< Ézéchiel 4 >

1 Toi, fils de l’homme, prends une brique, pose-la devant toi, et tu y dessineras une ville, Jérusalem.
“Nísinsin yìí, ìwọ ọmọ ènìyàn, mú amọ̀ ṣíṣù kan, gbé e sí iwájú rẹ, kí o sì ya àwòrán ìlú Jerusalẹmu sí orí rẹ̀.
2 Mets le siège contre elle, construis contre elle une tour d’attaque, élève contre elle des terrasses: place contre elle des camps, et pose contre elle des béliers tout autour.
Kí o sì dó tì í, kí o sì mọ ilé ìṣọ́ tì í, kí o sì mọ odi tì í, kí o sì gbé ogun sí i, kí o sì to òòlù yí i ká.
3 Et toi, prends une poêle en fer et place-la comme un mur de fer entre toi et la ville, et dirige ta face contre elle; elle sera assiégée et tu l’assiégeras. Que ce soit un signe pour la maison d’Israël!
Kí o sì fi àwo irin kan ṣe ògiri láàrín rẹ̀ àti ìlú yìí, kí o sì kọjú sí i, a ó sì dó tì í, ìwọ yóò sì dó tì í. Èyí yóò jẹ́ àmì fún ilé Israẹli.
4 Et toi, couche-toi sur ton côté gauche, et mets-y l’iniquité de la maison d’Israël; et le nombre de jours que tu resteras ainsi couché, tu porteras leur iniquité.
“Lẹ́yìn èyí, lọ fi ẹ̀gbẹ́ òsì dùbúlẹ̀, kí o sì gbé ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli lé orí ara rẹ. Iye ọjọ́ tí ìwọ bá fi sùn náà ni ìwọ yóò fi ru ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
5 Et moi, je t’ai compté les années de leur iniquité selon le nombre de jours: durant trois cent quatre-vingt-dix jours, tu porteras l’iniquité de la maison d’Israël.
Nítorí mo fi iye ọdún tí wọ́n fi ṣẹ̀ fún ọ gẹ́gẹ́ bí iye ọjọ́ tí ìwọ yóò lò. Nítorí náà, ìwọ yóò ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
6 Et quand tu auras achevé ces jours, tu te coucheras sur ton côté droit une seconde fois, et tu porteras l’iniquité de la maison de Juda, quarante jours; je t’ai compté un jour pour une année.
“Tí o bá parí èyí, tún fi ẹ̀gbẹ́ ọ̀tún dùbúlẹ̀ kí o sì ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Juda fún ogójì ọjọ́, nítorí pé ọjọ́ kan ló dúró fún ọdún kan.
7 Et tu dirigeras ta face et ton bras nu contre Jérusalem assiégée, et tu prophétiseras contre elle.
Ìwọ dojúkọ ìgbógunti Jerusalẹmu, na ọwọ́ rẹ sí i, kí o sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìlú náà.
8 Et voici que j’ai mis sur toi des cordes, afin que tu ne puisses pas te tourner d’un côté sur l’autre, jusqu’à ce que tu aies accompli les jours de ton siège.
Èmi yóò dè ọ́ ní okùn dé bi pé ìwọ kò ní í le yírapadà láti ìhà ọ̀tún sí ìhà òsì títí tí ọjọ́ ìgbóguntì rẹ yóò fi pé.
9 Prends du froment, de l’orge, des fèves, des lentilles, du millet et de l’épeautre; mets-les dans un vase et fais-en du pain pour toi, selon le nombre de jours que tu seras couché sur ton côté; tu en mangeras trois cent quatre-vingt-dix jours.
“Mú alikama, ọkà bàbà àti barle, erèé àti lẹntili, jéró àti ẹwẹ; fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe àkàrà tí ìwọ yóò máa jẹ nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀ fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
10 Et la nourriture que tu mangeras sera du poids de vingt sicles par jour; tu en mangeras de temps en temps.
Wọn òsùwọ̀n ogún ṣékélì oúnjẹ tí ìwọ yóò máa jẹ lójoojúmọ́ kí o sì máa jẹ ẹ́ ní àkókò tí a ti yà sọ́tọ̀.
11 Tu boiras de l’eau par petite quantité, un sixième de hin; tu en boiras de temps en temps.
Bákan náà, wọn ìdámẹ́fà omi, kí ìwọ ó sì máa mú ní àkókò tí a yà sọ́tọ̀.
12 Tu mangeras cela sous la forme de galettes d’orge, et tu le feras cuire sous leurs yeux avec des excréments d’homme. »
Ìwọ yóò sì jẹ ẹ́ bí àkàrà barle; dín in ní ojú àwọn ènìyàn, ìgbẹ́ ènìyàn ni kí o fi dáná rẹ.”
13 Et Yahweh me dit: « C’est ainsi que les enfants d’Israël mangeront leur pain souillé chez les nations où je les chasserai. »
Olúwa sọ pé, “Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò jẹ oúnjẹ àìmọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí èmi yóò lé wọn lọ.”
14 Je dis: « Ah! Seigneur Yahweh, voici que mon âme n’a jamais été souillée; je n’ai pas mangé d’une bête morte ou déchirée depuis ma jeunesse jusqu’à présent, et aucune chair souillée n’est entrée dans ma bouche. »
Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Kò rí bẹ́ẹ̀ Olúwa Olódùmarè! Láti ìgbà èwe mi di ìsinsin yìí èmi kò tí ì sọ ara mi di aláìmọ́ rí. Èmi kò tí ì jẹ ohun tó kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí tí ẹranko búburú fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Bẹ́ẹ̀ ni ẹran àìmọ́ kan kò tí ì wọ ẹnu mi rí.”
15 Il me dit: « Vois, je t’accorde de la fiente de bétail au lieu d’excréments d’homme, et tu feras cuire ton pain dessus. »
Nígbà náà ló wí fún mi pé, “Wò ó, Èmi ó fún ọ ní ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn. Èmi yóò mú ki ó dín àkàrà rẹ lórí ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn.”
16 Et il me dit: « Fils de l’homme, voici que je vais briser le bâton du pain dans Jérusalem; ils mangeront du pain au poids et dans l’angoisse; ils boiront de l’eau à la mesure et dans l’épouvante.
Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, èmi yóò dáwọ́ ìpèsè oúnjẹ dúró ní Jerusalẹmu. Ní pípín ni àwọn ènìyàn yóò máa pín oúnjẹ jẹ pẹ̀lú ìfọkànsọ́nà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wọn yóò máa mu omi pẹ̀lú ìdààmú,
17 Car ils manqueront de pain et d’eau; ils dépériront les uns et les autres, et se consumeront à cause de leur iniquité.
nítorí pé oúnjẹ àti omi yóò wọ́n. Wọn yóò máa wo ara wọn pẹ̀lú ìyanu, èmi yóò sì jẹ́ kí wọ́n ṣọ̀fọ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

< Ézéchiel 4 >