< Psaumes 37 >
1 De David. ALEPH. Ne t’irrite pas au sujet des méchants, ne porte pas envie à ceux qui font le mal.
Ti Dafidi. Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú, kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
2 Car, comme l’herbe, ils seront vite coupés; comme la verdure du gazon, ils se dessécheront.
nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko, wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.
3 Mets ta confiance en Yahweh, et fais le bien; habite le pays, et jouis de sa fidélité.
Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere; torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
4 Fais de Yahweh tes délices, et il te donnera ce que ton cœur désire.
Ṣe inú dídùn sí Olúwa; òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.
5 Remets ton sort à Yahweh et confie-toi en lui: il agira:
Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́; gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
6 il fera resplendir ta justice comme la lumière, et ton droit comme le soleil à son midi.
Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.
7 Tiens-toi en silence devant Yahweh, et espère en lui; ne t’irrite pas au sujet de celui qui prospère dans ses voies; de l’homme qui réussit en ses intrigues.
Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa, kí o sì fi sùúrù dúró dè é; má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn, nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.
8 Laisse la colère, abandonne la fureur; ne t’irrite pas, pour n’aboutir qu’au mal.
Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀, má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
9 Car les méchants seront retranchés, mais ceux qui espèrent en Yahweh posséderont le pays.
Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò, ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.
10 Encore un peu de temps, et le méchant n’est plus; tu regardes sa place, et il a disparu.
Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀; nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
11 Mais les doux posséderont la terre, ils goûteront les délices d’une paix profonde.
Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà, wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.
12 Le méchant forme des projets contre le juste, il grince les dents contre lui.
Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́, wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
13 Le Seigneur se rit du méchant, car il voit que son jour arrive.
ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú, nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.
14 Les méchants tirent le glaive, ils bandent leur arc; pour abattre le malheureux et le pauvre, pour égorger ceux dont la voie est droite.
Ènìyàn búburú fa idà yọ, wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn, láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀, láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
15 Leur glaive entrera dans leur propre cœur, et leurs arcs se briseront.
Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ, àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.
16 Mieux vaut le peu du juste, que l’abondance de nombreux méchants;
Ohun díẹ̀ tí olódodo ní, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
17 car les bras des méchants seront brisés, et Yahweh soutient les justes.
nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.
18 Yahweh connaît les jours des hommes intègres, et leur héritage dure à jamais.
Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin, àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé.
19 Ils ne sont pas confondus au jour du malheur, et ils sont rassasiés aux jours de la famine.
Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi, àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.
20 Car les méchants périssent; les ennemis de Yahweh sont comme la gloire des prairies; ils s’évanouissent en fumée, ils s’évanouissent.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé. Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù; wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.
21 Le méchant emprunte, et il ne rend pas; Le juste est compatissant, et il donne.
Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
22 Car ceux que bénit Yahweh possèdent le pays, et ceux qu’il maudit sont retranchés.
nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà, àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.
23 Yahweh affermit les pas de l’homme juste, et il prend plaisir à sa voie.
Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
24 S’il tombe, il n’est pas étendu par terre, car Yahweh soutient sa main.
bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá, nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.
25 J’ai été jeune, me voilà vieux, et je n’ai pas vu le juste abandonné; ni sa postérité mendiant son pain.
Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà; síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀, tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
26 Toujours il est compatissant, et il prête, et sa postérité est en bénédiction.
Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni; a sì máa bùsi i fún ni.
27 Détourne-toi du mal et fais le bien; et habite à jamais ta demeure.
Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere; nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
28 Car Yahweh aime la justice, et il n’abandonne pas ses fidèles. Ils sont toujours sous sa garde, mais la postérité des méchants sera retranchée.
Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́, kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
29 Les justes posséderont le pays, et ils y habiteront à jamais.
Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà, yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
30 La bouche du juste annonce la sagesse, et sa langue proclame la justice.
Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
31 La loi de son Dieu est dans son cœur; ses pas ne chancellent point.
Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn; àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
32 Le méchant épie le juste, et il cherche à le faire mourir.
Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo, Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
33 Yahweh ne l’abandonne pas entre ses mains, et il ne le condamne pas quand vient son jugement.
Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi, nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
34 Attends Yahweh et garde sa voie, et il t’élèvera et tu posséderas le pays; quand les méchants seront retranchés, tu le verras.
Dúró de Olúwa, kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́. Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà; nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.
35 J’ai vu l’impie au comble de la puissance; il s’étendait comme un arbre verdoyant.
Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà, ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
36 J’ai passé, et voici qu’il n’était plus; je l’ai cherché, et on ne l’a plus trouvé.
ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́; bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.
37 Observe celui qui est intègre, et regarde celui qui est droit; car il y a une postérité pour l’homme de paix.
Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin; nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
38 Mais les rebelles seront tous anéantis, la postérité des méchants sera retranchée.
Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀; ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.
39 De Yahweh vient le salut des justes; il est leur protecteur au temps de la détresse.
Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
40 Yahweh leur vient en aide et les délivre; il les délivre des méchants et les sauve, parce qu’ils ont mis en lui leur confiance.
Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n; yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.