< Ézéchiel 24 >
1 La parole de Yahweh me fut adressée la neuvième année, au dixième mois, le dix du mois, en ces termes:
Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 « Fils de l’homme, mets par écrit le nom de ce jour, de ce propre jour-ci: le roi de Babylone s’est jeté sur Jérusalem en ce jour même.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
3 Propose une parabole à la maison rebelle et dis-leur: Ainsi parle le Seigneur Yahweh: Dresse la chaudière, dresse- la et verses-y de l’eau.
Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
4 Amasses-y ses morceaux, tous les bons morceaux, la cuisse et l’épaule, remplis- la des meilleurs os.
Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
5 Prends ce qu’il y a de mieux dans le troupeau, entasse aussi les os sous la chaudière; fais-la bouillir à gros bouillons, et que les os qui sont dedans cuisent aussi.
mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
6 C’est pourquoi ainsi parle le Seigneur Yahweh: Malheur à la ville de sang, chaudière dans laquelle il y a du vert-de-gris, et de laquelle le vert-de-gris n’est pas sorti! Vide-la morceaux par morceaux, sans tirer au sort.
Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
7 Car le sang qu’elle a versé est au milieu d’elle; elle l’a mis sur la roche nue; elle ne l’a pas répandu sur la terre, pour le couvrir de poussière.
“‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
8 Afin d’exciter le courroux, afin de tirer vengeance, j’ai fait verser le sang qu’elle a répandu sur la roche nue, pour qu’il ne fût pas couvert.
Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
9 C’est pourquoi ainsi parle le Seigneur Yahweh: Malheur à la ville de sang! Moi aussi, je dresserai un grand monceau de bois.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
10 Amasse le bois, allume le feu, fais fondre la chair, fais bouillir la bouillie, et que les os soient consumés par le feu.
Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
11 Puis pose la chaudière vide sur ses charbons, afin qu’elle s’échauffe, que son airain s’embrase et que sa souillure se fonde au milieu d’elle, que son vert-de-gris soit consumé.
Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
12 Efforts inutiles! Sa masse de vert-de-gris ne s’en va pas, son vert-de-gris résiste au feu.
Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
13 Dans ta souillure il y a une énormité; puisque je t’ai purifiée et que tu n’es pas devenue pure, tu ne seras jamais plus purifiée de ta souillure, jusqu’à ce que j’aie fait reposer sur toi mon courroux.
“‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
14 Moi, Yahweh, j’ai parlé; cela arrivera et je le ferai; je ne lâcherai point, je n’épargnerai point, je ne me repentirai point. On te jugera selon tes voies, et selon tes forfaits, — oracle du Seigneur Yahweh. »
“‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 La parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
16 « Fils de l’homme, voici que je vais t’enlever par un coup soudain les délices de tes yeux; tu ne te lamenteras point, tu ne pleureras point, et tes larmes ne couleront pas.
“Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
17 Soupire en silence; ne fais pas le deuil des morts; ceins ta tête de ton turban et mets ta chaussure à tes pieds; ne te voile pas la barbe et ne mange pas le pain de consolation. »
Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
18 Je parlai au peuple le matin, et ma femme mourut le soir; le lendemain matin, je fis ce qui m’avait été ordonné.
Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
19 Et le peuple me dit: « Ne nous expliqueras-tu pas ce que signifie pour nous ce que tu fais là? »
Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
20 Je leur dis: « La parole de Yahweh m’a été adressée en ces termes:
Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
21 Dis à la maison d’Israël: Ainsi parle le Seigneur Yahweh: Voici que je vais profaner mon sanctuaire, l’orgueil de votre force, les délices de vos yeux et l’amour de vos âmes; et vos fils et vos filles que vous avez quittés tomberont par l’épée.
Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
22 Vous ferez alors ce que j’ai fait: vous ne vous couvrirez pas la barbe et vous ne mangerez pas le pain de consolation.
Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
23 Vos turbans resteront sur vos têtes et vos chaussures à vos pieds; vous ne vous lamenterez pas et vous ne pleurerez pas; mais vous vous consumerez dans vos iniquités, et vous gémirez l’un auprès de l’autre.
Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
24 Ézéchiel sera pour vous un emblème: selon tout ce qu’il a fait vous agirez, quand cela arrivera, et vous saurez que je suis le Seigneur Yahweh. »
Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
25 « Et toi, fils de l’homme, le jour où je leur ôterai ce qui fait leur force, leur gloire et leur joie, les délices de leurs yeux et le désir de leurs âmes, — leurs fils et leurs filles, —
“Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
26 en ce jour-là, un fugitif viendra vers toi pour en apporter la nouvelle.
ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
27 En ce jour-là, ta bouche s’ouvrira à l’ arrivée du fugitif; tu parleras et ne seras plus muet, et tu seras pour eux un emblème; ils sauront que je suis le Seigneur Yahweh. »
Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”