< Ézéchiel 21 >

1 Et la parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
2 " Fils de l'homme, tourne ta face vers Jérusalem, et fais découler ta parole vers les lieux saints, et prophétise contre la terre d'Israël.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli.
3 Dis à la terre d'Israël: Ainsi parle Yahweh: Voici que je viens à toi; je tirerai mon épée de son fourreau, et j'exterminerai de ton sein juste et méchant.
Kí ó sì sọ fún un pe, ‘Èyí yìí ni Olúwa wí, Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín.
4 Et parce que je vais exterminer de ton sein juste et méchant, à cause de cela, mon épée sortira de son fourreau contre toute chair, du midi au septentrion.
Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá.
5 Et toute chair saura que c'est moi, Yahweh, qui ai tiré mon épée du fourreau; elle n'y rentrera plus.
Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’
6 Et toi, fils de l'homme, gémis; jusqu'à te rompre les reins avec amertume, gémis devant eux.
“Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn.
7 Et quand ils te diront: pourquoi gémis-tu? Tu répondras: A cause d'une nouvelle qui arrive. Et tout cœur se fondra, toute main faiblira, tout esprit sera dans le trouble, tout genou s'en ira en eau. Voici qu'elle arrive; c'est fait, — oracle du Seigneur Yahweh. "
Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
8 Et la parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé:
9 " Fils de l'homme, prophétise et dis: Ainsi parle Yahweh: Dis: L'épée, l'épée est aiguisée et fourbie:
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, èyí yìí ní Olúwa wí pé, “‘Idà kan, idà kan, tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
10 c'est pour faire un massacre qu'elle est aiguisée, pour faire briller l'éclair qu'elle est fourbie. Ou bien nous réjouirons-nous en disant: " Le sceptre de mon fils méprise tout bois? "
a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀, a dán an láti máa kọ mọ̀nà! “‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.
11 On l'a donnée à fourbir pour qu'on la prenne en main; c'est une épée aiguisée, et elle est fourbie, pour qu'on la mette dans la main de l'égorgeur.
“‘Idà ní a yàn láti pọ́n, kí ó lè ṣe é gbámú; a pọ́n ọn, a sì dán an, ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
12 Crie et hurle, fils de l'homme, car elle est pour mon peuple, elle est pour tous les princes d'Israël. Ils sont livrés à l'épée avec mon peuple; frappe donc sur ta cuisse!
Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn, nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi; yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi nítorí idà náà; nítorí náà lu oókan àyà rẹ.
13 Car l'épreuve est faite: et quoi donc? Si ce sceptre continue de mépriser, mes menaces ne se réaliseraient pas, — oracle du Seigneur Yahweh!
“‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ń kọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’
14 Et toi, fils de l'homme, prophétise et frappe main contre main: Que l'épée double, triple ses coups! C'est l'épée du carnage, l'épée du grand carnage, qui les encercle.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́. Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì, kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
15 Pour que les cœurs se fondent, et pour multiplier les victimes, j'ai mis à toutes les portes l'épée meurtrière. Ah! elle est préparée pour lancer l'éclair, elle est aiguisée pour le carnage!
Kí ọkàn kí ó lè yọ́ kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀, mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun. Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná, a gbá a mú fún ìparun.
16 En position à droite! En place à gauche! Fais face de tous côtés.
Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún kí o sì jà sí òsì lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ.
17 Moi aussi, je frapperai main contre main; et j'assouvirai mon courroux. Moi, Yahweh, j'ai parlé. "
Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́ ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”
18 Et la parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
19 " Toi, fils de l'homme, trace deux chemins par où puisse aller l'épée du roi de Babylone; que tous deux partent du même pays, et grave un signe, grave-le à l'entrée du chemin d'une ville.
“Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe àmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà.
20 Tu traceras un chemin à l'épée pour aller à Rabbath, capitale des fils d'Ammon, ou en Juda, contre Jérusalem, ville forte.
La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi.
21 Car le roi de Babylone s'est arrêté au carrefour, à la tête des deux chemins, pour tirer des présages: il secoue les flèches, il interroge les théraphim, il examine le foie.
Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ. Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀.
22 Dans sa droite est le présage " Jérusalem ", pour dresser des béliers contre les murailles, pour ouvrir une entrée par une brèche, pour pousser à haute voix le cri de guerre, pour dresser des béliers contre les portes, pour élever des terrasses, pour construire des murs.
Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́.
23 A leurs yeux, ce n'est qu'une divination mensongère; ils ont pour eux les serments les plus sacrés; mais lui les fera souvenir de leurs iniquités lorsqu'ils seront pris.
Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí àmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.
24 C'est pourquoi ainsi parle le Seigneur Yahweh: Parce que vous avez rappelé votre iniquité en manifestant vos transgressions, en faisant voir vos péchés dans toutes vos actions, parce que vous vous êtes rappelés au souvenir, vous serez pris avec la main.
“Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.
25 Et toi, profane, méchant prince d'Israël, dont le jour est venu, maintenant que l'iniquité est à son terme,
“‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó,
26 ainsi parle le Seigneur Yahweh: La tiare va être ôtée et la couronne enlevée; tout sera bouleversé; ce qui est bas sera élevé, ce qui est haut sera abaissé.
èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀, ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.
27 J'en ferai une ruine, une ruine, une ruine; cela ne sera plus, jusqu'à ce que vienne celui à qui appartient le jugement et à qui je le remettrai.
Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’
28 Et toi, fils de l'homme, prophétise et dis: Ainsi parle le Seigneur Yahweh, contre les fils d'Ammon et au sujet de leurs outrages. Dis: L'épée, l'épée est tirée pour massacrer; elle est fourbie pour dévorer, pour lancer l'éclair.
“Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn: “‘Idà kan idà kan tí á fa yọ fún ìpànìyàn tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
29 — pendant qu'on a pour toi des visions vaines, et des présages menteurs, — pour te placer avec les cadavres des méchants livrés au glaive, dont le jour est venu au temps où l'iniquité est à son terme.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín a yóò gbé e lé àwọn ọrùn ènìyàn búburú ti a ó pa, àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé, àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
30 Rentre ton épée dans son fourreau; c'est dans le lieu ou tu as été créé, sur la terre où tu as pris naissance que je te jugerai.
“‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀. Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín, ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
31 Je répandrai sur toi mon courroux; avec le feu de ma fureur je soufflerai sur toi, et je te livrerai aux mains d'hommes insensés, à des artisans de destruction.
Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín, èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná mi bá yín jà.
32 Tu seras la pâture du feu, ton sang sera au milieu du pays, on ne se souviendra pas de toi; car moi, Yahweh, j'ai parlé. "
Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà, a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín, a kì yóò rántí yín mọ́; nítorí Èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’”

< Ézéchiel 21 >