< 1 Samuel 23 >

1 On annonça à David que des Philistins attaquaient Keïla et pillaient les granges.
Wọ́n sì wí fún Dafidi pé, “Sá wò ó, àwọn ará Filistini ń bá ará Keila jagun, wọ́n sì ja àwọn ilẹ̀ ìpakà lólè.”
2 Et David consulta le Seigneur, disant: "Dois-je y aller et battrai-je ces Philistins?" Le Seigneur lui répondit: "Va, tu battras les Philistins et tu dégageras Keïla."
Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Ṣé kí èmi ó lọ kọlu àwọn ará Filistini wọ̀nyí bí?” Olúwa sì wí fún Dafidi pé, “Lọ kí o sì kọlu àwọn ará Filistini kí o sì gba Keila sílẹ̀.”
3 Mais les gens de David lui dirent: "Certes, ici, en Juda, nous sommes inquiets, combien plus si nous allons à Keïla, vers les lignes des Philistins!"
Àwọn ọmọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, àwa ń bẹ̀rù níhìn-ín yìí ní Juda; ǹjẹ́ yóò ti rí nígbà ti àwa bá dé Keila láti fi ojú ko ogun àwọn ara Filistini?”
4 De nouveau, David consulta le Seigneur, qui lui répondit: "Va, descends à Keïla, je ferai tomber les Philistins en ton pouvoir."
Dafidi sì tún béèrè lọ́dọ̀ Olúwa. Olúwa sì dá a lóhùn, ó sì wí pé, “Dìde, kí o sọ̀kalẹ̀ lọ sí Keila, nítorí pé èmi ó fi àwọn ará Filistini náà lé ọ lọ́wọ́.”
5 David alla avec ses hommes à Keïla, attaqua les Philistins, emmena leur bétail et leur infligea une grande défaite; David délivra ainsi les habitants de Keïla.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Keila, wọ́n sì bá àwọn ará Filistini jà, wọ́n sì kó ohun ọ̀sìn wọn, wọ́n sì fi ìparun ńlá pa wọ́n. Dafidi sì gba àwọn ará Keila sílẹ̀.
6 Or, lorsque Ebiatar, fils d’Ahimélec, s’était réfugié auprès de David vers Keïla, il avait emporté l’éphod avec lui.
Ó sì ṣe, nígbà tí Abiatari ọmọ Ahimeleki fi sá tọ Dafidi lọ ní Keila, ó sọ̀kalẹ̀ òun pẹ̀lú efodu kan lọ́wọ́ rẹ̀.
7 Ayant appris que David était entré dans Keïla, Saül dit: "Dieu le livre en mon pouvoir, car il s’est enfermé, en entrant dans une ville munie de portes et de verrous."
A sì sọ fún Saulu pé Dafidi wá sí Keila. Saulu sì wí pé, “Ọlọ́run ti fi í lé mi lọ́wọ́; nítorí tí ó ti sé ara rẹ̀ mọ́ ní ti wíwá tí ó wá sí ìlú tí ó ní ìlẹ̀kùn àti kẹrẹ.”
8 Alors Saül convoqua tout le peuple à la guerre, l’invitant à descendre à Keïla pour assiéger David et son monde.
Saulu sì pe gbogbo àwọn ènìyàn náà jọ sí ogun, láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Keila, láti ká Dafidi mọ́ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀.
9 David, instruit des mauvais desseins de Saül à son égard, dit au prêtre Ebiatar: "Fais avancer l’éphod."
Dafidi sì mọ̀ pé Saulu ti gbèrò búburú sí òun; ó sì wí fún Abiatari àlùfáà náà pé, “Mú efodu náà wá níhìn-ín yìí!”
10 Puis David dit: "Seigneur, Dieu d’Israël, ton serviteur a appris que Saül cherche à pénétrer dans Keïla pour détruire cette ville à cause de moi.
Dafidi sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, lóòótọ́ ni ìránṣẹ́ rẹ ti gbọ́ pé Saulu ń wá ọ̀nà láti wá sí Keila, láti wá fọ́ ìlú náà nítorí mi.
11 Les bourgeois de Keïla me livreront-ils en sa main? Saül y viendra-t-il, comme ton serviteur l’a ouï dire? Seigneur, Dieu d’Israël, veuille le faire savoir à ton serviteur." Le Seigneur répondit: "Il viendra"
Àwọn àgbà ìlú Keila yóò fi mí lé e lọ́wọ́ bí? Saulu yóò ha sọ̀kalẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ rẹ ti gbọ́ bí?” Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èmi bẹ̀ ọ́, wí fún ìránṣẹ́ rẹ. Olúwa sì wí pé, “Yóò sọ̀kalẹ̀ wá.”
12 David reprit: "Les bourgeois de Keïla me livreront-ils avec mes hommes aux mains de Saül? ils vous livreront," répondit le Seigneur.
Dafidi sì wí pé, “Àwọn àgbà ìlú Keila yóò fi èmi àti àwọn ọmọkùnrin mi lé Saulu lọ́wọ́ bí?” Olúwa sì wí pé, “Wọn ó fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́.”
13 Alors David se leva avec ses gens, au nombre d’environ six cents hommes, et ils sortirent de Keïla, prenant une autre direction. Saül, ayant appris que David s’était échappé de Keïla, renonça à se mettre en campagne.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ tí wọ́n tó ẹgbẹ̀ta ènìyàn sì dìde, wọ́n lọ kúrò ní Keila, wọ́n sì lọ sí ibikíbi tí wọ́n lè rìn lọ. A sì wí fún Saulu pé, “Dafidi ti sá kúrò ní Keila; kò sì lọ sí Keila mọ́.”
14 David s’établit dans le désert en des points sûrs; il resta sur la montagne, au désert de Ziph. Saül le cherchait tout ce temps, mais Dieu ne le laissa pas tomber en son pouvoir.
Dafidi sì ń gbé ní aginjù, níbi tí ó ti sá pamọ́ sí, ó sì ń gbé níbi òkè ńlá kan ní aginjù Sifi. Saulu sì ń wá a lójoojúmọ́, ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò fi lé e lọ́wọ́.
15 David sut que Saül était sorti pour attenter à sa vie, et il se tint dans la forêt du désert de Ziph.
Nígbà tí Dafidi wà ní Horeṣi ní aginjù Sifi, Dafidi sì rí i pé, Saulu ti jáde láti wá ẹ̀mí òun kiri.
16 AIors Jonathan, fils de Saül, se mit en route, se rendit auprès de David dans la forêt, et l’encouragea au nom du Seigneur,
Jonatani ọmọ Saulu sì dìde, ó sì tọ Dafidi lọ nínú igbó Horeṣi, ó sì gbà á ní ìyànjú nípa ti Ọlọ́run.
17 lui disant: "Ne crains rien, la main de Saül, mon père, ne t’atteindra point; tu règneras sur Israël et moi je serai ton second; Saül, mon père, le sait bien aussi."
Òun sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí tí ọwọ́ Saulu baba mi kì yóò tẹ̀ ọ́. Ìwọ ni yóò jẹ ọba lórí Israẹli, èmi ni yóò sì ṣe ibìkejì rẹ. Saulu baba mi mọ̀ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.”
18 Tous deux firent alliance devant le Seigneur; David resta dans la forêt, et Jonathan regagna sa maison.
Àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn níwájú Olúwa; Dafidi sì jókòó nínú igbó Horeṣi. Jonatani sì lọ sí ilé rẹ̀.
19 Des Ziphiens montèrent auprès de Saül, à Ghibea, pour lui dire: "Sais-tu? David se cache parmi nous, dans les abris de la forêt, sur la colline de Hakhila, qui est à droite du désert.
Àwọn ará Sifi sì gòkè tọ Saulu wá sí Gibeah, wọ́n sì wí pé, “Ṣé Dafidi ti fi ara rẹ̀ pamọ́ sọ́dọ̀ wa ní ibi gíga ìsápamọ́sí ní Horeṣi, ní òkè Hakila, tí ó wà níhà gúúsù ti Jeṣimoni.
20 Et maintenant, ô roi, vas-y absolument à ton gré, nous nous chargeons de te le livrer."
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ọba, sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bi gbogbo ìfẹ́ tí ó wà ní ọkàn rẹ láti sọ̀kalẹ̀: ipa tí àwa ní láti fi lé ọba lọ́wọ́.”
21 Saül répondit: "Soyez bénis de l’Eternel, pour votre sollicitude à mon égard!
Saulu sì wí pé, “Alábùkún fún ni ẹ̀yin nípa Olúwa; nítorí pé ẹ̀yin ti káàánú fún mi.
22 Allez, je vous prie, prenez encore vos dispositions pour connaître et observer l’endroit où il se tient et savoir qui l’y a vu, car on m’a dit qu’il est fertile en ruses.
Lọ, èmi bẹ̀ yín, ẹ tún múra, kí ẹ sì mọ̀ ki ẹ si rí ibi tí ẹsẹ̀ rẹ̀ gbé wà, àti ẹni tí ó rí níbẹ̀: nítorí tí a ti sọ fún mi pé, ọgbọ́n ni ó ń lò jọjọ.
23 Voyez et reconnaissez toutes les retraites où il peut se cacher, venez me retrouver une fois bien renseignés, et j’irai avec vous; et s’il est dans le pays, je le rechercherai dans toutes les familles de Juda."
Ẹ sì wò, kí ẹ sì mọ ibi ìsápamọ́ tí ó máa ń sá pamọ́ sí, kí ẹ sì tún padà tọ̀ mí wá, kí èmi lè mọ̀ dájú; èmi ó sì bá yín lọ: yóò sì ṣe bí ó bá wà ní ilẹ̀ Israẹli, èmi ó sì wá a ní àwárí nínú gbogbo ẹgbẹ̀rún Juda!”
24 Ils partirent donc dans la direction de Ziph, précédant Saül, tandis que David, avec ses hommes, était dans le désert de Maon, dans la plaine, vers la droite du désert.
Wọ́n sì dìde, wọ́n sì ṣáájú Saulu lọ sí Sifi, ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wà ní aginjù Maoni, ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ níhà gúúsù ti Jeṣimoni.
25 Saül et ses gens se mirent à sa recherche. David, informé, descendit le long des rochers, mais resta dans le désert de Maon; Saül, l’apprenant, poursuivit David dans le désert de Maon.
Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ ń wá a. Wọ́n sì sọ fún Dafidi: ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí ibi òkúta kan, ó sì jókòó ní aginjù ti Maoni. Saulu sì gbọ́, ó sì lépa Dafidi ní aginjù Maoni.
26 Saül cheminait d’un côté de la montagne, tandis que David et ses hommes suivaient l’autre versant de la montagne. David s’avançait en toute hâte pour échapper à Saül, et celui-ci, avec ses gens, cernait David et sa troupe pour les capturer.
Saulu sì ń rin apá kan òkè kan, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ní apá kejì òkè náà. Dafidi sì yára láti sá kúrò níwájú Saulu; nítorí pé Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ti rọ̀gbà yí Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ká láti mú wọn.
27 Or, un messager vint dire à Saül: "Viens vite, les Philistins se sont répandus dans le pays."
Ṣùgbọ́n oníṣẹ́ kan sì tọ Saulu wá ó sì wí pé, “Ìwọ yára kí o sì wá, nítorí tí àwọn Filistini ti gbé ogun ti ilẹ̀ wa.”
28 Et Saül cessa de poursuivre David et alla à la rencontre des Philistins. C’Est pourquoi on appela ce lieu le Rocher de la Séparation.
Saulu sì padà kúrò ní lílépa Dafidi, ó sì lọ pàdé àwọn Filistini nítorí náà ni wọ́n sì ṣe ń pe ibẹ̀ náà ní Selahamalekoti (èyí tí ó túmọ̀ sí “Òkúta Ìpinyà”).
29 David remonta de là et s’arrêta dans les abris d’En-Ghedi.
Dafidi sì gòkè láti ibẹ̀ lọ, ó sì jókòó níbi tí ó sá pamọ́ sí ní En-Gedi.

< 1 Samuel 23 >