< Zacharie 10 >

1 Demandez à l’Éternel de la pluie, au temps de la pluie de la dernière saison. L’Éternel fera des éclairs, et il leur donnera des ondées de pluie: à chacun de l’herbe dans son champ.
Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa; Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná, tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn, fún olúkúlùkù koríko ní pápá.
2 Car les théraphim ont dit des paroles de vanité, et les devins ont vu un mensonge, et ils ont prononcé des songes trompeurs; ils consolent en vain. C’est pourquoi ils sont partis comme le menu bétail; ils sont opprimés, parce qu’il n’y a point de berger.
Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán, àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké, wọn sì tí rọ àlá èké; wọ́n ń tu ni nínú lásán, nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn, a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.
3 Ma colère s’est embrasée contre les bergers, et je punirai les boucs; car l’Éternel des armées a visité son troupeau, la maison de Juda, et il en a fait son cheval de gloire dans la bataille.
“Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran, èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀, ilé Juda wò, yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.
4 De lui est la pierre angulaire, de lui le clou, de lui l’arc de guerre, de lui sortent tous les dominateurs ensemble.
Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.
5 Et ils seront dans la bataille comme des hommes forts qui foulent aux pieds la boue des rues; et ils combattront, car l’Éternel sera avec eux; et ceux qui montent les chevaux seront couverts de honte.
Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun, nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn, wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.
6 Et je rendrai forte la maison de Juda, et je sauverai la maison de Joseph, et je les ramènerai, car j’userai de miséricorde envers eux; et ils seront comme si je ne les avais pas rejetés; car je suis l’Éternel, leur Dieu, et je les exaucerai.
“Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára, èmi o sì gba ilé Josẹfu là, èmi ó sì tún mú wọn padà nítorí mo tí ṣàánú fún wọn, ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù; nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi o sì gbọ́ tiwọn
7 Et [ceux d’]Éphraïm seront comme un homme fort, et leur cœur se réjouira comme par le vin, et leurs fils [le] verront et se réjouiront; leur cœur s’égaiera en l’Éternel.
Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára, ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì: àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í, wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.
8 Je les sifflerai et je les rassemblerai, car je les ai rachetés; et ils multiplieront comme ils avaient multiplié.
Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ; nítorí èmi tí rà wọ́n padà; wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.
9 Et je les sèmerai parmi les peuples, et ils se souviendront de moi dans les [pays] éloignés, et ils vivront avec leurs fils, et ils reviendront.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè: síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn; wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọn ó sì tún padà.
10 Et je les ramènerai du pays d’Égypte, et je les rassemblerai de l’Assyrie, et je les ferai venir au pays de Galaad et au Liban, et il ne sera pas trouvé [assez de place] pour eux.
Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria. Èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.
11 Et il passera par la mer, [par] l’affliction, et dans la mer il frappera les vagues, et toutes les profondeurs du Nil seront desséchées, et l’orgueil de l’Assyrie sera abattu, et le sceptre de l’Égypte sera ôté.
Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já, yóò sì bori rírú omi nínú Òkun, gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ, a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀, ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.
12 Et je les fortifierai en l’Éternel, et ils marcheront en son nom, dit l’Éternel.
Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa; wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,” ni Olúwa wí.

< Zacharie 10 >