< 1 Samuel 6 >

1 L’Arche du Seigneur était depuis sept mois dans le territoire des Philistins,
Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wà ní agbègbè Filistini fún oṣù méje,
2 lorsqu’ils mandèrent prêtres et devins et leur dirent: "Comment procéderons-nous pour l’arche de l’Eternel? Apprenez-nous la façon de la renvoyer au lieu de sa résidence."
àwọn ará Filistini pe àwọn àlùfáà, àti àwọn alásọtẹ́lẹ̀, wọ́n sì sọ pé, “Kí ni kí a ṣe pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa? Sọ fún wa bí àwa yóò ti dá a padà sí ààyè rẹ̀.”
3 Ceux-là répondirent: "Si vous renvoyez l’arche du Dieu d’Israël, ne la renvoyez point à vide, il faut aussi lui offrir un expiatoire; alors vous serez guéris, et vous saurez pourquoi sa main ne cesse de vous frapper.
Wọ́n dáhùn wí pé, “Tí ẹ bá dá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ti àwọn ọmọ Israẹli padà, ẹ má ṣe dá a padà ní òfìfo, ṣùgbọ́n bí ó ti wù kí ó rí, ẹ fún un ní ẹbọ ẹ̀bi. Nígbà náà ni a ó mú un yín láradá, ẹ̀yin yóò sì mọ ìdí tí ọwọ́ rẹ̀ kò fi tí ì kúrò lára yín.”
4 Quel expiatoire, dirent-ils, devons-nous lui offrir? Autant, répondit-on, que les Philistins ont de princes: cinq images d’hémorroïdes en or et cinq mulots en or; car vous souffrez d’une même plaie, vous tous et vos princes.
Àwọn ará Filistini béèrè pé, “Irú ẹbọ ẹ̀bi wo ni kí a fi fún un?” Wọ́n dáhùn, “Wúrà oníkókó márùn-ún àti eku ẹ̀lírí wúrà márùn-ún, gẹ́gẹ́ bí iye àwọn aláṣẹ Filistini, nítorí àjàkálẹ̀-ààrùn kan náà ni ó kọlù yín àti olórí yín.
5 Faites donc des simulacres de vos hémorroïdes et des mulots qui ravagent le pays, et offrez-les en hommage au Dieu d’Israël; peut-être cessera-t-il de faire peser sa main sur vous, sur votre dieu et votre pays.
Mọ àwòrán ààrùn oníkókó àti ti eku ẹ̀lírí yin tí ó ń ba orílẹ̀-èdè náà jẹ́ kí o sì bu ọlá fún Ọlọ́run Israẹli. Bóyá yóò gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lára yín, lára ọlọ́run yín àti lára ilẹ̀ yín.
6 Et pourquoi endurcir votre cœur comme l’ont fait les Egyptiens et Pharaon? Assurément, quand il les eut accablés de sa puissance, ils ont dû renvoyer ce peuple et il est parti!
Kí ni ó dé tí ẹ fi ń sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí àwọn ará Ejibiti àti Farao ti ṣe? Nígbà tí ó fi ọwọ́ líle mú wọn, ṣé wọn kò rán àwọn ọmọ Israẹli jáde kí wọn kí ó lè lọ ní ọ̀nà wọn?
7 Donc, faites fabriquer un chariot neuf, et prenez deux vaches laitières qui n’aient pas encore porté le joug; attelez ces vaches au chariot, et faites ramener leurs petits, séparés d’elles, à l’étable.
“Nísinsin yìí ẹ pèsè kẹ̀kẹ́ ẹrù tuntun sílẹ̀, pẹ̀lú màlúù méjì tí ó ti fi ọmú fún ọmọ, èyí tí a kò tí ì gba àjàgà sí ọrùn rí, kí ẹ sì so ó mọ́ kẹ̀kẹ́ náà, kí ẹ sì mú ọmọ wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn wá sí ilé láti so.
8 Prenez alors l’arche de l’Eternel, placez-la sur le chariot, et, à côté d’elle, posez dans un coffret les simulacres d’or que vous lui aurez destinés comme offrande d’expiation; puis vous la laisserez partir,
Kí ẹ sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí orí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kí ẹ̀yin sì kó àwọn ohun èlò wúrà tí ẹ̀yin fi fún un gẹ́gẹ́ bí ti ẹbọ ẹ̀bi sí inú àpótí ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó sì rán an lọ,
9 et vous la suivrez des yeux: si elle s’achemine vers son territoire, à Beth-Chémech, c’est elle qui nous a infligé cette grande calamité; sinon, nous en conclurons que ce n’est pas sa main, mais le hasard seul, qui nous a frappés."
ṣùgbọ́n kí ẹ sì máa ṣọ́ ọ. Tí ó bá ń lọ sí ilẹ̀ rẹ̀, ìlú rẹ̀, níhà Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà ni Olúwa mú àjálù ńlá yìí bá wa. Ṣùgbọ́n bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà náà ni a mọ̀ pé kì í ṣe ọwọ́ rẹ̀ ni ó kọlù wá, ṣùgbọ́n ó wá bẹ́ẹ̀ ni.”
10 Ainsi fit-on. L’On prit deux vaches laitières, qu’on attela à un chariot, en retenant les veaux à l’étable;
Nígbà náà ni wọ́n ṣe èyí. Wọ́n mú abo màlúù méjì, tí ń fi ọmú fún ọmọ, wọn mọ́ ara, wọ́n sì dè é ni ilé kẹ̀kẹ́ ẹrù, wọn sì so àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀ ni ilé.
11 et l’on mit l’arche du Seigneur sur le chariot, ainsi que le coffret contenant les mulots d’or et les simulacres d’hémorroïdes.
Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé orí kẹ̀kẹ́ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni àpótí tí eku ẹ̀lírí wúrà àti àwòrán ààrùn oníkókó wà níbẹ̀.
12 Les vaches marchèrent droit dans la direction de Beth-Chémech, suivirent toujours une même voie tout en mugissant, et ne s’en écartèrent ni à droite ni à gauche; les princes des Philistins marchèrent derrière elles, jusqu’aux confins de Beth-Chémech.
Nígbà náà; àwọn màlúù lọ tààrà sí ìhà Beti-Ṣemeṣi, wọ́n ń lọ tààrà, wọ́n sì ń dún bí wọ́n ti ń lọ. Wọn kò yà sí ọ̀tún tàbí yà sí òsì. Àwọn aláṣẹ Filistini tẹ̀lé wọn títí dé ibodè Beti-Ṣemeṣi.
13 Les gens de Beth-Chémech faisaient alors la coupe du froment dans la vallée; en levant les yeux, ils aperçurent l’arche et se réjouirent à cette vue.
Nísinsin yìí, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi ń kórè jéró wọn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí wọ́n wo òkè tí wọ́n sì rí àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n yọ̀ níwájú rẹ̀.
14 Le chariot, arrivé au champ de Josué, de Beth-Chémech, s’y arrêta; là se trouvait une grande pierre. On fendit en morceaux le bois du chariot, et l’on immola les vaches en holocauste à l’Eternel.
Kẹ̀kẹ́ ẹrù wá sí pápá Joṣua ti Beti-Ṣemeṣi, níbẹ̀ ni ó ti dúró ní ẹ̀bá àpáta ńlá kan. Àwọn ènìyàn gé igi ara kẹ̀kẹ́ ẹrù sí wẹ́wẹ́ wọ́n sì fi àwọn màlúù náà rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
15 Les lévites avaient descendu l’arche du Seigneur et le coffret qui l’accompagnait contenant les objets d’or, et avaient posé le tout sur la grosse pierre; alors les gens de Beth-Chémech offrirent, le même jour, des holocaustes et autres sacrifices à l’Eternel.
Àwọn ará Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àpótí tí ohun èlò wúrà wà níbẹ̀, wọ́n sì gbé wọn ka orí àpáta ńlá náà. Ní ọjọ́ náà, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi rú ẹbọ sísun, wọ́n sì ṣe ìrúbọ sí Olúwa.
16 Ce que voyant, les cinq princes des Philistins s’en retournèrent à Ekron ce jour-là.
Àwọn aláṣẹ Filistini márààrún rí gbogbo èyí, wọ́n sì padà ní ọjọ́ náà sí Ekroni.
17 Quant aux hémorroïdes imitées en or, que les Philistins avaient offertes en expiation à l’Eternel, en voici le compte: une pour Asdod, une pour Gaza, une pour Ascalon, une pour Gath, une pour Ekron.
Èyí ni kókó wúrà tí àwọn Filistini fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀bi ọ̀kọ̀ọ̀kan fún Aṣdodu, ọ̀kan ti Gasa, ọ̀kan ti Aṣkeloni, ọ̀kan ti Gati, ọ̀kan ti Ekroni.
18 Mais le nombre des mulots d’or égalait celui de toutes les villes des Philistins soumises aux cinq princes, depuis la ville forte jusqu’à la place ouverte, et jusqu’à la grosse pierre sur laquelle on posa l’arche du Seigneur et qui subsiste aujourd’hui encore, dans le champ de Josué de Beth-Chémech.
Wúrà eku ẹ̀lírí jẹ́ iye ìlú tí àwọn aláṣẹ Filistini márààrún ti wá, ìlú olódi pẹ̀lú ìletò wọn. Àpáta ńlá náà, lórí èyí tí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé jẹ́ ẹ̀rí títí di òní ní oko Joṣua ará Beti-Ṣemeṣi.
19 Le Seigneur frappa les habitants de Beth-Chémech, pour avoir regardé dans l’arche; il frappa, dans cette population, soixante-dix hommes sur cinquante mille. Le peuple fut consterné de cette grande mortalité que lui avait infligée le Seigneur;
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kọlu díẹ̀ lára àwọn ọkùnrin Beti-Ṣemeṣi, ó pa àádọ́rin wọn, nítorí wọ́n ti wo inú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Àwọn ènìyàn ṣọ̀fọ̀ nítorí àjálù ńlá tí Olúwa fi bá ọ̀pọ̀ wọn jà.
20 et les gens de Beth-Chémech se dirent: "Qui peut subsister devant l’Eternel, ce Dieu saint? Et où l’arche montera-t-elle de chez nous?"
Àwọn ọkùnrin ará Beti-Ṣemeṣi béèrè pé, “Ta ni ó le è dúró ní iwájú Olúwa Ọlọ́run mímọ́ yìí? Ọ̀dọ̀ ta ni àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò gbà gòkè lọ láti ibí yìí?”
21 Ils envoyèrent alors des messagers aux habitants de Kiryath-Yearim, pour leur dire: "Les Philistins ont restitué l’arche du Seigneur; venez, faites-la monter chez vous."
Nígbà náà, wọ́n rán àwọn ìránṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí Kiriati-Jearimu wí pé, “Àwọn Filistini ti dá àpótí ẹ̀rí Olúwa padà. Ẹ sọ̀kalẹ̀ wá, kí ẹ gbé e gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ yín.”

< 1 Samuel 6 >