< 2 Chroniques 11 >

1 Roboam se rendit à Jérusalem et convoqua la maison de Juda et de Benjamin, cent quatre-vingt mille guerriers d’élite, pour faire la guerre à Israël afin de restituer la royauté à Roboam.
Nígbà tí Rehoboamu dé Jerusalẹmu, ó kó ilé Juda àti Benjamini jọ, ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n jẹ́ ológun, láti bá Israẹli jà kí ó lè mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀.
2 Alors la parole du Seigneur s’adressa à Chemaya, homme de Dieu, en ces termes:
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
3 "Parle ainsi à Roboam, fils de Salomon, roi de Juda, et à tous les Israélites dans Juda et dans Benjamin:
“Wí fún Rehoboamu ọmọ Solomoni ọba Juda, sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní Juda àti Benjamini,
4 Ainsi parle le Seigneur: N’Allez point faire la guerre à vos frères, rentrez chacun dans vos demeures, car c’est par moi que cet événement s’est produit." Ils obéirent à la parole du Seigneur et renoncèrent à marcher contre Jéroboam.
‘Èyí ní ohun tí Olúwa wí. Ẹ má ṣe gòkè lọ láti lọ jà pẹ̀lú arákùnrin yín, ẹ lọ sílé, gbogbo yín, nítorí ti ìṣe mi nìyí.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n sì padà sẹ́yìn láti yan lọ dojúkọ Jeroboamu.
5 Roboam, s’étant établi à Jérusalem, érigea en forteresses des villes de Juda.
Rehoboamu ń gbe ní Jerusalẹmu ó sì kọ́ àwọn ìlú fún olódi ní Juda.
6 Il fortifia Bethléem, Etam, Tekoa,
Bẹtilẹhẹmu, Etamu, Tekoa,
7 Beth-Çour, Sokho, Adoullam,
Beti-Suri, Soko, Adullamu,
8 Gath, Marêcha, Ziph,
Gati, Meraṣa Sifi,
9 Adoraïm, Lakhich, Azêka,
Adoraimu, Lakiṣi, Aseka
10 Çorea, Ayyalôn et Hébron, toutes villes situées dans Juda et Benjamin et dont il fit des villes fortes:
Sora, Aijaloni, àti Hebroni. Wọ̀nyí ni àwọn ìlú ìdáàbòbò ní Juda àti Benjamini.
11 Pour augmenter la puissance de ces forteresses, il y établit des commandants, des réserves de vivres, d’huile et de vin;
Ó sì mú àwọn ìlú olódi lágbára, ó sì fi àwọn balógun sínú wọn àti àkójọ oúnjẹ, àti òróró àti ọtí wáìnì.
12 Il amassa également dans chacune de ces villes des boucliers et des lances, et les rendit ainsi très fortes. Juda et Benjamin lui restèrent dévoués.
Àti ní olúkúlùkù ìlú ni ó fi asà àti ọ̀kọ̀ sí, ó sì mú wọn lágbára gidigidi, ó sì ní Juda àti Benjamini lábẹ́ rẹ̀.
13 Les prêtres et les Lévites, répandus dans tout Israël, vinrent de tout le territoire se présenter à lui.
Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi, láti gbogbo ẹ̀yà wọn jákèjádò Israẹli wà ní ẹ̀bá rẹ̀.
14 Les Lévites abandonnaient, en effet, leurs lieux d’habitation et leurs possessions pour se rendre en Juda et à Jérusalem, parce que Jéroboam, avec ses fils, les avaient empêchés d’exercer leurs fonctions de prêtres,
Àwọn ará Lefi fi ìgbèríko sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Juda àti Jerusalẹmu nítorí Jeroboamu àti àwọn ọmọ rẹ̀, ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà Olúwa.
15 et qu’il avait institué des prêtres à lui pour les hauts lieux, pour les démons et pour les veaux d’or fabriqués par lui.
Ó sì yan àwọn àlùfáà tirẹ̀ fún àwọn ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, àti fún àwọn ère òbúkọ, àti fún ẹgbọrọ màlúù tí ó ṣe.
16 A la suite des Lévites, ceux d’entre toutes les tribus d’Israël qui avaient à cœur de rendre hommage à l’Eternel, Dieu d’Israël, vinrent à Jérusalem pour sacrifier à l’Eternel, Dieu de leurs pères.
Àwọn tó wá láti gbogbo ẹ̀yà Israẹli tí wọ́n fi ọkàn wọn fún wíwá Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tẹ̀lé àwọn ará Lefi lọ sí Jerusalẹmu láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run baba a wọn.
17 Ils contribuèrent à fortifier le royaume de Juda et à affermir le pouvoir de Roboam, fils de Salomon, pendant trois années; car pendant trois années, on marcha dans la voie de David et de Salomon.
Ó fún ìjọba Juda ní agbára, ó sì ti Rehoboamu ọmọ Solomoni lẹ́yìn fún ọdún mẹ́ta nítorí ọdún mẹ́ta ni wọ́n fi rìn ní ọ̀nà ti Dafidi àti Solomoni ní àkókò yí.
18 Roboam prit pour femme Mahalat, fille de Yerimot, fils de David, et d’Abihaïl, fille d’Elïab, fils de Jessé.
Rehoboamu fẹ́ Mahalati tí ó jẹ́ ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Dafidi Jerimoti bi àti ti Abihaili, ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Jese Eliabu bí.
19 Elle lui donna des fils: Yeouch, Chemaria et Zaham.
Ó bí àwọn ọmọ fún un: Jeuṣi, Ṣemariah àti Sahamu.
20 Après elle, il épousa Maakha, fille d’Absalon, qui lui enfanta Abiyya, Attaï, Ziza et Chelomit.
Nígbà náà, ó fẹ́ Maaka ọmọbìnrin Absalomu, tí ó bí Abijah fún Attai, Sisa àti Ṣelomiti.
21 Roboam préférait Maakha, fille d’Absalon, à toutes ses femmes et concubines: car il eut dix-huit femmes et soixante concubines, et il engendra vingt-huit fils et soixante filles.
Rehoboamu fẹ́ràn Maaka ọmọbìnrin Absalomu ju èyíkéyìí nínú àwọn ìyàwó rẹ̀ àti àwọn àlè rẹ̀ lọ. Ní gbogbo rẹ̀, ó ní ìyàwó méjìdínlógún àti ọgọ́ta àlè ọmọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n àti ọgọ́ta ọmọbìnrin.
22 Aussi Roboam établit-il Abiyya, fils de Maakha, comme chef et prince parmi ses frères, en vue de lui assurer la royauté.
Rehoboamu yan Abijah ọmọ Maaka láti jẹ́ olóyè ọmọ-aládé láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, kí ó ba à lè ṣe é ní ọba.
23 En homme avisé, il dispersa l’ensemble de ses fils dans toutes les terres de Juda et de Benjamin, en les établissant dans toutes les villes fortes. Il leur donna d’abondantes subsistances et demanda pour eux une multitude de femmes.
Ó hùwà ọlọ́gbọ́n, nípa fí fọ́n díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ jákèjádò ká àwọn agbègbè Juda àti Benjamini àti sí gbogbo àwọn ìlú ńlá olódi. Ó fún wọn ní ọ̀pọ̀ ohun tí wọ́n fẹ́, ó sì fẹ́ ọ̀pọ̀ ìyàwó fún wọn.

< 2 Chroniques 11 >