< Ézéchiel 14 >

1 Quelques-uns des anciens d’Israël vinrent auprès de moi et s’assirent devant moi.
Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
2 Et la parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
3 « Fils de l’homme, ces gens-là ont dressé dans leur cœur leurs infâmes idoles, et ils mettent devant leur face le scandale qui les fait pécher: me laisserai-je interroger par eux?
“Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
4 C’est pourquoi parle-leur et dis-leur: Ainsi parle le Seigneur Yahweh: Quiconque de la maison d’Israël dresse en son cœur ses infâmes idoles et met devant sa face le scandale qui le fait pécher, s’il vient vers le prophète, moi, Yahweh, je lui répondrai par moi-même, comme le mérite la multitude de ses idoles,
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
5 afin de prendre la maison d’Israël par son propre cœur, elle qui, avec toutes ses idoles infâmes, s’est détournée de moi.
Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
6 C’est pourquoi dis à la maison d’Israël: Ainsi parle le Seigneur Yahweh: Revenez et détournez-vous de vos idoles infâmes, et détournez votre face de toutes vos abominations.
“Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
7 Car quiconque de la maison d’Israël ou des étrangers séjournant en Israël se détourne de moi, dresse dans son cœur ses infâmes idoles et met devant sa face le scandale qui le fait pécher, s’il vient vers le prophète afin qu’il m’interroge pour lui, moi Yahweh je lui répondrai moi-même.
“‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
8 Je dirigerai ma face contre cet homme, je le détruirai pour faire de lui un signe et un proverbe; je le retrancherai du milieu de mon peuple, et vous saurez que je suis Yahweh.
Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
9 Et si le prophète se laisse séduire et qu’il prononce quelque parole, c’est moi, Yahweh, qui aurai séduit ce prophète; et j’étendrai ma main sur lui, et je l’exterminerai du milieu de mon peuple d’Israël.
“‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
10 Ils porteront ainsi la peine de leur iniquité, — telle l’iniquité de celui qui interroge, telle l’iniquité du prophète, —
Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
11 afin que la maison d’Israël ne s’égare plus loin de moi, et qu’elle ne se souille plus par toutes ses transgressions. Alors ils seront mon peuple, et moi je serai leur Dieu, — oracle du Seigneur Yahweh. »
Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
12 La parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
13 « Fils de l’homme, si un pays péchait contre moi par révolte, et si j’étendais ma main sur lui en brisant pour lui le bâton du pain, et si je lui envoyais la famine, en exterminant hommes et bêtes,
“Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
14 et qu’il y eut ces trois hommes au milieu de ce pays, Noé, Daniel et Job, … eux sauveraient leur âme par leur justice, — oracle du Seigneur Yahweh.
bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
15 Si je faisais passer dans le pays des bêtes malfaisantes, et qu’il fût dépeuplé, et qu’il devint un désert où personne ne passerait à cause des bêtes,
“Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
16 et qu’il y eût ces trois hommes au milieu de ce pays, je suis vivant, — oracle du Seigneur Yahweh: Ils ne sauveraient ni fils ni filles; eux seuls seraient sauvés, mais le pays serait dévasté.
bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
17 Ou si je faisais venir l’épée sur ce pays, et que je dise: Que l’épée passe sur le pays!… en exterminant hommes et bêtes,
“Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
18 et qu’il y eût ces trois hommes au milieu de ce pays, je suis vivant, — oracle du Seigneur Yahweh: Ils ne sauveraient ni fils, ni filles; eux seuls seraient sauvés.
Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
19 Ou si j’envoyais la peste sur ce pays, et que je répandisse sur lui mon courroux dans le sang, en exterminant hommes et bêtes,
“Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
20 et que Noé, Daniel et Job fussent au milieu de ce pays, je suis vivant, — oracle du Seigneur Yahweh: Ils ne sauveraient ni fils, ni filles, mais eux sauveraient leur âme par leur justice.
bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
21 Car ainsi parle le Seigneur Yahweh: Même quand j’aurai envoyé contre Jérusalem mes quatre châtiments terribles, l’épée, la famine, les bêtes malfaisantes et la peste, en exterminant hommes et bêtes,
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
22 voici qu’il y aura un reste qui échappera, qui sortira de la ville, des fils et des filles. Voici qu’ils viendront vers vous; vous verrez leur conduite et leurs œuvres, et vous vous consolerez du mal que j’aurai fait venir sur Jérusalem, de tout ce que j’aurai fait venir sur elle.
Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
23 Ils vous consoleront, quand vous verrez leur conduite et leurs œuvres, et vous saurez que ce n’est pas sans cause que j’aurai fait tout ce que je lui aurai fait, — oracle du Seigneur Yahweh. »
Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ézéchiel 14 >