< 1 Samuel 24 >

1 Or, quand Saül revint de poursuivre les Philistins, on lui annonça que David se trouvait dans le désert d’En-Ghedi.
Nígbà tí Saulu padà kúrò lẹ́yìn àwọn Filistini a sì sọ fún un pé, “Wò ó, Dafidi ń bẹ́ ni aginjù En-Gedi.”
2 Saül prit alors trois mille hommes choisis entre tout Israël, et alla à la recherche de David et de ses hommes, en parcourant les sentiers escarpés des chamois.
Saulu sì mú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta akọni ọkùnrin tí a yàn nínú gbogbo Israẹli ó sì lọ láti wá Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ lórí òkúta àwọn ewúrẹ́ igbó.
3 Il arriva près des parcs à brebis qui se trouvaient sur la route. Là était une caverne, où Saül entra pour satisfaire un besoin; or, David et ses hommes se trouvaient au fond de cette caverne.
Ó sì dé ibi àwọn agbo àgùntàn tí ó wà ní ọ̀nà, ihò kan sì wà níbẹ̀, Saulu sì wọ inú rẹ̀ lọ láti bo ẹsẹ̀ rẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń bẹ lẹ́bàá ihò náà.
4 "Ah! dirent ces hommes à David, voici le moment dont le Seigneur t’a dit: Vois, je mettrai ton ennemi en ta main, tu le traiteras comme bon te semblera." Et David alla couper sans bruit le bord du manteau de Saül.
Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, èyí ni ọjọ́ náà tí Olúwa wí fún ọ pé, ‘Wò ó, èmi fi ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́, ìwọ ó sì ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ lójú rẹ.’” Dafidi sì dìde, ó sì yọ́ lọ gé etí aṣọ Saulu.
5 Mais ensuite le cœur lui battit d’avoir coupé le vêtement de Saül,
Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, àyà já Dafidi nítorí tí ó gé etí aṣọ Saulu.
6 et il dit à ses hommes: "Dieu me préserve d’agir ainsi envers mon souverain, de porter la main sur l’oint du Seigneur! Oui, il est l’oint du Seigneur."
Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Èèwọ̀ ni fún mi láti ọ̀dọ́ Olúwa wá bí èmi bá ṣe nǹkan yìí sí ẹni tí a ti fi àmì òróró Olúwa yàn, láti nawọ́ mi sí i, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni.”
7 Il rompit par ces paroles le dessein de ses gens et ne leur permit pas d’attaquer Saül. Celui-ci sortit de la caverne et poursuivit son chemin.
Dafidi sì fi ọ̀rọ̀ wọ̀nyí dá àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dúró, kò sì jẹ́ kí wọn dìde sí Saulu, Saulu sì dìde kúrò ní ihò náà, ó sì bá ọ̀nà rẹ̀ lọ.
8 David se leva alors, sortit de la caverne et suivit Saül en criant: "Mon seigneur le roi!" Saül se retourna, David s’inclina et se prosterna la face contre terre.
Dafidi sì dìde lẹ́yìn náà, ó sì jáde kúrò nínú ihò náà ó sì kọ sí Saulu pé, “Olúwa mi, ọba!” Saulu sì wo ẹ̀yìn rẹ̀. Dafidi sì dojú rẹ́ bo ilẹ̀ ó sì tẹríba fún un.
9 Et il dit à Saül: "Pourquoi écoutes-tu les propos des gens qui disent: David cherche à te nuire?
Dafidi sì wí fún Saulu pé, “Èéha ti ṣe tí ìwọ fi ń gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn pé, ‘Wò ó, Dafidi ń wa ẹ̀mí rẹ́’?
10 Certes, aujourd’hui même, tu le vois, aujourd’hui le Seigneur t’a mis en mon pouvoir dans la caverne, me permettant ainsi de te tuer; mais je t’ai épargné et j’ai dit: Je ne porterai pas la main sur mon maître, car il est l’oint du Seigneur.
Wò ó, ojú rẹ́ rí i lónìí, bí Olúwa ti fi ìwọ lé mi lọ́wọ́ lónìí nínú ihò, àwọn kan ní kí èmi ó pa ọ, ṣùgbọ́n èmi dá ọ sí, ‘Èmi sì wí pé, èmi kì yóò nawọ́ mi sí olúwa mi, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni òun jẹ́.’
11 Regarde, ô mon père, regarde le bord de ton manteau dans ma main; puisque je l’ai coupé et ne t’ai pas tué, juge et comprends que je n’ai rien à me reprocher et que je ne t’ai manqué en rien, tandis que toi, tu cherches insidieusement à prendre ma vie!
Pẹ̀lúpẹ̀lú, baba mi, wò ó, àní wo etí aṣọ rẹ lọ́wọ́ mi; nítorí èmi gé etí aṣọ rẹ, èmi kò sì pa ọ́, sì wò ó, kí o sì mọ̀ pé kò sí ibi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ mi, èmi kò sì ṣẹ̀ ọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ ń dọdẹ ẹ̀mí mi láti gbà á.
12 Que Dieu juge entre toi et moi! Il pourra me venger de toi, mais je ne porterai pas la main sur toi.
Kí Olúwa ṣe ìdájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, àti kí Olúwa ó gbẹ̀san mi lára rẹ; ṣùgbọ́n, ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
13 Comme dit le proverbe des anciens, c’est des mauvais que vient le mal; mais ma main ne te touchera pas.
Gẹ́gẹ́ bí òwe ìgbà àtijọ́ ti wí, ìwà búburú a máa ti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn búburú jáde wá; ṣùgbọ́n ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
14 Contre qui le roi d’Israël s’est-il mis en campagne? Qui poursuis-tu? Un chien mort, un insecte!
“Nítorí ta ni ọba Israẹli fi jáde? Ta ni ìwọ ń lépa? Òkú ajá, tàbí eṣinṣin?
15 Oui, l’Eternel sera juge et prononcera entre nous deux! Qu’il voie, qu’il prenne ma cause en main et qu’il me fasse justice de toi!"
Kí Olúwa ó ṣe onídàájọ́, kí ó sì dájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, kí ó sì gbèjà mi, kí ó sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ.”
16 Quand David eut cessé de parler ainsi à Saül, Saül lui dit: "Est-ce là ta voix, David, mon fils?" Et Saül éclata en pleurs.
Ó sì ṣe, nígbà tí Dafidi sì dákẹ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Saulu, Saulu sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí, Dafidi ọmọ mi?” Saulu sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sọkún.
17 Puis il dit à David: "Tu vaux mieux que moi; car tu m’as fait du bien, et moi je t’ai fait du mal.
Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ṣe olódodo jù mí lọ; nítorí pé ìwọ ti fi ìre san án fún mi, èmi fi ibi san án fún ọ.
18 Tu as attesté aujourd’hui que tu as bien agi à mon égard, puisque le Seigneur m’a livré en ta main et que tu ne m’as pas tué.
Ìwọ sì fi oore tí ìwọ ti ṣe fún mi hàn lónìí: nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti fi ẹ̀mí mi lé ọ lọ́wọ́, ìwọ kò sì pa mí.
19 Lorsqu’un homme surprend son ennemi, le laisse-t-il aller sain et sauf?… Dieu te rende le bien que tu m’as fait en ce jour!
Nítorí pé bí ènìyàn bá rí ọ̀tá rẹ̀, ó lè jẹ́ kí ó lọ ní àlàáfíà bí? Olúwa yóò sì fi ìre san èyí ti ìwọ ṣe fún mi lónìí.
20 Or, je sais que certainement tu régneras, et que la royauté d’Israël te restera acquise.
Wò ó, èmi mọ̀ nísinsin yìí pé, nítòótọ́ ìwọ ó jẹ ọba, àti pé ìjọba Israẹli yóò sì fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ rẹ.
21 Jure-moi donc par l’Eternel que tu ne détruiras pas ma postérité après moi et que tu ne retrancheras pas mon nom de la maison de mon père."
Sì búra fún mi nísinsin yìí ní orúkọ Olúwa, pé, ìwọ kì yóò gé irú-ọmọ mi kúrò lẹ́yìn mi, àti pé, ìwọ kì yóò pa orúkọ mi run kúrò ní ìdílé baba mi.”
22 David en fit le serment à Saül. Celui-ci retourna dans sa maison, et David et ses hommes montèrent vers leur abri.
Dafidi sì búra fún Saulu. Saulu sì lọ sí ilé rẹ̀; ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì gòkè lọ sí ihò náà.

< 1 Samuel 24 >