes pères, à plus forte raison votre Dieu ne pourra-t-il vous soustraire à mon pouvoir."
Nísinsin yìí, ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ó tàn yín àti ṣì yín tọ́ ṣọ́nà báyìí. Ẹ má ṣe gbà á gbọ́, nítorí tí kò sí ọlọ́run orílẹ̀-èdè mìíràn tàbí ìjọba tí ó ní agbára láti gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi tàbí lọ́wọ́ àwọn baba mi, mélòó mélòó wa ni Ọlọ́run yín tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ mi!”
16 Ses serviteurs continuèrent à déblatérer contre le Seigneur Dieu et contre Ezéchias, son serviteur.
Àwọn ìjòyè Sennakeribu sọ̀rọ̀ síwájú sí i ní ìlòdì sí Olúwa Ọlọ́run àti sí ìránṣẹ́ rẹ̀ Hesekiah.
17 Il avait écrit aussi des libelles injurieux pour l’Eternel, Dieu d’Israël, et s’exprimait sur lui en ces termes: "Tels les dieux des contrées qui n’ont pu soustraire leur peuple à mon pouvoir, ainsi le Dieu d’Ezéchias ne soustraira point son peuple à mon pouvoir."
Ọba pẹ̀lú sì kọ àwọn ìwé ní bíbú Olúwa Ọlọ́run Israẹli àti ní sísọ èyí ní ìlòdì sí: “Ní gẹ́gẹ́ bí àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn kò ṣe gba àwọn ènìyàn wọn kúrò lọ́wọ́ mi. Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run Hesekiah kì yóò gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi.”
18 Ils s’adressaient à haute voix en judéen au peuple de Jérusalem qui était sur le rempart pour les effrayer et les troubler afin de s’emparer de la ville.
Lẹ́yìn náà wọ́n pè jáde ní èdè Heberu sí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu tí ó wà lára ògiri, láti dá ọjọ́ fún wọn, ki wọn kí ó lè fi agbára mú ìlú náà.
19 Ils parlaient du Dieu de Jérusalem comme des dieux des nations de la terre, œuvre des mains de l’homme.
Wọ́n sọ̀rọ̀ nípa Ọlọ́run Jerusalẹmu bí wọ́n ti ṣe nípa àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn mìíràn ti àgbáyé, iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn.
20 Alors le roi Ezéchias et le prophète Isaïe, fils d’Amoç, se mirent à prier à ce sujet et ils implorèrent le Ciel.
Ọba Hesekiah àti wòlíì Isaiah ọmọ Amosi sọkún jáde nínú àdúrà sí ọ̀run nípa èyí.
21 L’Eternel envoya un ange, qui extermina tous les guerriers, princes et chefs, dans le camp du roi d’Assyrie, lequel s’en revint, plein de confusion, dans son pays. Il entra dans le temple de son dieu et là, il tomba sous le glaive de sa propre progéniture.
Olúwa sì ran angẹli tí ó pa gbogbo àwọn ọmọ-ogun àti àwọn adarí àti àwọn ìjòyè tí ó wà nínú àgọ́ ọba Asiria run. Bẹ́ẹ̀ ni ó padà sí ilẹ̀ rẹ̀ ní ìtìjú. Nígbà tí ó sì lọ sínú ilé ọlọ́run rẹ̀, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.
22 C’Est ainsi que l’Eternel sauva Ezéchias et les habitants de Jérusalem de la main de Sennachérib, roi d’Assyrie, et de la main de tous leurs ennemis et les protégea tout alentour.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yọ Hesekiah àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ Sennakeribu ọba Asiria àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn mìíràn. Ó tọ́jú wọn ní gbogbo ọ̀nà.
23 Puis, beaucoup apportèrent une offrande à l’Eternel à Jérusalem et des présents à Ezéchias, roi de Juda; et il fut élevé après cela aux yeux de tous les peuples.
Ọ̀pọ̀ mú ọrẹ wá sí Jerusalẹmu fún Olúwa àti àwọn ẹ̀bùn iyebíye fún Hesekiah ọba Juda. Ó sì gbéga lójú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè lẹ́yìn náà.
24 En ce temps-là Ezéchias fut atteint d’une maladie mortelle. Il implora le Seigneur, qui lui parla et lui accorda un prodige.
Ní ọjọ́ wọ́n nì Hesekiah ṣe àárẹ̀, ó sì dójú ikú. Ó gbàdúrà sí Olúwa tí ó dá a lóhùn, tí ó sì fún un ní àmì àgbàyanu.
25 Mais Ezéchias n’agit pas comme il aurait dû en retour de cette faveur, car son cœur s’enorgueillit, et la colère divine fut excitée contre lui et contre Juda et Jérusalem.
Ṣùgbọ́n ọkàn Hesekiah ṣe ìgbéraga, kò sì kọbi ara sí i inú rere tí a fihàn án. Nítorí náà, ìbínú Olúwa wà lórí rẹ̀ àti lórí Juda àti Jerusalẹmu.
26 Mais Ezéchias s’humilia dans son cœur orgueilleux, lui et les habitants de Jérusalem, et la colère de l’Eternel ne les atteignit pas du temps d’Ezéchias.
Nígbà náà ni Hesekiah ronúpìwàdà ní ti ìgbéraga ọkàn rẹ̀, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu sì ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí náà, ìbínú Olúwa kò wá sí orí wọn ní ìgbà àwọn ọjọ́ Hesekiah.
27 Ezéchias eut des richesses et des honneurs en grande abondance; il se fit des trésors pour l’argent, l’or et les pierres précieuses, pour les aromates, les boucliers et tous les objets de prix,
Hesekiah ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá àti ọlá, ó sì ṣe àwọn ilé ìṣúra fún fàdákà àti wúrà rẹ̀ àti fún àwọn òkúta iyebíye rẹ̀, àwọn tùràrí olóòórùn dídùn àwọn àpáta àti gbogbo oríṣìí nǹkan iyebíye.
28 des magasins pour les récoltes de blé, pour le moût et l’huile, des étables pour tous les animaux domestiques et des troupeaux pour les étables.
Ó kọ́ àwọn ilé pẹ̀lú láti tọ́jú àwọn ọkà àwọn tí wọ́n ka, ọtí tuntun àti òróró; ó sì ṣe àwọn àtíbàbà fún oríṣìí àwọn ẹran ọ̀sìn àti àwọn àṣémọ́ fun àwọn ọ̀wọ̀ ẹran.
29 Il se bâtit des villes, s’acquit du menu et du gros bétail en quantité, car Dieu lui avait donné des richesses très considérables.
Ó kọ́ àwọn ìletò, ó sì gba ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran, nítorí tí Ọlọ́run ti fún un ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá.
30 Ce fut Ezéchias qui boucha l’issue supérieure des eaux du Ghihôn et les dirigea par en bas du côté occidental vers la cité de David, et Ezéchias réussit dans toutes ses entreprises.
Hesekiah ni ó dí ojú ìṣúra apá òkè ti orísun Gihoni. Ó sì gbe gba ìsàlẹ̀ sí ìhà ìwọ oòrùn ìlú ńlá ti Dafidi. Ó ṣe àṣeyọrí rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé.
31 Pourtant, dans l’affaire des conseillers des princes de Babylone qui lui avaient envoyé une ambassade pour s’informer du prodige qui avait eu lieu dans le pays, Dieu l’abandonna afin de le mettre à l’épreuve et connaître tous les sentiments de son cœur.
Ṣùgbọ́n nígbà tí a rán àwọn oníṣẹ́ ọba wá láti Babeli láti bi í lérè nípa àmì ìyanu tí ó ṣẹlẹ̀ nì, Ọlọ́run fi sílẹ̀ láti dán an wò àti láti mọ gbogbo nǹkan tí ó wà lọ́kàn rẹ̀.
32 Pour les autres faits concernant Ezéchias et ses mérites, tout cela est consigné dans les prophéties d’Isaïe, fils d’Amoç et dans le livre des rois de Juda et d’Israël.
Gbogbo iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Hesekiah àti àwọn ìṣe rẹ̀, ìfarajì rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìran wòlíì Isaiah ọmọ Amosi nínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli
33 Ezéchias s’endormit avec ses pères; on l’ensevelit sur la montée des tombeaux de la famille de David, et des honneurs lui furent rendus à sa mort par tout Juda et par les habitants de Jérusalem. Il eut pour successeur son fils Manassé.
Hesekiah sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín sórí òkè níbi tí àwọn ibojì àwọn àtẹ̀lé Dafidi wà. Gbogbo Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni ó bu ọlá fún un nígbà tí ó kú. Manase ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

< 2 Chroniques 32 >