< Proverbes 30 >

1 Paroles d'Agur, fils de Jaké; sentence. Cet homme a dit: Je me suis fatigué pour connaître Dieu, pour connaître Dieu, et je suis à bout de forces.
Àwọn ọ̀rọ̀ Aguri ọmọ Jake, ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí ọkùnrin yìí sọ fún Itieli. Sí Itieli àti sí Ukali.
2 Car je suis plus stupide que personne, et je n'ai pas l'intelligence d'un homme.
“Èmi ni aláìmòye ju nínú àwọn ènìyàn; n kò ní òye ènìyàn.
3 Je n'ai pas appris la sagesse, et je ne connais pas la science du Saint.
Èmi kò tilẹ̀ kọ́ ọgbọ́n tàbí ní ìmọ̀ ẹni mímọ́ nì.
4 Qui monte au ciel et qui en descend? Qui a recueilli le vent dans ses mains? Qui a lié les eaux dans son vêtement? Qui a affermi toutes les extrémités de la terre? Quel est son nom et quel est le nom de son fils? Le sais-tu?
Ta ni ó ti gòkè lọ sí ọ̀run tí ó sì padà sọ̀kalẹ̀? Ta ni ó ti kó afẹ́fẹ́ jọ sí ihò àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀? Ta ni ó ti ta kókó omi sétí aṣọ? Ta ni ó fi gbogbo ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀? Kí ni orúkọ rẹ̀, àti orúkọ ọmọ rẹ̀? Sọ fún mi bí o bá mọ̀.
5 Toute parole de Dieu est éprouvée par le feu; il est un bouclier pour ceux qui se réfugient auprès de lui.
“Gbogbo ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ aláìlábùkù; òun ni ààbò fún gbogbo ẹni fi í ṣe ibi ìpamọ́ wọn.
6 N'ajoute rien à ses paroles, de peur qu'il ne te reprenne et que tu ne sois trouvé menteur.
Má ṣe fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀, àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò bá ọ wí yóò sì sọ ọ́ di òpùrọ́.
7 Je te demande deux choses, ne me les refuse pas avant que je meure:
“Ohun méjì ni mo ń béèrè lọ́wọ́ rẹ, Olúwa; má ṣe fi wọ́n dù mí kí ń tó kú.
8 Eloigne de moi la fausseté et la parole mensongère; ne me donne ni pauvreté, ni richesse, accorde-moi le pain qui m'est nécessaire:
Mú èké ṣíṣe àti irọ́ jìnnà sí mi; má ṣe fún mi ní òsì tàbí ọrọ̀, ṣùgbọ́n fún mi ní oúnjẹ òòjọ́ mi nìkan.
9 de peur que, rassasié, je ne te renie et ne dise: « Qui est Yahweh? »; et que, devenu pauvre, je ne dérobe, et n'outrage le nom de mon Dieu.
Àìṣe bẹ́ẹ̀, mo lè ní àníjù kí n sì gbàgbé rẹ kí ń sì wí pé, ‘Ta ni Olúwa?’ Tàbí kí ń di òtòṣì kí ń sì jalè kí ń sì ṣe àìbọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run mi.
10 Ne calomnie pas un serviteur auprès de son maître, de peur qu'il ne te maudisse et que tu n'en portes la peine.
“Má ṣe ba ìránṣẹ́ lórúkọ jẹ́ lọ́dọ̀ ọ̀gá rẹ̀, kí ó má ba fi ọ́ bú, kí ìwọ má ba jẹ̀bi.
11 Il est une race qui maudit son père, et qui ne bénit pas sa mère.
“Àwọn kan wá ṣépè fún àwọn baba wọn tí wọn kò sì súre fún àwọn ìyá wọn.
12 Il est une race qui est pure à ses propres yeux, et qui n'est pas lavée de sa souillure.
Àwọn tí ó mọ́ ní ojú ara wọn síbẹ̀ tí wọn kò sì mọ́ kúrò nínú èérí wọn;
13 Il est une race — combien ses regards sont altiers, et ses paupières élevées!
àwọn ẹni tí ojú wọn gbéga nígbà gbogbo, tí ìwolẹ̀ wọn sì kún fún ìgbéraga.
14 Il est une race dont les dents sont des glaives, et les molaires des couteaux, pour dévorer les malheureux de dessus la terre, et les indigents parmi les hommes.
Àwọn ẹni tí eyín wọn jẹ́ idà àwọn tí èrìgì wọn kún fún ọ̀bẹ láti jẹ àwọn tálákà run kúrò ní ilẹ̀ ayé àwọn aláìní kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
15 La sangsue a deux filles: Donne! donne! Trois choses sont insatiables, quatre ne disent jamais: Assez:
“Eṣúṣú ni ọmọbìnrin méjì. ‘Mú wá! Mú wá!’ ní wọn ń ké. “Àwọn nǹkan mẹ́ta kan wà tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn láéláé, mẹ́rin tí kò jẹ́ wí láéláé pé, ‘Ó tó!’:
16 le schéol, le sein stérile, la terre qui n'est pas rassasiée d'eau et le feu qui ne dit jamais: Assez! (Sheol h7585)
Ibojì, inú tí ó yàgàn, ilẹ̀ tí omi kì í tẹ́lọ́rùn láéláé, àti iná, tí kì í wí láéláé pé, ‘Ó tó!’ (Sheol h7585)
17 L'œil qui se moque d'un père, et qui dédaigne l'obéissance envers une mère, les corbeaux du torrent le perceront, et les petits de l'aigle le dévoreront.
“Ojú tí ń fi baba ṣẹ̀fẹ̀, tí ó kẹ́gàn ìgbọ́ràn sí ìyá, ẹyẹ ìwò ẹ̀bá odò ni yóò yọ ọ́, igún yóò mú un jẹ.
18 Il y a trois choses qui me dépassent, et même quatre que je ne comprends pas:
“Àwọn nǹkan mẹ́ta wà tí ó jẹ́ ìyàlẹ́nu fún mi, mẹ́rin tí kò yé mi,
19 la trace de l'aigle dans les cieux, la trace du serpent sur le rocher, la trace du navire au milieu de la mer, et la trace de l'homme chez la jeune fille.
ipa ẹyẹ idì ní òfúrufú ipa ejò lórí àpáta ipa ọkọ̀ ojú omi lójú agbami Òkun àti ipa ọ̀nà ọkùnrin tí ó mú wúńdíá lọ́wọ́.
20 Telle est la voie de la femme adultère: elle mange et, s'essuyant la bouche, elle dit: « Je n'ai pas fait de mal. »
“Èyí ni ọ̀nà alágbèrè obìnrin ó jẹun ó sì nu ẹnu rẹ̀ ó sì wí pé, ‘N kò ṣe ohunkóhun tí kò tọ́.’
21 Sous trois choses la terre tremble, et sous quatre, qu'elle ne peut supporter:
“Lábẹ́ nǹkan mẹ́ta ni ilé ayé ti ń wárìrì lábẹ́ ohun mẹ́rin ni kò ti lè mí fín ín.
22 sous un esclave lorsqu'il vient à régner, et un insensé lorsqu'il est rassasié de pain,
Ìránṣẹ́ tí ó di ọba aláìgbọ́n tí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,
23 sous une femme dédaignée lorsqu'elle se marie, et sous une servante lorsqu'elle hérite de sa maîtresse.
obìnrin tí gbogbo ènìyàn kórìíra tí ó sì wá lọ́kọ ìránṣẹ́bìnrin tí ó gbọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
24 Il y a sur la terre quatre animaux bien petits, et qui sont cependant très sages:
“Àwọn ohun mẹ́rin ló kéré láyé síbẹ̀ wọ́n gbọ́n gidigidi.
25 Les fourmis, peuple sans force, préparent en été leur nourriture;
Àwọn èèrà jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá, síbẹ̀ wọ́n kó oúnjẹ wọn pamọ́ ní àsìkò òjò.
26 les damans, peuple sans puissance, placent leur gîte dans les rochers;
Ehoro jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá; síbẹ̀ wọ́n ń ṣe ihò wọn sí ibi pálapàla àpáta;
27 les sauterelles n'ont pas de roi, et elles sortent toutes par bandes;
àwọn eṣú kò ní ọba, síbẹ̀ gbogbo wọ́n ń jáde lọ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́
28 tu peux prendre le lézard avec la main, et il se trouve dans le palais des rois.
Ọmọnílé fi ọwọ́ rẹ̀ dì mú, síbẹ̀ a ń rí i ní ààfin ọba.
29 Il y en a trois qui ont une belle allure, et quatre qui ont une belle démarche:
“Àwọn ohun mẹ́ta ní ń bẹ tí ń rìn rere, ohun mẹ́rin ni ó dára púpọ̀ ní ìrìn rírìn:
30 le lion, le plus brave des animaux, ne reculant devant aucun adversaire;
Kìnnìún, alágbára láàrín ẹranko tí kì í sá fún ohunkóhun
31 l'animal aux reins agiles, ou le bouc, et le roi, à qui personne ne résiste.
Ẹsin tí a dì lẹ́gbẹ̀ẹ́; àti òbúkọ, àti ọba láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
32 Si tu es assez fou pour te laisser emporter par l'orgueil, et si tu en as la pensée, mets la main sur ta bouche,
“Bí ìwọ bá ti hùwà aṣiwèrè nípa gbígbé ara rẹ ga, tàbí tí o bá ti gbèrò ibi, da ọwọ́ rẹ bo ẹnu rẹ!
33 car la pression du lait produit du beurre, la pression du nez produit du sang, et la pression de la colère produit la querelle. PAROLES DU ROI LAMUEL.
Nítorí bí fífún omi ọmú tí í mú wàrà wá, tí fífún imú sì ń mú ẹ̀jẹ̀ jáde, bẹ́ẹ̀ ni rírú ìbínú sókè í mú ìjà wá.”

< Proverbes 30 >