< Psaumes 77 >
1 Au chef de musique. Sur Jeduthun. D’Asaph. Psaume. Ma voix s’adresse à Dieu, et je crierai; ma voix s’adresse à Dieu, et il m’écoutera.
Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Ti Asafu. Saamu. Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́; mo kígbe sí Ọlọ́run láti gbọ́ tèmi.
2 Au jour de ma détresse j’ai cherché le Seigneur; ma main était étendue durant la nuit et ne se lassait point; mon âme refusait d’être consolée.
Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú, mo wá Olúwa; ní òru ni mo na ọwọ́ mi jáde ní àìkáárẹ̀ ọkàn mí sì kọ̀ láti tù ú nínú.
3 Je me souvenais de Dieu, et j’étais agité; je me lamentais, et mon esprit défaillait. (Sélah)
Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run, mo sì kẹ́dùn; mo ṣe àròyé, ẹ̀mí mi sì rẹ̀wẹ̀sì. (Sela)
4 Tu tiens ouvertes mes paupières; je suis inquiet, et je ne parle pas.
Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun, mo dààmú tó bẹ́ẹ̀ tí ń kò le sọ̀rọ̀.
5 Je pense aux jours d’autrefois, aux années des siècles passés.
Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì; ọdún pípẹ́ sẹ́yìn;
6 Je me souviens, de nuit, de mon cantique; je médite en mon cœur, et mon esprit cherche diligemment.
mo rántí orin mi ní òru. Èmi ń bá àyà mi sọ̀rọ̀, ọkàn mi sì ń ṣe àwárí jọjọ.
7 Le Seigneur rejettera-t-il pour toujours? et ne montrera-t-il plus sa faveur?
“Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé? Ki yóò ha ṣe ojúrere rẹ̀ mọ́?
8 Sa bonté a-t-elle cessé pour toujours? Sa parole a-t-elle pris fin de génération en génération?
Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé? Ìlérí rẹ̀ ha kùnà títí ayé?
9 Dieu a-t-il oublié d’user de grâce? A-t-il enfermé ses miséricordes dans la colère? (Sélah)
Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú? Ní ìbínú rẹ̀, ó ha sé ojúrere rẹ̀ mọ́?” (Sela)
10 Et je dis: C’est ici mon infirmité; – [je me souviendrai des] années de la droite du Très-haut,
Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi, pé ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
11 Je me souviendrai des œuvres de Jah; car je me souviendrai de tes merveilles d’autrefois,
Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
12 Et je penserai à toute ton œuvre, et je méditerai tes actes.
Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo, pẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára rẹ.
13 Ô Dieu! ta voie est dans le lieu saint. Où y a-t-il un dieu grand comme Dieu?
Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́. Ọlọ́run wo ni ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
14 Toi, tu es le Dieu qui fais des merveilles; tu as fait connaître ta puissance parmi les peuples.
Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu; ìwọ fi agbára rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
15 Tu as racheté par [ton] bras ton peuple, les fils de Jacob et de Joseph. (Sélah)
Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà, àwọn ọmọ Jakọbu àti Josẹfu. (Sela)
16 Les eaux t’ont vu, ô Dieu! les eaux t’ont vu, elles ont tremblé; les abîmes aussi se sont émus.
Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run, nígbà tí àwọn omi rí ọ, ẹ̀rù bà wọ́n, nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
17 Les nuées ont versé des eaux, les nuages ont fait retentir une voix, et tes flèches se sont promenées.
Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀, àwọsánmọ̀ fi àrá dáhùn; ọfà rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú.
18 La voix de ton tonnerre était dans le tourbillon, les éclairs ont illuminé le monde; la terre en a été émue et a tremblé.
Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé; ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
19 Ta voie est dans la mer, et tes sentiers dans les grandes eaux; et tes traces ne sont pas connues.
Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun, ọ̀nà la omi alágbára kọjá ipa rẹ̀ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá, nítòótọ́ a kò rí ojú ẹsẹ̀ rẹ̀.
20 Tu as conduit ton peuple comme un troupeau, par la main de Moïse et d’Aaron.
Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.