< Psaumes 21 >

1 Au chef de musique. Psaume de David. Éternel! le roi se réjouira en ta force, et combien s’égaiera-t-il en ton salut!
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Háà! Olúwa, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ, àti ní ìgbàlà rẹ, yóò ti yọ̀ pẹ́ tó!
2 Tu lui as donné le désir de son cœur, et tu ne lui as pas refusé la requête de ses lèvres. (Sélah)
Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu rẹ̀. (Sela)
3 Car tu l’as prévenu par des bénédictions excellentes; tu as mis sur sa tête une couronne d’or fin.
Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà ìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.
4 Il t’a demandé la vie: tu [la] lui as donnée, – une longueur de jours pour toujours et à perpétuité!
Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un, àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.
5 Sa gloire est grande dans ta délivrance; tu l’as revêtu de majesté et de magnificence.
Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un; ìwọ sì jẹ́ kí iyì ọláńlá rẹ̀ wà lára rẹ.
6 Car tu l’as mis pour bénédictions à toujours; tu l’as rempli de joie par ta face.
Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un: ìwọ sì mú inú rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u rẹ̀.
7 Car le roi se confie en l’Éternel, et, par la bonté du Très-haut, il ne sera pas ébranlé.
Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa; nípasẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá-ògo tí kì í kùnà kì yóò sípò padà.
8 Ta main trouvera tous tes ennemis, ta droite trouvera ceux qui te haïssent.
Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí; ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò wá àwọn tí o kórìíra rẹ rí.
9 Tu les rendras comme un four de feu, au temps de ta présence; l’Éternel, dans sa colère, les engloutira, et le feu les dévorera.
Nígbà tí ìwọ bá yọ ìwọ yóò mú wọn dàbí iná ìléru. Olúwa yóò gbé wọn mì nínú ìbínú rẹ̀, àti pé iná rẹ̀ yóò jó wọn run.
10 Tu feras périr leur fruit de dessus la terre, et leur semence d’entre les fils des hommes.
Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀, àti irú-ọmọ wọn kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
11 Car ils ont essayé de faire venir du mal sur toi, et ont médité des desseins qu’ils n’ont pu mettre à exécution.
Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ wọ́n sì ń pète ìwà ìkà, wọn kì yóò ṣe àṣeyọrí.
12 Car tu leur feras tourner le dos, quand tu ajusteras la corde de ton arc contre leurs faces.
Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà nígbà tí o bá pinnu láti ta wọ́n ní ọfà.
13 Sois exalté, ô Éternel, dans ta force! Nous chanterons, et nous célébrerons ta puissance.
Gbígbéga ni ọ́ Olúwa, nínú agbára rẹ; a ó kọrin, a ó yín agbára a rẹ̀.

< Psaumes 21 >