< 1 Chroniques 14 >

1 Hiram, roi de Tyr, envoya une députation à David, avec du bois de cèdre, des maçons et des charpentiers pour lui bâtir une maison.
Nísinsin yìí Hiramu àti ọba Tire rán oníṣẹ́ sí Dafidi, àti pẹ̀lú igi kedari pẹ̀lú àwọn ọ̀mọ̀lé àti gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ààfin fún un.
2 Et David reconnut que le Seigneur l’avait destiné à régner sur Israël, et lui avait accordé une royauté glorieuse en faveur de son peuple Israël.
Dafidi sì mọ Israẹli àti pé Olúwa ti fi òun ṣe ọba lórí Israẹli àti pé ìjọba rẹ̀ ga jùlọ nítorí ti àwọn ènìyàn rẹ̀.
3 David prit encore des épouses dans Jérusalem, et il engendra encore des fils et des filles.
Ní Jerusalẹmu Dafidi mú ọ̀pọ̀ ìyàwó ó sì di baba àwọn ọmọ ọkùnrin púpọ̀ àti ọmọbìnrin.
4 Voici les noms de ceux qui lui naquirent à Jérusalem: Chammoua, Chobab, Nathan et Salomon;
Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ náà tí wọ́n bí fún un níbẹ̀: Ṣammua, Ṣobabu, Natani, Solomoni,
5 Yibhar, Elichoua, Elpélet;
Ibhari, Eliṣua, Elifeleti,
6 Nogah, Néfeg et Yafia;
Noga, Nefegi, Jafia,
7 Elichama, Beélyada et Elifélet.
Eliṣama, Beeliada, àti Elifeleti.
8 Les Philistins, ayant su que David avait été oint comme roi de tout Israël, montèrent tous pour chercher à le prendre; David l’apprit et sortit à leur rencontre.
Nígbà tí àwọn ará Filistini gbọ́ pé a ti fi àmì òróró yàn Dafidi ní ọba lórí gbogbo Israẹli, wọ́n sì lọ sókè pẹ̀lú ipá láti wá a rí, ṣùgbọ́n Dafidi gbọ́ nípa rẹ̀ ó sì jáde lọ láti pàdé wọn.
9 Les Philistins étaient arrivés et s’étaient déployés dans la vallée de Refaïm.
Nísinsin yìí àwọn ará Filistini ti wá láti gbógun ti àfonífojì Refaimu;
10 Alors David consulta Dieu en disant: "Dois-je monter vers les Philistins? Les livreras-tu entre mes mains?" Le Seigneur répondit à David: "Monte, je les livrerai entre tes mains.
Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run wí pé, “Kí èmi kí ó gòkè tọ àwọn ará Filistini lọ bí? Ìwọ ó ha fi wọ́n lé mi lọ́wọ́?” Olúwa sì wí fún un pé, “Gòkè lọ èmi ó sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.”
11 On monta à Baal-Peraçim, et David les y battit. Et il dit: "Dieu a dispersé mes ennemis par ma main, comme une eau débordée." C’Est pour cela que cet endroit fut nommé Baal-Peracim.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gòkè lọ sí Baali-Perasimu, níbẹ̀ ó sì kọlù wọ́n. Ó sí wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí omi tí ya jáde, Ọlọ́run ti ya Dafidi lórí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀lú ọwọ́ mi.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń pè ibẹ̀ ní Baali-Perasimu.
12 Ils laissèrent là leurs idoles, qui furent brûlées sur l’ordre de David.
Àwọn ará Filistini sì ti fi àwọn òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀. Dafidi sì pa á láṣẹ láti jó wọn nínú iná.
13 Mais de nouveau les Philistins se déployèrent dans la vallée.
Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn ará Filistini gbógun wọ́n sì fọ́nká àfonífojì,
14 David consulta encore Dieu, et Dieu lui répondit: "Ne monte pas à leur suite: fais un demi-tour et marche sur eux du côté des bekhaïm.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì tún béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Ọlọ́run sì dalóhùn pé, “Má ṣe gòkè tààrà, ṣùgbọ́n ẹ yí wọn ká, kí ẹ sì mú wọn níwájú igi muliberi.
15 Or, lorsque tu entendras un bruit de pas sur les cimes des bekhaïm, engage le combat, car alors Dieu sera venu à ton secours, pour que tu battes l’armée des Philistins."
Tí ó bá sì ṣe, tí ẹ̀yin bá ti gbọ́ ìró ẹsẹ̀ ní orí òkè igi muliberi, ẹ jáde fún ogun, nítorí èyí yóò fihàn pé Ọlọ́run ti jáde níwájú rẹ láti kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini.”
16 David se conforma aux instructions de Dieu, et ils battirent l’armée des Philistins depuis Ghibôn jusqu’à Ghézer.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ṣe ohun tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini láti gbogbo ọ̀nà Gibeoni lọ sí Geseri.
17 Et la renommée de David se répandit dans tous les pays, et l’Eternel imprima sa terreur à toutes les nations.
Bẹ́ẹ̀ ni òkìkí Dafidi tàn ká gbogbo ilẹ̀ káàkiri, Olúwa sì mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè bẹ̀rù rẹ̀.

< 1 Chroniques 14 >