< 1 Chroniques 5 >

1 Voici les descendants de Ruben, le premier-né d’Israël. (C’Était, en effet, le premier-né, mais comme il avait profané la couche de son père, son droit d’aînesse fut attribué aux fils de Joseph, fils d’Israël, sans que ce dernier portât, dans les généalogies, le titre d’aîné.
Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí Israẹli. (Nítorí òun ni àkọ́bí; ṣùgbọ́n, bí ó ti ṣe pé ó ba ibùsùn baba rẹ̀ jẹ́, a fi ogún ìbí rẹ̀ fún àwọn ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli: a kì yóò sì ka ìtàn ìdílé náà gẹ́gẹ́ bí ipò ìbí.
2 Si Juda l’emporta sur ses frères et donna le jour à un prince, c’est à Joseph que fut dévolue l’aînesse.)
Nítorí Juda borí àwọn arákùnrin rẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni aláṣẹ ti ń jáde wá; ṣùgbọ́n ogún ìbí jẹ́ ti Josẹfu),
3 Fils de Ruben, premier-né d’Israël: Hénoc, Pallou, Heçrôn et Karmi.
àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku àti Pallu, Hesroni àti Karmi.
4 Fils de Joël: Chemaïa; celui-ci eut pour fils Gog, celui-ci Chimeï,
Àwọn ọmọ Joẹli: Ṣemaiah ọmọ rẹ̀, Gogu ọmọ rẹ̀, Ṣimei ọmọ rẹ̀.
5 celui-ci Mikha, celui-ci Reaïa, celui-ci Baal,
Mika ọmọ rẹ̀, Reaiah ọmọ rẹ̀, Baali ọmọ rẹ̀.
6 celui-ci Beêra, qu’exila Tilgath Pilneécer, roi d’Assyrie. C’Était un phylarque de Ruben.
Beera ọmọ rẹ̀, tí Tiglat-Pileseri ọba Asiria kó ní ìgbèkùn lọ. Ìjòyè àwọn ọmọ Reubeni ni Beera jẹ́.
7 Ses frères, selon leurs familles, enregistrées d’après leur généalogie, étaient Yeïêl, en tête, puis Zekhariahou,
Àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn: Jeieli àti Sekariah ni olórí,
8 Béla, fils d’Azaz, fils de Chéma, fils de Joël; Béla demeurait à Aroêr et s’étendait jusqu’à Nebo et Baal Meôn.
àti Bela ọmọ Asasi ọmọ Ṣema, ọmọ Joẹli. Wọ́n tí ń gbé Aroeri àní títí dé Nebo àti Baali-Meoni.
9 A l’Est, son habitation atteignait l’entrée du désert, depuis le fleuve de l’Euphrate, car leurs troupeaux s’étaient accrus dans le pays de Galaad.
Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àtiwọ aginjù láti odò Eufurate; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ sí i ní ilẹ̀ Gileadi.
10 Au temps de Saül, ils avaient fait la guerre avec les Hagriites, qui étaient tombés en leur pouvoir; ils s’étaient installés dans leurs tentes, sur toute la bande orientale attenante au Galaad.
Àti ní ọjọ́ Saulu, wọ́n bá àwọn ọmọ Hagari jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gileadi.
11 Les enfants de Gad, à l’opposite, demeuraient dans le pays du Basan jusqu’à Salca.
Àti àwọn ọmọ Gadi ń gbé lékè wọn, ní ilẹ̀ Baṣani títí dé Saleka:
12 En tête venait Joël, en second Chafam, puis Yanaï et Chafat dans le Basan.
Joẹli jẹ́ olórí, Ṣafamu ìran ọmọ Janai, àti Ṣafati ni Baṣani.
13 Leurs frères, classés selon leurs maisons paternelles, étaient: Mikhaêl, Mechoullam, Chéba, Yoraï, Yakân, Zïa et Eber, en tout sept.
Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní: Mikaeli, Meṣullamu Ṣeba, Jorai, Jaka, Sia àti Eberi méje.
14 Ceux-ci furent les fils d’Abihaïl, fils de Houri, fils de Yaroab, fils de Galaad, fils de Mikhaël, fils de Yechichaï, fils de Yahdo, fils de Bouz.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Abihaili, ọmọ Huri, ọmọ Jeroa, ọmọ Gileadi, ọmọ Mikaeli, ọmọ Jeṣiṣai, ọmọ Jado, ọmọ Busi.
15 Ahi, fils d’Abdiël, fils de Gouni, était le chef de leur clan familial.
Ahi, ọmọ Adbeeli, ọmọ Guni, olórí ilé àwọn baba wọn.
16 Ils demeuraient dans le Galaad, le Basan et leurs bourgades, et dans tous les pâturages de Saron formant issues.
Wọ́n sì ń gbé Gileadi ní Baṣani àti nínú àwọn ìlú rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbèríko Ṣaroni, ní agbègbè wọn.
17 Tous furent enregistrés au temps de Jotham, roi de Juda, et au temps de Jéroboam, roi d’Israël.
Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn ìdílé, ní ọjọ́ Jotamu ọba Juda, àti ní ọjọ́ Jeroboamu ọba Israẹli.
18 Les Rubénites, les Gadites et ceux de la demi-tribu de Manassé, qui étaient guerriers, porteurs de boucliers et d’épées, archers et exercés aux combats, formaient un effectif de quarante-quatre mille sept cent soixante soldats.
Àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé asà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹgbẹ̀rìnlélógún dín ogójì ènìyàn, tí ó jáde lọ sí ogún náà.
19 Ils firent la guerre aux Hagriites et aux gens de Yetour, de Nafich et de Nodab.
Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hagari jagun, pẹ̀lú Jeturi, àti Nafiṣi àti Nadabu.
20 Ils furent victorieux et reçurent la soumission des Hagriites et de tous leurs auxiliaires, car ils avaient invoqué Dieu dans le combat et avaient été exaucés pour avoir mis leur confiance en Lui.
Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hagari lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí tiwọn ké pe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
21 Ils razzièrent leurs troupeaux, leurs chameaux au nombre de cinquante mille, deux cent cinquante mille têtes de menu bétail, deux mille ânes et cent mille personnes.
Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ìbákasẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùn-ún, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì, àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn-ún.
22 Beaucoup avaient succombé dans le combat, car Dieu est le maître de la guerre. Ils occupèrent ces lieux jusqu’à l’exil.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbèkùn.
23 Ceux de la demi-tribu de Manassé habitaient le pays qui s’étend du Basan à Baal-Hermôn, à Senir et à la montagne de Hermôn. Ils étaient nombreux.
Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Baṣani títí dé Baali-Hermoni, àti Seniri àti títí dé òkè Hermoni.
24 Voici quels furent les chefs de leurs clans familiaux: Efer, Yicheï, Eliël, Azriël, Jérémie, Hodavia et Yahdiël. C’Étaient de vaillants hommes, des gens fameux, que ces chefs de leurs clans familiaux.
Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Eferi, Iṣi, Elieli, Asrieli, Jeremiah, Hodafiah àti Jahdieli àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn.
25 Mais ils devinrent infidèles au Dieu de leurs ancêtres, en se prostituant aux divinités des peuples du pays que Dieu avait exterminés devant eux.
Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì ṣe àgbèrè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn.
26 Alors le Dieu d’Israël excita l’esprit de Poul, roi d’Assyrie, et celui de Tilgat-Pilnésser, roi d’Assyrie, qui déporta les Rubénites, les Gadites et ceux de la demi-tribu de Manassé et les amena à Halah, Habor, Hara, et près du fleuve de Gozân, où ils sont encore aujourd’hui.
Nítorí náà Ọlọ́run Israẹli ru ẹ̀mí Pulu ọba Asiria sókè (èyí ni Tiglat-Pileseri ọba Asiria), ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase lọ sí ìgbèkùn. Ó sì kó wọn wá sí Hala, àti Habori, àti Harani, àti sí etí odò Gosani; títí dí òní yìí.

< 1 Chroniques 5 >