< 2 Chroniques 13 >

1 C’Est dans la dix-huitième année du règne de Jéroboam qu’Abiyya devint roi de Juda.
Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu, Abijah di ọba Juda.
2 Il régna trois ans à Jérusalem. Sa mère se nommait Mikhayahou, fille d’Ouriêl, de Ghibea. Il y eut guerre entre Abiyya et Jéroboam.
Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Mikaiah, ọmọbìnrin Urieli ti Gibeah. Ogun wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
3 Abiyya engagea la guerre avec une armée de vaillants combattants, au nombre de quatre cent mille hommes d’élite; Jéroboam lui opposa une ligne de bataille de huit cent mille hommes d’élite, guerriers vaillants.
Abijah lọ sí ojú ogun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun ogún ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára, Jeroboamu kó ogun jọ pẹ̀lú ogójì ọ̀kẹ́ ọ̀wọ́ ogun tí ó lágbára.
4 Abiyya se mit debout sur le sommet du mont Cemaraïm, qui fait partie des monts d’Ephraïm, et dit: "Ecoutez-moi, Jéroboam et tout Israël!
Abijah dúró lórí òkè Semaraimu ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, ó sì wí pé, Jeroboamu àti gbogbo Israẹli, ẹ gbọ́ mi!
5 Ne devriez-vous pas savoir que l’Eternel, Dieu d’Israël, a octroyé pour toujours à David la royauté sur Israël, à lui et à ses fils, en vertu d’un pacte inviolable?
Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti fún Dafidi àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ ni oyè ọba títí láé nípasẹ̀ májẹ̀mú iyọ̀?
6 Cependant Jéroboam, fils de Nebat, serviteur de Salomon, fils de David, se leva et s’insurgea contre son maître.
Síbẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, oníṣẹ́ Solomoni ọmọ Dafidi, ṣọ̀tẹ̀ sí ọ̀gá rẹ̀.
7 Des aventuriers, des gens de rien, se groupèrent autour de lui et firent violence à Roboam, fils de Salomon, qui était alors jeune et de cœur tendre et ne sut leur tenir tête.
Àwọn ènìyàn lásán sì kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àwọn ọmọ ẹni búburú, wọ́n sì kẹ̀yìn sí Rehoboamu ọmọ Solomoni ní ìgbà tí ó sì kéré tí kò lè pinnu fúnra rẹ̀, tí kò lágbára tó láti takò wọ́n.
8 Et maintenant vous prétendez l’emporter sur la royauté de l’Eternel, qui s’exerce par les mains des fils de David, et, en vérité, vous formez une grande multitude et vous avez avec vous les veaux d’or dont Jéroboam vous a fait des dieux.
“Nísinsin yìí, ìwọ ṣètò láti kọ́ ìjọba Olúwa, tí ó wà lọ́wọ́ àwọn àtẹ̀lé Dafidi. Ìwọ jẹ́ ọmọ-ogun tí ó gbilẹ̀, ìwọ sì ní pẹ̀lú rẹ ẹgbọrọ màlúù wúrà ti Jeroboamu dà láti fi ṣe Ọlọ́run yín.
9 Mais n’avez-vous point expulsé les prêtres du Seigneur, les fils d’Aaron et les Lévites, pour vous donner des prêtres à l’exemple des peuples des autres pays? Quiconque se présente pour se faire investir des fonctions sacerdotales, au moyen d’un jeune taureau et de sept béliers, devient prêtre d’un dieu… qui n’existe pas.
Ṣùgbọ́n ṣé ìwọ kò lé àwọn àlùfáà Olúwa jáde, àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ará Lefi. Tí ó sì ṣe àwọn àlùfáà ti ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn ti ṣe? Ẹnikẹ́ni tí ó bá wá láti ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò méjì lè jẹ́ àlùfáà ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run.
10 Tandis que nous, l’Eternel est notre Dieu, nous ne l’avons pas trahi. Les prêtres au service de l’Eternel sont fils d’Aaron, et les Lévites remplissent leur tâche.
“Ní ti àwa, Olúwa ni Ọlọ́run wa, àwa kò sì ti ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Àwọn àlùfáà tí ó ń sin Olúwa jẹ́ àwọn ọmọ Aaroni àwọn ará Lefi sì ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
11 Ils font fumer chaque matin et chaque soir des holocaustes offerts à l’Eternel, l’encens aromatique; le pain de proposition est rangé sur la table pure, le chandelier d’or et ses lampes sont allumés chaque soir, car nous, nous veillons aux observances de l’Eternel, alors que vous les délaissez.
Ní àràárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́, wọ́n gbé ẹbọ sísun àti tùràrí olóòórùn dídùn síwájú Olúwa. Wọ́n gbé àkàrà jáde sórí tábìlì àsè mímọ́, wọ́n sì tan iná sí àwọn fìtílà lórí ìdúró ọ̀pá fìtílà wúrà ní gbogbo ìrọ̀lẹ́. A ń pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa mọ́. Ṣùgbọ́n ìwọ ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
12 Et voyez, nous avons à notre tête Dieu et ses prêtres, et les trompettes retentissantes pour en faire éclater les fanfares contre vous. Fils d’Israël, ne combattez pas contre l’Eternel, Dieu de vos pères, car vous ne triompherez pas!"
Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa; òun ni olórí wa. Àwọn àlùfáà rẹ̀ pẹ̀lú fèrè wọn yóò fọn ìpè ogun sí i yín. Ẹyin ọkùnrin Israẹli, ẹ má ṣe dojú ìjà kọ Olúwa Ọlọ́run baba yín nítorí ẹ̀yin kì yóò yege.”
13 Alors Jéroboam fit avancer les troupes placées en embuscade pour prendre ses adversaires à revers; son armée faisait face à Juda et la troupe en embuscade était derrière eux.
Nísinsin yìí, Jeroboamu ti rán àwọn ọ̀wọ́ ogun lọ yíká láti jagun ẹ̀yìn. Kí ó lè jẹ́ pé, tí òun bá wà níwájú Juda, bíba ní bùba á wà ní ẹ̀yìn wọn.
14 Les hommes de Juda firent volte-face; et voilà qu’ils eurent à combattre devant et derrière. Ils invoquèrent l’Eternel, et les prêtres firent retentir les trompettes.
Nígbà tí Juda sì bojú wo ẹ̀yìn, sì kíyèsi i, ogun ń bẹ níwájú àti lẹ́yìn, wọn sì ké pe Olúwa, àwọn àlùfáà sì fun ìpè.
15 En même temps, les hommes de Juda poussèrent des cris de guerre et, à la suite de ces clameurs, Dieu fit succomber Jéroboam et tout Israël devant Abiyya et Juda.
Olúkúlùkù, ọkùnrin Juda sì fún ìpè ogun, ó sì ṣe, bí àwọn ọkùnrin Juda sì ti fun ìpè ogun, ni Ọlọ́run kọlu Jeroboamu àti gbogbo Israẹli níwájú Abijah àti Juda.
16 Les enfants d’Israël s’enfuirent donc devant Juda, aux mains de qui Dieu les livra.
Àwọn ọmọ Israẹli sálọ kúrò níwájú Juda, Ọlọ́run sì fi wọ́n lé wọn lọ́wọ́.
17 Abiyya et son peuple leur infligèrent une grande défaite; cinq cent mille hommes d’élite tombèrent, en Israël, frappés à mort.
Abijah àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ìdààmú ńlá jẹ wọ́n ní ìyà, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ọkùnrin tí a yàn ṣubú ní pípa nínú Israẹli.
18 Les enfants d’Israël furent humiliés en ce temps-là, tandis que les fils de Juda furent victorieux pour s’être appuyés sur l’Eternel, Dieu de leurs pères.
Báyìí ni a rẹ àwọn ọmọ Israẹli sílẹ̀ ní àkókò náà, àwọn ọmọ Juda sì borí nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn.
19 Abiyya se mit à la poursuite de Jéroboam et lui prit des villes: Beth-El et ses bourgades, Yechana et ses bourgades, Ephraïn et ses bourgades.
Abijah sì lépa Jeroboamu, ó sì gba ìlú lọ́wọ́ rẹ̀, Beteli pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Jeṣana pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Efroni pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀.
20 Jéroboam n’osa plus rien entreprendre du vivant d’Abiyya. L’Eternel le frappa, et il mourut.
Bẹ́ẹ̀ ní Jeroboamu kò sì tún ní agbára mọ́ ní ọjọ́ Abijah. Olúwa sì lù ú ó sì kú.
21 Abiyya devint puissant. Il épousa quatorze femmes et engendra vingt-deux fils et seize filles.
Abijah sì di alágbára, ó sì gbé obìnrin mẹ́tàlá ní ìyàwó, ó sì bi ọmọkùnrin méjìlélógún, àti ọmọbìnrin mẹ́rìndínlógún.
22 Pour le surplus de l’histoire d’Abiyya, de ses faits et gestes, ils sont consignés dans l’exposé du prophète Iddo.
Àti ìyókù ìṣe Abijah, àti ìwà rẹ̀, àti iṣẹ́ rẹ̀, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtumọ̀, wòlíì Iddo.

< 2 Chroniques 13 >