< Ézéchiel 19 >

1 Et toi, prononce une lamentation sur les princes d’Israël, et dis:
“Kọ orin ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ-aládé Israẹli
2 « Pourquoi ta mère, comme une lionne, s’est-elle couchée entre des lions? Au milieu des jeunes lions elle a nourri ses petits.
wí pé: “‘Èwo nínú abo kìnnìún ni ìyá rẹ̀ ní àárín àwọn kìnnìún yòókù? Ó sùn ní àárín àwọn ọ̀dọ́ kìnnìún ó sì ń tọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
3 Elle éleva l’un de ses petits, et ce fut un jeune lion; il apprit à déchirer sa proie, il dévorait des hommes.
Ó sì tọ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ dàgbà, ó sì di kìnnìún tó ní agbára, ó kọ́ ọ láti ṣọdẹ, ó sì ń pa àwọn ènìyàn jẹ.
4 Les nations entendirent parler de lui; il fut pris dans leur fosse. Elles le conduisirent, avec des crochets aux mâchoires, au pays de l’Égypte.
Àwọn orílẹ̀-èdè gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì fi ẹ̀wọ̀n mú un nínú iho wọn. Wọn fi ẹ̀wọ̀n mu nu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
5 Et la lionne vit qu’elle attendait en vain, et que son espoir était perdu; elle prit un autre de ses petits, et en fit un lion.
“‘Nígbà tí abo kìnnìún yìí rí pé ìrètí rẹ̀ sì jásí asán, ó mú ọmọ rẹ̀ mìíràn ó sì tún tọ́ ọ dàgbà di kìnnìún tó ní agbára.
6 Il marcha au milieu des lions, et ce fut un jeune lion; il apprit à déchirer sa proie; il dévorait des hommes.
Ó sì ń rìn káàkiri láàrín àwọn kìnnìún nítorí pé ó ti lágbára, o kọ ọdẹ ṣíṣe, ó sì pa àwọn ènìyàn.
7 Il connut leurs veuves, et il ravagea leurs villes; le pays et ce qu’il contenait fut épouvanté du bruit de son rugissement.
Ó sì wó odi wọn palẹ̀ ó sì sọ àwọn ìlú wọn di ahoro. Ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé ibẹ̀ sì wà ní ìpayà nítorí bíbú ramúramù rẹ̀.
8 Alors les peuples des contrées d’alentour dressèrent contre lui et étendirent sur lui leurs filets, et il fut pris dans leur fosse.
Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè dìde sí i, àwọn tó yìí ká láti ìgbèríko wá. Wọn dẹ àwọ̀n wọn fún un, wọn sì mú nínú ihò wọn.
9 Ils le mirent dans une cage, avec des crochets aux mâchoires, et le conduisirent au roi de Babylone; et ils le conduisirent dans des forteresses, afin qu’on n’entendît plus sa voix sur les montagnes d’Israël.
Wọn fi ìwọ̀ gbé e sínú àgò, wọn mú un lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli, wọn fi sínú ìhámọ́, a kò sì gbọ́ bíbú rẹ̀ mọ́ lórí òkè Israẹli.
10 Ta mère était comme une vigne, au temps de ta prospérité; elle était plantée au bord des eaux; elle donna du fruit et poussa du feuillage, à cause des eaux abondantes.
“‘Ìyá rẹ dàbí àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ̀; tí á gbìn sí etí odò ó, kún fún èso, ó sì kún fún ẹ̀ka nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
11 Elle avait des branches vigoureuses, pour des sceptres de souverains, et sa taille était élevée parmi les rameaux touffus. Elle apparut dans sa grandeur, avec la multitude de ses sarments.
Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ lágbára tó láti fi ṣe ọ̀pá àṣẹ ìjòyè, ó ga sókè láàrín ewé rẹ̀, gíga rẹ̀ hàn jáde láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ka rẹ̀.
12 Mais elle a été arrachée avec fureur, et elle a été jetée par terre; et le vent d’orient a desséché son fruit. Ses branches vigoureuses ont été rompues et desséchées; le feu les a dévorées.
Ṣùgbọ́n ó fà á tu ní ìrunú, á sì wọ́ ọ lulẹ̀, afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn sì gbé èso rẹ̀, ọ̀pá líle rẹ̀ ti ṣẹ́, ó sì rọ iná sì jó wọn run.
13 Et maintenant, elle est plantée dans le désert, dans une terre sèche et aride.
Báyìí, a tún ún gbìn sínú aṣálẹ̀ ni ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tó ń pòǹgbẹ omi.
14 Un feu est sorti d’un de ses rameaux, il a dévoré son fruit; elle n’a plus de rameaux puissants, de sceptre pour dominer. » C’est là une lamentation, et elle deviendra une lamentation.
Iná sì jáde láti ọ̀kan lára ẹ̀ka rẹ̀ ó sì pa ẹ̀ka àti èso rẹ̀ run, dé bi pé kò sí ẹ̀ka tó lágbára lórí rẹ̀ mọ́; èyí to ṣe fi ṣe ọ̀pá fún olórí mọ́.’ Èyí ni orin ọ̀fọ̀ a o sì máa lo bí orin ọ̀fọ̀.”

< Ézéchiel 19 >