< Amos 7 >

1 Ainsi me fit voir le Seigneur Yahweh, et voici qu’il formait des sauterelles, au commencement de la pousse des regains; c’était le regain après la coupe du roi.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Ó pèsè ọwọ́ eṣú lẹ́yìn ìgbà tí a kórè ìpín ọba, ní ìgbà ti èso ẹ̀ẹ̀kejì ń jáde bọ̀.
2 Quand elles eurent achevé de dévorer l’herbe de la terre, je dis: « Seigneur Yahweh, daignez pardonner! Comment Jacob tiendra-t-il? Car il est petit. »
Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè, mo bẹ̀ ọ́, dáríjì! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
3 Et Yahweh se repentit de cela: « Cela ne sera pas », dit Yahweh.
Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí kò ni ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.
4 Ainsi me fit voir le Seigneur Yahweh, et voici que le Seigneur Yahweh venait châtier par le feu, et le feu dévorait le grand abîme, et il dévorait la portion du Seigneur.
Èyí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Olúwa Olódùmarè ń pè fún ìdájọ́ pẹ̀lú iná; ó jó ọ̀gbun ńlá rún, ó sì jẹ ilẹ̀ run.
5 Et je dis: « Seigneur Yahweh, daignez cesser! Comment Jacob tiendra-t-il? Car il est petit. »
Nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè jọ̀wọ́ má ṣe ṣe é! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
6 Yahweh se repentit: « Cela non plus ne sera pas », dit le Seigneur Yahweh.
Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí náà kò ní ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
7 Ainsi me fit voir Yahweh, et voici que le Seigneur se tenait sur un mur vertical, et il avait dans sa main un fil à plomb.
Èyí ni ohun tí ó fihàn mí: Olúwa dúró ní ẹ̀gbẹ́ odi ti a fi okùn ìwọ̀n mọ́, ti òun ti okùn ìwọ̀n tí ó rún ni ọwọ́ rẹ̀.
8 Et Yahweh me dit: « Que vois-tu, Amos? » Je répondis: « Un fil à plomb. » Et le Seigneur me dit: « Voici que je mets le fil à plomb au milieu de mon peuple d’Israël; je ne lui pardonnerai pas plus longtemps.
Olúwa sì bi mi pé, “Amosi, kí ni ìwọ rí?” Mo dáhùn pé, “Okùn ìwọ̀n.” Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Wò ó, Èmí ń gbé okùn ìwọ̀n kalẹ̀ láàrín àwọn Israẹli ènìyàn mi; Èmi kì yóò sì tún kọjá lọ́dọ̀ wọn mọ́.
9 Les hauts lieux d’Isaac seront dévastés, et les sanctuaires d’Israël seront détruits, et je me lèverai contre la maison de Jéroboam, avec l’épée. »
“Ibi gíga Isaaki wọ̀n-ọn-nì yóò sì di ahoro àti ibi mímọ Israẹli wọ̀n-ọn-nì yóò di ahoro. Èmi yóò sì fi idà dìde sí ilé Jeroboamu.”
10 Et Amasias, prêtre de Béthel, envoya dire à Jéroboam, roi d’Israël: « Amos conspire contre toi au milieu de la maison d’Israël; le pays ne peut plus supporter toutes ses paroles.
Nígbà náà Amasiah àlùfáà Beteli ránṣẹ́ sí Jeroboamu ọba Israẹli, wí pé: “Amosi ti dìde láti dìtẹ̀ sí ọ ni àárín gbùngbùn Israẹli. Ilẹ̀ kò sì le gba gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀.
11 Car Amos a parlé ainsi: Jéroboam mourra par l’épée, et Israël sera emmené captif hors de son pays. »
Nítorí èyí ni ohun ti Amosi ń sọ: “‘Jeroboamu yóò ti ipa idà kú, lóòtítọ́ Israẹli yóò lọ sí ìgbèkùn, jìnnà kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
12 Et Amasias dit à Amos: « Voyant, va-t-en, fuis au pays de Juda, et manges-y ton pain; là tu prophétiseras.
Nígbà náà ni Amasiah sọ fún Amosi pé, “Lọ jáde, ìwọ aríran! Padà sí ilẹ̀ àwọn Juda. Kí o máa jẹun rẹ níbẹ̀, kí o sì máa sọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.
13 Mais ne continue pas de prophétiser à Béthel, car c’est un sanctuaire du roi, et c’est une maison royale ».
Má ṣe sọtẹ́lẹ̀ mọ ni Beteli nítorí ibi mímọ́ ọba ni àti ibi tẹmpili ìjọba rẹ̀.”
14 Amos répondit et dit à Amasias: « Je ne suis pas un prophète, je ne suis pas un fils de prophète; je suis bouvier et je cultive les sycomores.
Amosi dá Amasiah lóhùn pé, “Èmi kì í ṣe wòlíì tàbí àwọn ọmọ wòlíì, ṣùgbọ́n mo jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn, mo sì ń ṣe ìtọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ sikamore.
15 Et Yahweh m’a pris derrière le troupeau, et Yahweh m’a dit: Va, prophétise à mon peuple d’Israël.
Ṣùgbọ́n Olúwa mu mi bí mo ti ń tọ́ agbo ẹran lẹ́yìn, ó sì wí fun mi pé, ‘Lọ sọtẹ́lẹ̀ fun àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
16 Et maintenant, écoute la parole de Yahweh: Tu dis: Tu ne prophétiseras pas contre Israël, et tu ne parleras pas contre la maison d’Isaac!…
Nítorí náà nísinsin yìí, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Ìwọ wí pé, “‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí Israẹli, má sì ṣe wàásù sí ilé Isaaki.’
17 C’est pourquoi ainsi parle Yahweh: Ta femme sera prostituée dans la ville, tes fils et tes filles tomberont par l’épée, ta terre sera partagée au cordeau; et toi, tu mourras sur une terre impure, et Israël sera emmené captif hors de sa terre. »
“Nítorí náà, èyí ni ohun ti Olúwa wí: “‘Ìyàwó rẹ yóò di panṣágà ni ìlú, àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú. A ó fi okùn wọn ilẹ̀ rẹ, a ó sì pín in àti ìwọ pẹ̀lú yóò kú ni ilẹ̀ àìmọ́. Israẹli yóò sì lọ sí ìgbèkùn, kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”

< Amos 7 >