< Job 40 >

1 Et l’Éternel répondit à Job et dit:
Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
2 Celui qui conteste avec le Tout-puissant l’instruira-t-il? Celui qui reprend Dieu, qu’il réponde à cela!
“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
3 Et Job répondit à l’Éternel et dit:
Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
4 Voici, je suis une créature de rien, que te répliquerai-je? Je mettrai ma main sur ma bouche.
“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
5 J’ai parlé une fois, et je ne répondrai plus; et deux fois, et je n’ajouterai rien.
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
6 Et l’Éternel répondit à Job du milieu du tourbillon et dit:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
7 Ceins tes reins comme un homme; je t’interrogerai, et tu m’instruiras!
“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
8 Veux-tu donc anéantir mon jugement? Me démontreras-tu inique afin de te justifier?
“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
9 As-tu un bras comme Dieu, et tonneras-tu de ta voix comme lui?
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
10 Pare-toi, je te prie, de grandeur et de magnificence; revêts-toi de majesté et de gloire!
Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
11 Répands les fureurs de ta colère, et regarde tout ce qui s’élève et abaisse-le;
Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
12 Regarde tout ce qui s’élève [et] humilie-le, et écrase sur place les méchants;
Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Cache-les ensemble dans la poussière, lie leurs faces dans un lieu caché:
Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
14 Alors moi aussi je te célébrerai, parce que ta droite te sauve!
Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
15 Vois le béhémoth, que j’ai fait avec toi: il mange l’herbe comme le bœuf.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16 Regarde donc: sa force est dans ses reins, et sa puissance dans les muscles de son ventre.
Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17 Il courbe sa queue comme un cèdre; les nerfs de sa cuisse sont entrelacés;
Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
18 Ses os sont des tubes d’airain, ses membres sont des barres de fer!
Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19 Il est la première des voies de Dieu: celui qui l’a fait lui a fourni son épée.
Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Car les montagnes lui apportent [sa] pâture, là où se jouent toutes les bêtes des champs.
Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
21 Il se couche sous les lotus dans une retraite de roseaux et de marécages;
Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
22 Les lotus le couvrent de leur ombre, les saules de la rivière l’environnent.
Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
23 Voici, que le fleuve déborde avec violence, il ne se précipite pas; il est plein d’assurance si un Jourdain se jette contre sa gueule.
Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
24 Le prendra-t-on en face? Lui percera-t-on le nez dans une trappe?
Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

< Job 40 >