< Lévitique 10 >

1 Les fils d’Aaron, Nadab et Abiu, prirent chacun leur encensoir, y mirent du feu et, ayant posé du parfum dessus, ils apportèrent devant Yahweh un feu étranger, ce qu’il ne leur avait point commandé.
Nadabu àti Abihu tí í ṣe ọmọ Aaroni sì mú àwo tùràrí kọ̀ọ̀kan, wọ́n fi iná àti tùràrí sínú rẹ̀, wọ́n sì rú iná àjèjì níwájú Olúwa, èyí tó lòdì sí àṣẹ Olúwa.
2 Alors un feu sortit de devant Yahweh et les dévora: ils moururent devant Yahweh.
Torí èyí, iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì jó wọn pa, wọ́n sì kú níwájú Olúwa.
3 Et Moïse dit à Aaron: « C’est ce que Yahweh a déclaré, lorsqu’il a dit: Je serai sanctifié en ceux qui m’approchent, et je serai glorifié en présence de tout le peuple. » Aaron se tut.
Mose sì sọ fún Aaroni pé, “Ohun tí Olúwa ń sọ nípa rẹ̀ nìyìí nígbà tó wí pé, “‘Ní àárín àwọn tó súnmọ́ mi, Èmi yóò fi ara mi hàn ní mímọ́ ojú gbogbo ènìyàn Ní a ó ti bu ọlá fún mi.’” Aaroni sì dákẹ́.
4 Et Moïse appela Misaël et Elisaphon, fils d’Oziel, oncle d’Aaron, et il leur dit: « Approchez-vous, emportez vos frères loin du sanctuaire, hors du camp. »
Mose pe Miṣaeli àti Elsafani ọmọ Usieli tí í ṣe arákùnrin Aaroni, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ wá, kí ẹ sì gbé àwọn arákùnrin yín jáde kúrò níwájú ibi mímọ́ lọ sí ẹ̀yìn ibùdó.”
5 Ils s’approchèrent et les emportèrent revêtus de leurs tuniques hors du camp, comme Moïse l’avait ordonné.
Wọ́n sì wá gbé wọn, pẹ̀lú ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọn ní ọrùn wọn lọ sí ẹ̀yìn ibùdó bí Mose ti sọ.
6 Moïse dit à Aaron, à Eléazar et à Ithamar: « Vous ne laisserez point flotter en désordre les cheveux de votre tête et vous ne déchirerez point vos vêtements, de peur que vous ne mouriez, et que Yahweh ne s’irrite contre toute l’assemblée. Que vos frères, toute la maison d’Israël, pleurent sur l’embrasement que Yahweh a allumé.
Mose sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yòókù, Eleasari àti Itamari pé, “ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ nípa ṣíṣe aláìtọ́jú irun yín tàbí kí ẹ ṣí orí yín sílẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ ya aṣọ, bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ ó kùú, Olúwa yóò sì bínú sí gbogbo ìjọ ènìyàn. Ṣùgbọ́n àwọn ẹbí yín, àti gbogbo ilé Israẹli le è ṣọ̀fọ̀ lórí àwọn tí Olúwa fi iná parun.
7 Pour vous, vous ne sortirez point de l’entrée de la tente de réunion, de peur que vous ne mouriez; car l’huile de l’onction de Yahweh est sur vous. » Ils firent ce que Moïse avait dit.
Ẹ má ṣe kúrò ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, bí ẹ bá kúrò níbẹ̀, ẹ ó kù ú, nítorí pé òróró ìtasórí Olúwa wà lórí yín.” Wọ́n sì ṣe bí Mose ti wí.
8 Yahweh parla à Aaron, en disant:
Olúwa sì sọ fún Aaroni pé.
9 « Tu ne boiras ni vin, ni boisson enivrante, toi et tes fils avec toi, lorsque vous entrerez dans la tente de réunion, afin que vous ne mouriez pas: c’est une loi perpétuelle parmi vos descendants,
“Ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀ kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle mìíràn nígbàkígbà tí ẹ bá n lọ inú àgọ́ ìpàdé, bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ ó kù ú, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún un yín láti ìrandíran.
10 et afin que vous sachiez discerner ce qui est saint de ce qui est profane, ce qui est pur de ce qui est impur,
Ẹ gbọdọ̀ mọ ìyàtọ̀ láàrín mímọ́ àti àìmọ́, láàrín èérí àti àìléèérí.
11 et afin que vous puissiez enseigner aux enfants d’Israël toutes les lois que Yahweh leur a données par Moïse. »
Ẹ gbọdọ̀ kọ́ àwọn ara Israẹli ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún wọn láti ẹnu Mose.”
12 Moïse dit à Aaron, à Eléazar et à Ithamar, les deux fils qui restaient à Aaron: « Prenez l’oblation qui reste des sacrifices faits par le feu à Yahweh, et mangez-la sans levain près de l’autel, car c’est une chose très sainte.
Mose sì sọ fún Aaroni, Eleasari àti Itamari àwọn ọmọ rẹ̀ yòókù pé, “Ẹ mú ẹbọ ohun jíjẹ tó ṣẹ́kù láti inú ẹbọ àfinásun sí Olúwa, kí ẹ jẹ ẹ́ láìní ìwúkàrà nínú, lẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ nítorí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
13 Vous la mangerez dans un lieu saint: c’est ton droit et le droit de tes fils sur les offrandes faites par le feu à Yahweh; c’est là ce qui m’a été ordonné.
Ẹ jẹ́ ní ibi mímọ́, nítorí pé òun ni ìpín rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ nínú ẹbọ tí a finá sun sí Olúwa nítorí pé bẹ́ẹ̀ ni mo ṣe pa á láṣẹ.
14 Vous mangerez aussi en lieu pur, toi, tes fils et tes filles avec toi, la poitrine qui aura été balancée et la cuisse qui aura été prélevée; car ces morceaux vous sont donnés comme ton droit et le droit de tes fils sur les sacrifices pacifiques des enfants d’Israël.
Ṣùgbọ́n ìwọ àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ le jẹ igẹ̀ ẹran tí a fì níwájú Olúwa àti itan tí wọ́n gbé síwájú Olúwa, kí ẹ jẹ wọ́n ní ibi tí a kà sí mímọ́, èyí ni a ti fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpín yín nínú ẹbọ àlàáfíà àwọn ara Israẹli.
15 Ils apporteront, outre les graisses destinées à être consumées par le feu, la cuisse que l’on prélève et la poitrine que l’on balance, pour qu’elles soient balancées devant Yahweh; elles seront pour toi et pour tes fils avec toi par une loi perpétuelle, comme Yahweh l’a ordonné. »
Itan tí wọ́n mú wá àti igẹ̀ ẹran tí ẹ fì ni ẹ gbọdọ̀ mú wá pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ tí a finá sun láti le è fì wọ́n níwájú Olúwa bí ẹbọ fífì. Èyí yóò sì jẹ́ ìpín tìrẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ nígbà gbogbo bí Olúwa ṣe pàṣẹ.”
16 Moïse s’enquit du bouc immolé pour le péché, et voici, il avait été brûlé. Alors, il s’irrita contre Eléazar et Ithamar, les fils qui restaient à Aaron, et il leur dit:
Nígbà tí Mose wádìí nípa ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tó sì rí i pé wọ́n ti sun ún, ó bínú sí Eleasari àti Itamari, àwọn ọmọ Aaroni yòókù, ó sì béèrè pé,
17 « Pourquoi n’avez-vous pas mangé la victime pour le péché dans le lieu saint? Car c’est une chose très sainte, et Yahweh vous l’a donnée, afin que vous portiez l’iniquité de l’assemblée, afin que vous fassiez pour elle l’expiation devant Yahweh.
“Èéṣe tí ẹ kò jẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ní agbègbè ibi mímọ́? Ó jẹ́ mímọ́ jùlọ, a fi fún yín láti lè mú ẹ̀ṣẹ̀ ìjọ ènìyàn kúrò nípa fífi ṣe ètùtù fún wọn níwájú Olúwa.
18 Voici, le sang de la victime n’a pas été porté dans l’intérieur du sanctuaire; vous deviez la manger dans un lieu saint, comme je l’ai commandé. »
Níwọ́n ìgbà tí ẹ kò mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wá sí Ibi Mímọ́, ẹ̀ bá ti jẹ ewúrẹ́ náà ní agbègbè Ibi Mímọ́ bí mo ṣe pa á láṣẹ.”
19 Aaron dit à Moïse: « Voici, ils ont offert aujourd’hui leur sacrifice pour le péché et leur holocauste devant Yahweh; mais, après ce qui m’est arrivé, si j’avais mangé aujourd’hui la victime pour le péché, cela eût-il été agréable aux yeux de Yahweh? »
Aaroni sì dá Mose lóhùn pé, “Lónìí tí wọ́n rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun wọn níwájú Olúwa ni irú èyí tún ṣẹlẹ̀ sí mi. Ǹjẹ́ inú Olúwa yóò wá dùn bí mo bá jẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ lónìí?”
20 Moïse, ayant entendu ces paroles, il les eut pour agréables.
Nígbà tí Mose gbọ́ èyí, ọkàn rẹ̀ balẹ̀.

< Lévitique 10 >