< Néhémie 11 >

1 Et les chefs du peuple habitaient à Jérusalem: et le reste du peuple jeta le sort pour qu’un sur dix vienne habiter à Jérusalem, la ville sainte, et que les neuf [autres] parties [demeurent] dans les villes.
Nísinsin yìí àwọn olórí àwọn ènìyàn tẹ̀dó sí Jerusalẹmu, àwọn ènìyàn tókù sì dìbò láti mú ẹnìkọ̀ọ̀kan jáde nínú àwọn mẹ́wàá mẹ́wàá láti máa gbé ní Jerusalẹmu, ìlú mímọ́, nígbà tí àwọn mẹ́sàn-án tókù yóò dúró sí àwọn ìlú u wọn.
2 Et le peuple bénit tous les hommes qui s’offrirent volontairement pour habiter à Jérusalem.
Àwọn ènìyàn súre fún gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn láti gbé ní Jerusalẹmu.
3 Or ce sont ici les chefs de la province qui habitèrent à Jérusalem; mais, dans les villes de Juda, habitèrent, chacun dans sa possession, dans leurs villes, Israël, les sacrificateurs, et les lévites, et les Nethiniens, et les fils des serviteurs de Salomon.
Wọ̀nyí ni àwọn olórí agbègbè ìjọba tí wọ́n tẹ̀dó sí Jerusalẹmu (díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ìran àwọn ìránṣẹ́ Solomoni ń gbé àwọn ìlú Juda, olúkúlùkù ń gbé lórí ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní àwọn ìlú náà.
4 Et à Jérusalem habitèrent des fils de Juda, et des fils de Benjamin. – Des fils de Juda: Athaïa, fils d’Ozias, fils de Zacharie, fils d’Amaria, fils de Shephatia, fils de Mahalaleël, d’entre les fils de Pérets;
Nígbà tí àwọn ènìyàn tókù nínú àwọn Juda àti Benjamini ń gbé ní Jerusalẹmu). Nínú àwọn ọmọ Juda: Ataiah ọmọ Ussiah ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatia, ọmọ Mahalaleli, ìran Peresi;
5 et Maascéïa, fils de Baruc, fils de Col-Hozé, fils de Hazaïa, fils d’Adaïa, fils de Joïarib, fils de Zacharie, d’entre les Shilonites.
àti Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Koli-Hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣilo.
6 Tous les fils de Pérets qui habitèrent à Jérusalem: 468 hommes vaillants.
Àwọn ìran Peresi tó gbé ní Jerusalẹmu jẹ́ àádọ́rinlénírinwó ó dín méjì alágbára ọkùnrin.
7 – Et ce sont ici les fils de Benjamin: Sallu, fils de Meshullam, fils de Joëd, fils de Pedaïa, fils de Kolaïa, fils de Maascéïa, fils d’Ithiel, fils d’Ésaïe;
Nínú àwọn ìran Benjamini: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Joẹdi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jeṣaiah,
8 et après lui, Gabbaï, Sallaï: 928;
àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Gabbai àti Sallai jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rún ó lé mẹ́jọ ọkùnrin.
9 et Joël, fils de Zicri, était préposé sur eux, et Juda, fils d’Hassenua, en second, sur la ville.
Joẹli ọmọ Sikri ni olórí òṣìṣẹ́ wọn, Juda ọmọ Hasenuah sì ni olórí agbègbè kejì ní ìlú náà.
10 Des sacrificateurs: Jedahia, [fils de] Joïarib, Jakin;
Nínú àwọn àlùfáà: Jedaiah; ọmọ Joiaribu; Jakini;
11 Seraïa, fils de Hilkija, fils de Meshullam, fils de Tsadok, fils de Meraïoth, fils d’Akhitub, prince de la maison de Dieu;
Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, àwọn ni olórí tó ń bojútó ilé Ọlọ́run,
12 et leurs frères qui faisaient les travaux de la maison: 822. Et Adaïa, fils de Jerokham, fils de Pelalia, fils d’Amtsi, fils de Zacharie, fils de Pashkhur, fils de Malkija,
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ní tẹmpili jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó lé mẹ́rìnlélógún ọkùnrin: Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaiah, ọmọ Amisi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah,
13 et ses frères, chefs des pères: 242. Et Amassaï, fils d’Azareël, fils d’Akhzaï, fils de Meshillémoth, fils d’Immer;
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí ìdílé jẹ́ òjìlúgba ó lé méjì ọkùnrin: Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahsai, ọmọ Meṣilemoti, ọmọ Immeri,
14 et leurs frères, hommes forts et vaillants: 128; et Zabdiel, fils de Guedolim, était préposé sur eux.
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin jẹ́ méjìdínláàádóje. Olórí òṣìṣẹ́ ẹ wọn ni Sabdieli ọmọ Hagedolimu.
15 Et des lévites: Shemahia, fils de Hashub, fils d’Azrikam, fils de Hashabia, fils de Bunni;
Láti inú àwọn ọmọ Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ọmọ Bunni;
16 et Shabthaï et Jozabad, d’entre les chefs des lévites, [préposés] sur l’ouvrage extérieur de la maison de Dieu;
Ṣabbetai àti Josabadi, olórí méjì nínú àwọn ọmọ Lefi, àwọn tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ tí ó wà ní ẹ̀yìn àgbàlá ilé Ọlọ́run;
17 et Matthania, fils de Michée, fils de Zabdi, fils d’Asaph, le chef, qui entonnait la louange à la prière, et Bakbukia, le second d’entre ses frères, et Abda, fils de Shammua, fils de Galal, fils de Jeduthun.
Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, adarí tí ó ń ṣáájú ìdúpẹ́ àti àdúrà; Bakbukiah ẹnìkejì láàrín àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀; àti Abida ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.
18 Tous les lévites dans la ville sainte: 284.
Àwọn ọmọ Lefi nínú ìlú mímọ́ jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́rin.
19 Et les portiers, Akkub, Talmon, et leurs frères, qui étaient de garde aux portes, 172.
Àwọn aṣọ́nà: Akkubu, Talmoni, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n máa ń ṣọ́nà jẹ́ méjìléláàádọ́sàn-án ọkùnrin.
20 Et le reste d’Israël, les sacrificateurs, [et] les lévites, [habitèrent] dans toutes les villes de Juda, chacun dans son héritage.
Àwọn tókù nínú àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wà ní gbogbo ìlú u Juda, olúkúlùkù lórí ilẹ̀ ìní tirẹ̀.
21 Et les Nethiniens habitèrent Ophel; et Tsikha et Guishpa étaient [préposés] sur les Nethiniens.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili ń gbé lórí òkè Ofeli, Siha àti Giṣpa sì ni alábojútó wọn.
22 Et celui qui était préposé sur les lévites à Jérusalem était Uzzi, fils de Bani, fils de Hashabia, fils de Matthania, fils de Michée, des fils d’Asaph, les chantres pour l’œuvre de la maison de Dieu.
Olórí òṣìṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ní Jerusalẹmu ní Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah ọmọ Mika. Ussi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìran Asafu tí wọ́n jẹ́ akọrin ojúṣe nínú ìjọ́sìn ní ilé Ọlọ́run.
23 Car c’était le commandement du roi à leur égard, et il y avait un fixe pour les chantres, pour chaque jour ce qu’il fallait.
Àwọn akọrin wà ní abẹ́ àṣẹ ọba, èyí tí ó n díwọ̀n iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn.
24 Et Pethakhia, fils de Meshézabeël, des fils de Zérakh, fils de Juda, était auprès du roi pour toutes les affaires du peuple.
Petahiah ọmọ Meṣesabeli, ọ̀kan nínú àwọn Sera ọmọ Juda ní aṣojú ọba nínú ohun gbogbo tí ó jẹ mọ́ ti àwọn ènìyàn náà.
25 Et pour ce qui est des hameaux de leurs campagnes, [quelques-uns] des fils de Juda habitèrent à Kiriath-Arba et dans les villages de son ressort, et à Dibon et dans les villages de son ressort, et à Jekabtsëel et dans ses hameaux,
Fún ìletò pẹ̀lú oko wọn, díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn Juda tí ń gbé Kiriati-Arba, àti àwọn ìletò agbègbè e rẹ̀, ní Diboni àti ìletò rẹ̀, ní Jekabseeli.
26 et à Jéshua, et à Molada, et à Beth-Péleth,
Ní Jeṣua, ní Molada, ní Beti-Peleti
27 et à Hatsar-Shual, et à Beër-Shéba et dans les villages de son ressort,
ní Hasari-Ṣuali, ní Beerṣeba àti àwọn agbègbè rẹ̀.
28 et à Tsiklag, et à Mecona et dans les villages de son ressort,
Ní Siklagi, ní Mekona àti àwọn ìletò rẹ̀,
29 et à En-Rimmon, et à Tsorha, et à Jarmuth,
ní Ẹni-Rimoni, ní Sora, ní Jarmatu,
30 Zanoakh, Adullam et leurs hameaux, Lakis et ses campagnes, Azéka et les villages de son ressort; et ils demeurèrent depuis Beër-Shéba jusqu’à la vallée de Hinnom.
Sanoa, Adullamu àti àwọn ìletò o wọn, ní Lakiṣi àti àwọn oko rẹ̀, àti ní Aseka àti àwọn ìletò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé láti Beerṣeba títí dé àfonífojì Hinnomu.
31 Et les fils de Benjamin [s’établirent], depuis Guéba, [à] Micmash, et Aïa, et Béthel et les villages de son ressort,
Àwọn ọmọ Benjamini láti Geba ń gbé ní Mikmasi, Aija, Beteli àti àwọn ìletò rẹ̀.
32 Anathoth, Nob, Anania,
Ní Anatoti, Nobu àti Ananiah,
33 Hatsor, Rama, Guitthaïm,
ní Hasori Rama àti Gittaimu,
34 Hadid, Tseboïm, Neballath,
ní Hadidi, Seboimu àti Neballati,
35 Lod et Ono, la vallée des artisans.
ní Lodi àti Ono, àti ní àfonífojì àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà.
36 Et d’entre les Lévites, il y eut des divisions de Juda [qui s’établirent] en Benjamin.
Nínú ìpín àwọn ọmọ Lefi ni Juda tẹ̀dó sí Benjamini.

< Néhémie 11 >