< Psaumes 145 >
1 Louange de David. Je t’exalterai, mon Dieu, ô Roi! et je bénirai ton nom à toujours et à perpétuité.
Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
2 Je te bénirai chaque jour, et je louerai ton nom à toujours et à perpétuité.
Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
3 L’Éternel est grand et fort digne de louange; et sa grandeur est insondable.
Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
4 Une génération célébrera tes œuvres auprès de l’autre génération, et elles raconteront tes actes puissants.
Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
5 Je parlerai de la magnificence glorieuse de ta majesté, et de tes actes merveilleux.
Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
6 Et ils diront la force de tes actes terribles, et [moi], je déclarerai tes grands faits.
Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
7 Ils feront jaillir la mémoire de ta grande bonté, et ils chanteront hautement ta justice.
Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
8 L’Éternel est plein de grâce et miséricordieux, lent à la colère, et grand en bonté.
Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
9 L’Éternel est bon envers tous, et ses compassions sont sur toutes ses œuvres.
Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
10 Toutes tes œuvres te célébreront, ô Éternel! et tes saints te béniront;
Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
11 Ils parleront de la gloire de ton royaume, et ils diront ta puissance,
Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
12 Afin de faire connaître aux fils de l’homme ses actes puissants et la magnificence glorieuse de son royaume.
kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
13 Ton royaume est un royaume de tous les siècles, et ta domination est de toutes les générations.
Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
14 L’Éternel soutient tous ceux qui tombent, et relève tous ceux qui sont courbés.
Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
15 Les yeux de tous s’attendent à toi, et tu leur donnes leur nourriture en son temps.
Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
16 Tu ouvres ta main, et tu rassasies à souhait tout ce qui a vie.
Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
17 L’Éternel est juste dans toutes ses voies, et bon dans toutes ses œuvres.
Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
18 L’Éternel est près de tous ceux qui l’invoquent, de tous ceux qui l’invoquent en vérité.
Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
19 Il accomplit le souhait de ceux qui le craignent: il entend leur cri, et les sauve.
Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
20 L’Éternel garde tous ceux qui l’aiment, et il extermine tous les méchants.
Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
21 Ma bouche dira la louange de l’Éternel; et que toute chair bénisse son saint nom, à toujours et à perpétuité.
Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.