< Psaumes 59 >

1 Au chef de musique. Al-Tashkheth. De David. Mictam; quand Saül envoya, et qu’on surveilla sa maison, afin de le faire mourir. Délivre-moi de mes ennemis, ô mon Dieu! protège-moi contre ceux qui s’élèvent contre moi.
Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
2 Délivre-moi des ouvriers d’iniquité, et sauve-moi des hommes de sang.
Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
3 Car voici, ils ont dressé des embûches contre ma vie, des hommes forts se sont assemblés contre moi, – non pour ma transgression, ni pour mon péché, ô Éternel!
Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
4 Sans qu’il y ait d’iniquité [en moi] ils courent et se préparent; éveille-toi pour venir à ma rencontre, et regarde.
Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
5 Et toi, Éternel, Dieu des armées! Dieu d’Israël! réveille-toi pour visiter toutes les nations; n’use de grâce envers aucun de ceux qui trament l’iniquité. (Sélah)
Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
6 Ils reviennent le soir, ils hurlent comme un chien, et font le tour de la ville.
Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
7 Voici, de leur bouche ils vomissent l’injure, des épées sont sur leurs lèvres; car, [disent-ils], qui [nous] entend?
Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
8 Mais toi, Éternel, tu te riras d’eux, tu te moqueras de toutes les nations.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
9 [À cause de] sa force, je regarderai à toi; car Dieu est ma haute retraite.
Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
10 Le Dieu qui use de bonté envers moi me préviendra; Dieu me fera voir [mon plaisir] en mes ennemis.
Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
11 Ne les tue pas, de peur que mon peuple ne l’oublie; fais-les errer par ta puissance, et abats-les, ô Seigneur, notre bouclier!
Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
12 [À cause du] péché de leur bouche, – la parole de leurs lèvres, – qu’ils soient pris dans leur orgueil, et à cause de la malédiction et des mensonges qu’ils profèrent!
Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
13 Consume-[les] en ta fureur, consume-[les], et qu’ils ne soient plus, et qu’ils sachent que Dieu domine en Jacob jusqu’aux bouts de la terre. (Sélah)
pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
14 Et ils reviendront le soir, ils hurleront comme un chien, et feront le tour de la ville.
Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
15 Ils errent çà et là pour trouver à manger; ils y passeront la nuit s’ils ne sont pas rassasiés.
Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
16 Et moi je chanterai ta force, et, dès le matin, je célébrerai avec joie ta bonté; car tu m’as été une haute retraite et un refuge au jour où j’étais dans la détresse.
Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
17 Ma force! à toi je chanterai; car Dieu est ma haute retraite, le Dieu qui use de bonté envers moi.
Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.

< Psaumes 59 >