< Esdras 2 >
1 Et voici ceux de la province qui remontèrent de la captivité de ceux qui avaient été transportés, lesquels Nebucadnetsar, roi de Babylone, avait transportés à Babylone, et qui retournèrent à Jérusalem et en Juda, chacun à sa ville,
Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
2 lesquels vinrent avec Zorobabel, Jéshua, Néhémie, Seraïa, Reélaïa, Mardochée, Bilshan, Mispar, Bigvaï, Rehum, [et] Baana. Nombre des hommes du peuple d’Israël:
Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
3 Les fils de Parhosh, 2 172;
Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
4 les fils de Shephatia, 372;
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
6 les fils de Pakhath-Moab, des fils de Jéshua [et de] Joab, 2 812;
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
7 les fils d’Élam, 1 254;
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
8 les fils de Zatthu, 945;
Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
9 les fils de Zaccaï, 760;
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
10 les fils de Bani, 642;
Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
11 les fils de Bébaï, 623;
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
12 les fils d’Azgad, 1 222;
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
13 les fils d’Adonikam, 666;
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
14 les fils de Bigvaï, 2 056;
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
16 les fils d’Ater, [de la famille] d’Ézéchias, 98;
Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
17 les fils de Bétsaï, 323;
Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
18 les fils de Jora, 112;
Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
19 les fils de Hashum, 223;
Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
20 les fils de Guibbar, 95;
Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
21 les fils de Bethléhem, 123;
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
22 les hommes de Netopha, 56;
Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
23 les hommes d’Anathoth, 128;
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
24 les fils d’Azmaveth, 42;
Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
25 les fils de Kiriath-Arim, de Kephira et de Beéroth, 743;
Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
26 les fils de Rama et de Guéba, 621;
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
27 les hommes de Micmas, 122;
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
28 les hommes de Béthel et d’Aï, 223;
Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
30 les fils de Magbish, 156;
Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
31 les fils de l’autre Élam, 1 254;
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
32 les fils de Harim, 320;
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
33 les fils de Lod, de Hadid et d’Ono, 725;
Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
34 les fils de Jéricho, 345;
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
35 les fils de Senaa, 3 630.
Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
36 Sacrificateurs: les fils de Jedahia, de la maison de Jéshua, 973;
Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
37 les fils d’Immer, 1 052;
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
38 les fils de Pashkhur, 1 247;
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
39 les fils de Harim, 1 017.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
40 Lévites: les fils de Jéshua et de Kadmiel, d’entre les fils d’Hodavia, 74.
Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
41 Chantres: les fils d’Asaph, 128.
Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
42 Fils des portiers: les fils de Shallum, les fils d’Ater, les fils de Talmon, les fils d’Akkub, les fils de Hatita, les fils de Shobaï, en tout 139.
Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
43 Nethiniens: les fils de Tsikha, les fils de Hasupha, les fils de Tabbaoth,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
44 les fils de Kéros, les fils de Siaha, les fils de Padon,
Kerosi, Siaha, Padoni,
45 les fils de Lebana, les fils de Hagaba, les fils d’Akkub,
Lebana, Hagaba, Akkubu,
46 les fils de Hagab, les fils de Shamlaï, les fils de Hanan,
Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
47 les fils de Guiddel, les fils de Gakhar, les fils de Reaïa,
Giddeli, Gahari, Reaiah,
48 les fils de Retsin, les fils de Nekoda, les fils de Gazzam,
Resini, Nekoda, Gassamu,
49 les fils d’Uzza, les fils de Paséakh, les fils de Bésaï,
Ussa, Pasea, Besai,
50 les fils d’Asna, les fils de Meünim, les fils de Nephusim,
Asna, Mehuni, Nefisimu,
51 les fils de Bakbuk, les fils de Hakupha, les fils de Harkhur,
Bakbu, Hakufa, Harhuri.
52 les fils de Batsluth, les fils de Mekhida, les fils de Harsha,
Basluti, Mehida, Harṣa,
53 les fils de Barkos, les fils de Sisera, les fils de Thamakh,
Barkosi, Sisera, Tema,
54 les fils de Netsiakh, les fils de Hatipha.
Nesia àti Hatifa.
55 Fils des serviteurs de Salomon: les fils de Sotaï, les fils de Sophéreth, les fils de Peruda,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
56 les fils de Jaala, les fils de Darkon, les fils de Guiddel,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
57 les fils de Shephatia, les fils de Hattil, les fils de Pokéreth-Hatsebaïm, les fils d’Ami.
Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
58 Tous les Nethiniens et les fils des serviteurs de Salomon, 392.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
59 Et voici ceux qui montèrent de Thel-Mélakh, de Thel-Harsha, de Kerub-Addan, d’Immer; mais ils ne purent pas montrer leurs maisons de pères et leur descendance, s’ils étaient d’Israël:
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
60 les fils de Delaïa, les fils de Tobija, les fils de Nekoda, 652;
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
61 et des fils des sacrificateurs, les fils de Hobaïa, les fils d’Hakkots, les fils de Barzillaï, qui prit une femme d’entre les filles de Barzillaï, le Galaadite, et fut appelé de leur nom.
Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
62 Ceux-ci cherchèrent leur inscription généalogique, mais elle ne se trouva pas; et ils furent exclus, comme profanes, de la sacrificature.
Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
63 Et le Thirshatha leur dit qu’ils ne devaient point manger des choses très saintes, jusqu’à ce que soit suscité un sacrificateur avec les urim et les thummim.
Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
64 Toute la congrégation réunie était de 42 360 [personnes],
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
65 sans compter leurs serviteurs et leurs servantes; ceux-ci [étaient au nombre de] 7 337; et parmi eux, il y avait 200 chanteurs et chanteuses.
Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
66 Ils avaient 736 chevaux, 245 mulets,
Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
67 435 chameaux, [et] 6 720 ânes.
ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
68 Et des chefs des pères, quand ils arrivèrent à la maison de l’Éternel qui est à Jérusalem, donnèrent volontairement pour la maison de Dieu, pour la relever sur son emplacement;
Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
69 ils donnèrent au trésor de l’œuvre, selon leur pouvoir, 61 000 dariques d’or, et 5 000 mines d’argent, et 100 tuniques de sacrificateurs.
Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
70 Et les sacrificateurs, et les lévites, et ceux du peuple, et les chantres, et les portiers, et les Nethiniens, habitèrent dans leurs villes: tout Israël se trouva dans ses villes.
Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.