< Zacharie 10 >

1 Demandez à Yahweh de la pluie au printemps. C'est Yahweh qui fait les éclairs; il leur donnera une pluie abondante, à chacun de l'herbe dans son champ.
Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa; Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná, tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn, fún olúkúlùkù koríko ní pápá.
2 Car les théraphim ont parlé futilité, et les devins ont eu des visions de mensonge; ils débitent de vains songes, et donnent de fausses consolations. C'est pourquoi ils sont partis comme un troupeau; ils ont été opprimés, faute de berger.
Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán, àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké, wọn sì tí rọ àlá èké; wọ́n ń tu ni nínú lásán, nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn, a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.
3 Ma colère s'est enflammée contre les bergers, et je châtierai les boucs! Car Yahweh des armées visite son troupeau, la maison de Juda, et il en fait son cheval d'honneur dans la bataille.
“Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran, èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀, ilé Juda wò, yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.
4 De lui viendra la troupe, de lui le pieu, de lui l'arc de guerre; de lui sortiront tous les chefs ensemble.
Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.
5 Ils seront comme des héros, foulant la boue des chemins dans la bataille; ils combattront, car Yahweh sera avec eux, et ils couvriront de honte ceux qui sont montés sur des chevaux.
Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun, nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn, wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.
6 Je fortifierai la maison de Juda, et je sauverai la maison de Joseph; je les rétablirai, car j'ai compassion d'eux, et ils seront comme si je ne les avais pas rejetés. Car moi, je suis Yahweh, leur Dieu, et je les exaucerai.
“Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára, èmi o sì gba ilé Josẹfu là, èmi ó sì tún mú wọn padà nítorí mo tí ṣàánú fún wọn, ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù; nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi o sì gbọ́ tiwọn
7 Ceux d'Ephraïm seront comme des héros, et leur cœur sera joyeux comme par le vin; leurs fils le verront et se réjouiront, et leur cœur tressaillira en Yahweh.
Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára, ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì: àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í, wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.
8 Je sifflerai après eux, et je les rassemblerai, car je les ai rachetés, et ils se multiplieront comme ils s'étaient multipliés.
Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ; nítorí èmi tí rà wọ́n padà; wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.
9 Quand je les aurai répandus parmi les peuples, et qu'ils se souviendront de moi dans les pays lointains, ils vivront avec leurs enfants et ils reviendront.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè: síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn; wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọn ó sì tún padà.
10 Je les ramènerai du pays d'Egypte, et je les rassemblerai d'Assyrie, et je les ferai venir au pays de Galaad et au Liban, et il ne se trouvera pas assez d'espace pour eux.
Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria. Èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.
11 Il passera par la mer, mer de détresse, il frappera les flots dans la mer, et toutes les profondeurs du fleuve seront mises à sec. L'orgueil de l'Assyrie sera abattu, et le sceptre de l'Egypte sera ôté.
Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já, yóò sì bori rírú omi nínú Òkun, gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ, a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀, ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.
12 Je les fortifierai en Yahweh, et ils marcheront en son nom, — oracle de Yahweh.
Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa; wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,” ni Olúwa wí.

< Zacharie 10 >