< Psaumes 66 >

1 Au maître de chant. Cantique. Psaume. Pousse vers Dieu des cris de joie, terre entière!
Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
2 Chantez la gloire de son nom, célébrez magnifiquement ses louanges!
Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
3 Dites à Dieu: " Que tes œuvres sont redoutables! A cause de ta toute-puissance, tes ennemis te flattent.
Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
4 Que toute la terre se prosterne devant toi, qu'elle chante en ton honneur, qu'elle chante ton nom! " — Séla.
Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
5 Venez et contemplez les œuvres de Dieu! Il est redoutable dans ses desseins sur les fils de l'homme.
Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
6 Il a changé la mer en une terre sèche, on a passé le fleuve à pied; alors nous nous réjouîmes en lui.
Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
7 Il règne éternellement par sa puissance; ses yeux observent les nations: que les rebelles ne s'élèvent point! — Séla.
Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
8 Peuples, bénissez notre Dieu, faites retentir sa louange!
Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
9 Il a conservé la vie à notre âme, et n'a pas permis que notre pied chancelât.
Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
10 Car tu nous as éprouvés, ô Dieu, tu nous as fait passer au creuset, comme l'argent.
Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
11 Tu nous as conduits dans le filet, tu as mis sur nos reins un fardeau.
Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
12 Tu as fait marcher des hommes sur nos têtes; nous avons passé par le feu et par l'eau; mais tu nous en as tirés pour nous combler de biens.
Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
13 Je viens dans ta maison avec des holocaustes, pour m'acquitter envers toi de mes vœux,
Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
14 que mes lèvres ont proférés, que ma bouche a prononcés au jour de ma détresse.
ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
15 Je t'offre des brebis grasses en holocauste, avec la fumée des béliers; j'immole le taureau avec le jeune bouc. — Séla.
Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
16 Venez, écoutez, et je vous raconterai, à vous tous qui craignez Dieu, ce qu'il a fait à mon âme.
Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
17 J'ai crié vers lui de ma bouche, et sa louange était sur ma langue.
Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
18 Si j'avais vu l'iniquité dans mon cœur, le Seigneur ne m'exaucerait pas.
Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
19 Mais Dieu m'a exaucé, il a été attentif à la voix de ma prière.
ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
20 Béni soit Dieu, qui n'a pas repoussé ma prière, et n'a pas éloigné de moi sa grâce!
Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!

< Psaumes 66 >