< Josué 19 >
1 Et le deuxième lot échut à Siméon, pour la tribu des fils de Siméon, selon leurs familles; et leur héritage fut au milieu de l’héritage des fils de Juda.
Kèké kejì jáde fún ẹ̀yà Simeoni, ní agbo ilé, ní agbo ilé. Ìní wọn sì wà ní àárín ilẹ̀ Juda.
2 Et ils eurent dans leur héritage Beër-Shéba, et Shéba, et Molada,
Lára ìpín wọn ní: Beerṣeba (tàbí Ṣeba), Molada,
3 et Hatsar-Shual, et Bala, et Étsem,
Hasari-Ṣuali, Bala, Esemu,
4 et Eltholad, et Bethul, et Horma,
Eltoladi, Betuli, Horma,
5 et Tsiklag, et Beth-Marcaboth, et Hatsar-Susa,
Siklagi, Beti-Markaboti, Hasari Susa,
6 et Beth-Lebaoth, et Sharukhen: 13 villes et leurs hameaux;
Beti-Lebaoti àti Ṣarueli, ìlú wọn jẹ́ mẹ́tàlá àti ìletò wọn.
7 Aïn, Rimmon, et Éther, et Ashan: quatre villes et leurs hameaux;
Aini, Rimoni, Eteri àti Aṣani, ìlú wọn jẹ́ mẹ́rin àti ìletò wọn,
8 et tous les hameaux qui étaient autour de ces villes, jusqu’à Baalath-Beër, la Rama du midi. Tel fut l’héritage de la tribu des fils de Siméon, selon leurs familles.
àti gbogbo àwọn agbègbè ìlú wọ̀nyí títí dé Baalati-Beeri (Rama ní gúúsù). Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Simeoni, agbo ilé, ní agbo ilé.
9 L’héritage des fils de Siméon fut pris du lot des fils de Juda, car la part des fils de Juda était trop grande pour eux; et les fils de Siméon héritèrent au milieu de leur héritage.
A mú ogún ìní àwọn ọmọ Simeoni láti ìpín Juda, nítorí ìpín Juda pọ̀ ju èyí tí wọ́n nílò lọ. Báyìí ni àwọn ọmọ Simeoni gba ìní wọn ní àárín ilẹ̀ Juda.
10 Et le troisième sort tomba pour les fils de Zabulon, selon leurs familles; et la frontière de leur héritage fut jusqu’à Sarid;
Kèké kẹta jáde fún Sebuluni, ní agbo ilé ní agbo ilé ààlà ìní wọn sì lọ títí dé Saridi.
11 et leur frontière montait vers l’occident, et à Marhala, et touchait à Dabbésheth, et touchait au torrent qui est devant Jokneam;
Ó sì lọ sí ìwọ̀-oòrùn ní Marala, ó sì dé Dabbeṣeti, ó sì lọ títí dé odo ní ẹ̀bá Jokneamu.
12 et elle tournait de Sarid vers l’orient au soleil levant, sur la frontière de Kisloth-Thabor, et sortait vers Dabrath, et montait à Japhia,
Ó sì yípadà sí ìlà-oòrùn láti Saridi sí ìhà ìlà-oòrùn dé ilẹ̀ Kisiloti-Tabori, ó sì lọ sí Daberati, ó sì gòkè lọ sí Jafia.
13 et de là passait vers l’orient, au levant, à Gath-Hépher, à Eth-Katsin, et sortait à Rimmon, qui s’étend jusqu’à Néa.
Nígbà náà ní o lọ sí ìhà ìlà-oòrùn lọ sí Gati-Heferi àti Eti-Kaṣini, ó sì jáde ní Rimoni, ó sì yí sí ìhà Nea.
14 Et la frontière en faisait le tour, au nord, vers Hannathon, et aboutissait à la vallée de Jiphtah-El;
Ní ibẹ̀, ààlà sì yíká ní ìhà àríwá lọ sí Hnatoni ó sì pín ní àfonífojì Ifita-Eli.
15 … et Kattath, et Nahalal, et Shimron, et Jideala, et Bethléhem: douze villes et leurs hameaux.
Lára wọn ni Katati, Nahalali, Ṣimroni, Idala àti Bẹtilẹhẹmu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
16 Tel fut l’héritage des fils de Zabulon, selon leurs familles: ces villes-là et leurs hameaux.
Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní Sebuluni, ní agbo ilé agbo ilé.
17 Le quatrième sort échut à Issacar, pour les fils d’Issacar, selon leurs familles.
Kèké kẹrin jáde fún Isakari, agbo ilé ní agbo ilé.
18 Et leur territoire fut vers Jizreël, et Kesulloth, et Sunem,
Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Jesreeli, Kesuloti, Ṣunemu,
19 et Hapharaïm, et Shion, et Anakharath,
Hafraimu, Ṣihoni, Anaharati,
20 et Rabbith, et Kishion, et Ébets,
Rabiti, Kiṣioni, Ebesi,
21 et Rémeth, et En-Gannim, et En-Hadda, et Beth-Patsets;
Remeti, Eni-Gannimu, Eni-Hada àti Beti-Pasesi.
22 et la frontière touchait à Thabor, et à Shakhatsim, et à Beth-Shémesh; et leur frontière aboutissait au Jourdain: 16 villes et leurs hameaux.
Ààlà náà sì dé Tabori, Ṣahasuma, àti Beti-Ṣemeṣi, ó sì pin ní Jordani. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
23 Tel fut l’héritage de la tribu des fils d’Issacar, selon leurs familles: ces villes et leurs hameaux.
Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní ẹ̀yà Isakari, ní agbo ilé agbo ilé.
24 Et le cinquième sort échut à la tribu des fils d’Aser, selon leurs familles.
Kèké karùn-ún jáde fún ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
25 Et leur territoire fut Helkath, et Hali, et Béten, et Acshaph,
Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Helikati, Hali, Beteni, Akṣafu,
26 et Allammélec, et Amhad, et Misheal; et [la frontière] touchait au Carmel, à l’occident, et au Shikhor-Libnath;
Allameleki, Amadi, àti Miṣali. Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ààlà náà dé Karmeli àti Ṣihori-Libinati.
27 et elle tournait vers le soleil levant, contre Beth-Dagon, et touchait à Zabulon et à la vallée de Jiphtah-El, au nord de Beth-Émek et de Neïel, et sortait vers Cabul au nord;
Nígbà náà ni o yí sí ìhà ìlà-oòrùn Beti-Dagoni, dé Sebuluni àti àfonífojì Ifita-Eli, ó sì lọ sí àríwá sí Beti-Emeki àti Neieli, ó sì kọjá lọ sí Kabulu ní apá òsì.
28 et vers Ébron, et Rehob, et Hammon, et Kana, jusqu’à Sidon la grande;
Ó sì lọ sí Abdoni, Rehobu, Hammoni àti Kana títí dé Sidoni ńlá.
29 et la frontière tournait vers Rama et jusqu’à la ville forte de Tyr; et la frontière tournait vers Hosa, et aboutissait à la mer, près de la contrée d’Aczib;
Ààlà náà sì tẹ̀ sí ìhà Rama, ó sì lọ sí ìlú olódi Tire, ó sì yà sí Hosa, ó sì jáde ní Òkun Ńlá ní ilẹ̀ Aksibu,
30 … et Umma, et Aphek, et Rehob: 22 villes et leurs hameaux.
Uma, Afeki àti Rehobu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlélógún àti ìletò wọn.
31 Tel fut l’héritage de la tribu des fils d’Aser, selon leurs familles: ces villes-là et leurs hameaux.
Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
32 Le sixième sort échut aux fils de Nephthali, pour les fils de Nephthali, selon leurs familles.
Ìpín kẹfà jáde fún Naftali, agbo ilé ní agbo ilé,
33 Et leur frontière fut depuis Héleph, depuis le chêne de Tsaanannim, et Adami-Nékeb, et Jabneël, jusqu’à Lakkum, et elle aboutissait au Jourdain;
ààlà wọn lọ láti Helefi àti igi ńlá ní Saananimu nímù; kọjá lọ sí Adami Nekebu àti Jabneeli dé Lakkumu, ó sì pín ní Jordani.
34 et la frontière tournait vers l’occident, contre Aznoth-Thabor, et sortait de là vers Hukkok, et touchait au midi à Zabulon; et à l’occident elle touchait à Aser, et à Juda sur le Jourdain au soleil levant.
Ààlà náà gba ìhà ìwọ̀-oòrùn lọ sí Asnoti-Tabori ó sì jáde ní Hukoki. Ó sì dé Sebuluni, ní ìhà gúúsù Aṣeri ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Juda ní Jordani ní ìhà ìlà-oòrùn.
35 Et les villes fortes étaient: Tsiddim, Tser, et Hammath, Rakkath, et Kinnéreth,
Àwọn ìlú olódi sì Siddimu, Seri, Hamati, Rakàti, Kinnereti,
36 et Adama, et Rama, et Hatsor,
Adama, Rama Hasori,
37 et Kédesh, et Édréhi, et En-Hatsor,
Kedeṣi, Edrei, Eni-Aṣọri,
38 et Jireon, et Migdal-El, Horem, et Beth-Anath, et Beth-Shémesh: 19 villes et leurs hameaux.
Ironi, Migdali-Eli, Horemu, Beti-Anati àti Beti-Ṣemeṣi. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mọ́kàndínlógún àti ìletò wọn.
39 Tel fut l’héritage de la tribu des fils de Nephthali, selon leurs familles: ces villes et leurs hameaux.
Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Naftali, ní agbo ilé sí agbo ilé.
40 Le septième sort échut à la tribu des fils de Dan, selon leurs familles.
Ìbò kéje jáde fún ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé ní agbo ilé.
41 Et le territoire de leur héritage fut: Tsorha, et Eshtaol, et Ir-Shémesh,
Ilẹ̀ ìní wọn nìwọ̀nyí: Sora, Eṣtaoli, Iri-Ṣemesi,
42 et Shaalabbin, et Ajalon, et Jithla,
Ṣaalabini, Aijaloni, Itila,
43 et Élon, et Thimnatha, et Ékron,
Eloni, Timna, Ekroni,
44 et Eltheké, et Guibbethon, et Baalath,
Elteke, Gibetoni, Baalati,
45 et Jehud, et Bené-Berak, et Gath-Rimmon,
Jehudu, Bene-Beraki, Gati-Rimoni,
46 et Mé-Jarkon, et Rakkon, avec la frontière vis-à-vis de Japho.
Me Jakoni àti Rakkoni, pẹ̀lú ilẹ̀ tí ó kọjú sí Joppa.
47 Et la frontière des fils de Dan se terminait par elles. Et les fils de Dan montèrent et combattirent contre Léshem, et la prirent, et la frappèrent par le tranchant de l’épée, et en prirent possession et y habitèrent; et ils appelèrent Léshem, Dan, du nom de Dan, leur père.
(Ṣùgbọ́n àwọn ará Dani ní ìṣòro láti gba ilẹ̀ ìní wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ, wọ́n sì kọlu Leṣemu, wọ́n sì gbà á, wọ́n sì fi idà kọlù ú, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀. Wọ́n sì ń gbé ní Leṣemu, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dani orúkọ baba ńlá wọn).
48 Tel fut l’héritage de la tribu des fils de Dan, selon leurs familles: ces villes-là et leurs hameaux.
Àwọn ìlú wọ́n yí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé agbo ilé.
49 Et quand on eut achevé de partager le pays selon ses frontières, les fils d’Israël donnèrent un héritage au milieu d’eux à Josué, fils de Nun.
Nígbà tí wọ́n ti parí pínpín ilẹ̀ náà ní ìpín ti olúkúlùkù, àwọn ará Israẹli fún Joṣua ọmọ Nuni ní ìní ní àárín wọn,
50 Selon le commandement de l’Éternel, ils lui donnèrent la ville qu’il demanda: Thimnath-Sérakh, dans la montagne d’Éphraïm; et il bâtit la ville, et y habita.
bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n fún un ni ìlú tí ó béèrè fún, Timnati Serah ní ìlú òkè Efraimu. Ó sì kọ́ ìlú náà, ó sì ń gbé ibẹ̀.
51 Ce sont là les héritages qu’Éléazar, le sacrificateur, et Josué, fils de Nun, et les chefs des pères des tribus des fils d’Israël, distribuèrent par le sort, à Silo, devant l’Éternel, à l’entrée de la tente d’assignation; et ils achevèrent le partage du pays.
Wọ̀nyí ni àwọn ilẹ̀ tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti àwọn olórí ẹ̀yà agbo ilé Israẹli fi ìbò pín ní Ṣilo ní iwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Báyìí ni wọ́n parí pínpín ilẹ̀ náà.