< Nombres 33 >

1 Ce sont ici les traites des fils d’Israël, qui sortirent du pays d’Égypte, selon leurs armées, sous la main de Moïse et d’Aaron.
Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
2 Et Moïse écrivit leurs départs, selon leurs traites, suivant le commandement de l’Éternel; et ce sont ici leurs traites, selon leurs départs.
Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
3 Ils partirent de Ramsès, le premier mois, le quinzième jour du premier mois: le lendemain de la Pâque, les fils d’Israël sortirent à main levée, aux yeux de tous les Égyptiens;
Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
4 et les Égyptiens enterraient ceux que l’Éternel avait frappés parmi eux, tous les premiers-nés; et l’Éternel avait exécuté des jugements sur leurs dieux.
Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
5 Et les fils d’Israël partirent de Ramsès, et campèrent à Succoth.
Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
6 Et ils partirent de Succoth, et campèrent à Étham, qui est à l’extrémité du désert.
Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
7 Et ils partirent d’Étham et retournèrent à Pi-Hahiroth, qui est vis-à-vis de Baal-Tsephon, et campèrent devant Migdol.
Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
8 Et ils partirent de devant Hahiroth, et passèrent au milieu de la mer, vers le désert, et allèrent le chemin de trois jours dans le désert d’Étham, et campèrent à Mara.
Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
9 Et ils partirent de Mara, et vinrent à Élim; et à Élim, il y avait douze fontaines d’eau et 70 palmiers, et ils campèrent là.
Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
10 Et ils partirent d’Élim, et campèrent près de la mer Rouge.
Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
11 Et ils partirent de la mer Rouge, et campèrent dans le désert de Sin.
Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
12 Et ils partirent du désert de Sin, et campèrent à Dophka.
Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
13 Et ils partirent de Dophka, et campèrent à Alush.
Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
14 Et ils partirent d’Alush, et campèrent à Rephidim, où il n’y avait pas d’eau à boire pour le peuple.
Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
15 Et ils partirent de Rephidim, et campèrent dans le désert de Sinaï.
Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
16 Et ils partirent du désert de Sinaï, et campèrent à Kibroth-Hattaava.
Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
17 Et ils partirent de Kibroth-Hattaava, et campèrent à Hatséroth.
Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
18 Et ils partirent de Hatséroth, et campèrent à Rithma.
Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
19 Et ils partirent de Rithma, et campèrent à Rimmon-Pérets.
Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
20 Et ils partirent de Rimmon-Pérets, et campèrent à Libna.
Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
21 Et ils partirent de Libna, et campèrent à Rissa.
Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
22 Et ils partirent de Rissa, et campèrent à Kehélatha.
Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
23 Et ils partirent de Kehélatha, et campèrent dans la montagne de Shapher.
Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
24 Et ils partirent de la montagne de Shapher, et campèrent à Harada.
Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
25 Et ils partirent de Harada, et campèrent à Makhéloth.
Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
26 Et ils partirent de Makhéloth, et campèrent à Thakhath.
Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
27 Et ils partirent de Thakhath, et campèrent à Thérakh.
Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
28 Et ils partirent de Thérakh, et campèrent à Mithka.
Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
29 Et ils partirent de Mithka, et campèrent à Hashmona.
Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
30 Et ils partirent de Hashmona, et campèrent à Moséroth.
Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
31 Et ils partirent de Moséroth, et campèrent à Bené-Jaakan.
Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
32 Et ils partirent de Bené-Jaakan, et campèrent à Hor-Guidgad.
Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
33 Et ils partirent de Hor-Guidgad, et campèrent à Jotbatha.
Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
34 Et ils partirent de Jotbatha, et campèrent à Abrona.
Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
35 Et ils partirent d’Abrona, et campèrent à Étsion-Guéber.
Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
36 Et ils partirent d’Étsion-Guéber, et campèrent dans le désert de Tsin, qui est Kadès.
Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
37 Et ils partirent de Kadès, et campèrent dans la montagne de Hor, aux confins du pays d’Édom.
Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
38 Et Aaron le sacrificateur monta sur la montagne de Hor, suivant le commandement de l’Éternel, et il y mourut, en la quarantième année après que les fils d’Israël furent sortis du pays d’Égypte, le cinquième mois, le premier [jour] du mois:
Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
39 et Aaron était âgé de 123 ans, quand il mourut sur la montagne de Hor.
Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
40 Et le Cananéen, roi d’Arad, qui habitait le midi, dans le pays de Canaan, apprit que les fils d’Israël venaient.
Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
41 Et ils partirent de la montagne de Hor, et campèrent à Tsalmona.
Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
42 Et ils partirent de Tsalmona, et campèrent à Punon.
Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
43 Et ils partirent de Punon, et campèrent à Oboth.
Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
44 Et ils partirent d’Oboth, et campèrent à Ijim-Abarim, sur la frontière de Moab.
Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
45 Et ils partirent d’Ijim, et campèrent à Dibon-Gad.
Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
46 Et ils partirent de Dibon-Gad, et campèrent à Almon, vers Diblathaïm.
Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
47 Et ils partirent d’Almon vers Diblathaïm, et campèrent dans les montagnes d’Abarim, devant Nebo.
Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
48 Et ils partirent des montagnes d’Abarim, et campèrent dans les plaines de Moab, près du Jourdain de Jéricho;
Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
49 et ils campèrent près du Jourdain, depuis Beth-Jeshimoth jusqu’à Abel-Sittim, dans les plaines de Moab.
Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
50 Et l’Éternel parla à Moïse, dans les plaines de Moab, près du Jourdain de Jéricho, disant:
Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
51 Parle aux fils d’Israël, et dis-leur: Quand vous aurez passé le Jourdain [et que vous serez entrés] dans le pays de Canaan,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
52 vous déposséderez tous les habitants du pays devant vous, et vous détruirez toutes leurs figures sculptées, et vous détruirez toutes leurs images de fonte, et vous dévasterez tous leurs hauts lieux;
lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
53 et vous prendrez possession du pays, et vous y habiterez, car je vous ai donné le pays pour le posséder.
Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
54 Et vous recevrez le pays en héritage par le sort, selon vos familles: à ceux qui sont nombreux, vous augmenterez l’héritage, et à ceux qui sont peu nombreux, vous diminuerez l’héritage; là où le sort lui sera échu, là sera [l’héritage] de chacun: vous hériterez selon les tribus de vos pères.
Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
55 Et si vous ne dépossédez pas devant vous les habitants du pays, ceux d’entre eux que vous laisserez de reste seront comme des épines à vos yeux et comme des piquants dans vos côtés, et ils vous opprimeront dans le pays que vous habiterez.
“‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
56 Et il arrivera que je vous ferai à vous, comme j’ai pensé de leur faire, à eux.
Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”

< Nombres 33 >