< Psaumes 101 >
1 Psaume de David. Je veux chanter la bonté et la justice; C’est toi, Yahweh, que je veux célébrer.
Ti Dafidi. Saamu. Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo; sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
2 Je prendrai garde à la voie de l’innocence. — Quand viendras-tu à moi? — Je marcherai dans l’intégrité de mon cœur, au milieu de ma maison.
Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀, ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi? Èmi yóò máa rìn ní ilé mi pẹ̀lú àyà pípé.
3 Je ne mettrai devant mes yeux aucune action mauvaise. Je hais la conduite perverse; elle ne s’attachera point à moi.
Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi: iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra. Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
4 Un cœur faux ne sera jamais le mien; je ne veux pas connaître le mal.
Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi; èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
5 Le détracteur qui déchire en secret son prochain, je l’exterminerai; L’homme au regard hautain et au cœur gonflé d’orgueil, je ne le supporterai pas.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀, òun ní èmi yóò gé kúrò ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà, òun ní èmi kì yóò faradà fún.
6 J’aurai les yeux sur les hommes fidèles du pays, pour qu’ils demeurent auprès de moi; celui qui marche dans une voie intègre sera mon serviteur.
Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀, kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé òun ni yóò máa sìn mí.
7 Il n’aura point de place dans ma maison, celui qui agit avec fourberie; celui qui profère le mensonge ne subsistera pas devant mes yeux.
Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi, kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
8 Chaque matin j’exterminerai tous les méchants du pays, afin de retrancher de la cité de Yahweh tous ceux qui commettent l’iniquité.
Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà; èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú kúrò ní ìlú Olúwa.