< 2 Chroniques 19 >
1 Josaphat, roi de Juda, retourna sain et sauf chez lui, à Jérusalem.
Nígbà tí Jehoṣafati ọba Juda padà ní àlàáfíà sí ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu,
2 Jéhu, fils de Hanani, le Voyant, alla à sa rencontre et dit au roi Josaphat: "Devais-tu prêter ton concours à cet impie? Sont-ce les ennemis du Seigneur que tu aimes? Par là, tu as provoqué contre toi la colère de l’Eternel.
Jehu aríran, ọmọ Hanani jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Ṣé ìwọ yóò máa ran ènìyàn búburú lọ́wọ́, kí o sì fẹ́ràn àwọn tí ó kórìíra Olúwa? Nítorí èyí, ìbínú Olúwa wà lórí wa.
3 Toutefois, des mérites réels se trouvent en toi, puisque tu as fait disparaître les Achêrot de ce pays, et que tu t’es appliqué, de cœur, à rechercher l’Eternel."
Bí ó ti wù kí ó rí, ohun rere wà nínú rẹ, nítorí tí ìwọ ti mú àwọn ilé àwọn ère òrìṣà Aṣerah kúrò, tí o sì múra ọkàn rẹ láti wá Ọlọ́run.”
4 Josaphat, après s’être réinstallé à Jérusalem, se remit à visiter les populations depuis Bersabée jusqu’aux monts d’Ephraïm et les ramena à l’Eternel, Dieu de leurs ancêtres.
Jehoṣafati sì ń gbé ní Jerusalẹmu ó sì jáde lọ padà láàrín àwọn ènìyàn láti Beerṣeba dé òkè ìlú Efraimu, ó sì mú wọn padà sọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run baba wọn.
5 Il institua des juges dans le pays, dans chacune des villes fortes de Juda,
Ó sì yan àwọn onídàájọ́ sí ilẹ̀ náà, ní olúkúlùkù ìlú olódi Juda.
6 et dit à ces juges: "Soyez attentifs à ce que vous faites! Ce n’est pas au nom d’un homme que vous rendez justice, mais au nom de l’Eternel: Il est présent quand vous prononcez un jugement.
Ó sì wí fun wọ́n pé, “Ẹ kíyèsi ohun tí ẹ̀yin ń ṣe, nítorí ìwọ kò ṣe ìdájọ́ fun ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ ní ìdájọ́.
7 Puisse donc la crainte du Seigneur vous inspirer! Soyez circonspects dans vos actes, car l’Eternel, notre Dieu, n’admet ni iniquité, ni acception de personnes, ni corruption par les présents."
Nísinsin yìí jẹ́ kí ìbẹ̀rù Olúwa kí ó wá sí ọkàn rẹ̀. Ṣe ìdájọ́ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, nítorí pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run kò sí àìṣedéédéé tàbí ojúsàájú tàbí gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.”
8 A Jérusalem également, Josaphat choisit des Lévites, des prêtres et des chefs de famille d’Israël pour connaître des affaires religieuses et des autres litiges. (On était revenu à Jérusalem.)
Ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, Jehoṣafati yan díẹ̀ lára àwọn Lefi, àwọn àlùfáà àti àwọn olórí ìdílé Israẹli si pípa òfin Olúwa mọ́ àti láti ṣe ìdájọ́. Wọn sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
9 Il leur adressa ces recommandations: "Voici comment vous agirez, guidés par la crainte du Seigneur, en toute droiture et d’un cœur intègre.
Ó sì kìlọ̀ fún wọn wí pé. “Ìwọ gbọdọ̀ sìn pẹ̀lú òtítọ́ àti pẹ̀lú ọkàn pípé ní ìbẹ̀rù Olúwa.
10 Chaque fois que vos frères, demeurant dans leurs villes respectives, porteront un procès devant vous, qu’il s’agisse d’une question de meurtre ou qu’il s’agisse de doctrine, de prescriptions, de statuts et de droits, vous les éclairerez pour qu’ils ne se rendent pas coupables envers le Seigneur, ce qui vous attirerait à vous et à vos frères la colère divine. Faites ainsi, et vous éviterez les fautes.
Ní gbogbo ẹjọ́ tí ó bá wà níwájú rẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin yín tí ń gbé ìlú wọn bóyá ẹ̀jẹ̀ tí ń sàn tàbí ìyókù òfin pẹ̀lú, pa á láṣẹ ìlànà àti ẹ̀tọ́, ìwọ gbọdọ̀ kìlọ̀ fún wọn láti má ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú yóò sì wá sórí yín, àti sórí àwọn arákùnrin. Ṣe èyí, ìwọ kì yóò sì jẹ̀bi.
11 Et voyez, le prêtre Amariahou sera à votre tête pour toutes les affaires religieuses, et Zebadiahou, fils d’Ismaël, le prince de la maison de Juda, pour toutes les affaires du roi. Les Lévites seront à votre disposition comme prévôts. Courage donc et à l’œuvre! Que l’Eternel assiste quiconque veut le bien!"
“Amariah àlùfáà ni yóò jẹ́ olórí yín nínú gbogbo ọ̀ràn tí ó jẹ́ ti Olúwa, àti Sebadiah ọmọ Iṣmaeli alákòóso ìdílé Juda, ní yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba, àti àwọn ará Lefi pẹ̀lú yin yóò sìn gẹ́gẹ́ bí ìjòyè níwájú yín. Ẹ ṣe é pẹ̀lú ìmọ́kànle, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú àwọn tó bá ń ṣe rere.”