< Ézéchiel 30 >
1 La parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
2 « Fils de l’homme prophétise et dis: Ainsi parle le Seigneur Yahweh: Hurlez! Ah! ce jour!
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
3 Car le jour est proche, le jour est proche pour Yahweh! Jour de nuage! Ce sera le temps des nations!
Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
4 Une épée viendra sur l’Égypte, et il y aura de l’angoisse en Ethiopie, lorsque les blessés à mort tomberont en Égypte, quand on enlèvera ses richesses, et qu’on renversera ses fondements.
Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
5 Ethiopiens, Libyens et Lydiens, étrangers de toutes sortes, Chub et les fils du pays de l’alliance tomberont avec eux par l’épée.
Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
6 Ainsi parle Yahweh: ils tomberont les soutiens de l’Égypte, et l’orgueil de sa force sera abaissé. De Migdol à Syène on y tombera par l’épée; — oracle du Seigneur Yahweh.
“‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
7 Elle sera désolée au milieu des pays désolés, et ses villes seront ruinées au milieu des villes ruinées;
Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
8 et l’on saura que je suis Yahweh, quand je mettrai le feu à l’Égypte et que tous ses auxiliaires seront brisés.
Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
9 En ce jour-là, des messagers s’en iront de ma part sur des barques, pour troubler l’Ethiopie dans sa sécurité, et il y aura chez elle de l’angoisse, comme dans le jour de l’Égypte, car voici qu’il arrive!
“‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
10 Ainsi parle le Seigneur Yahweh: je ferai cesser tout le bruit de l’Égypte, par la main de Nabuchodonosor, roi de Babylone.
“‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
11 Lui et son peuple avec lui, nation féroce entre toutes, seront amenés pour ravager le pays; ils tireront leurs épées contre l’Égypte, et rempliront de morts le pays.
Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
12 Je changerai les fleuves en lieux arides; je livrerai le pays aux mains d’hommes méchants, et je dévasterai le pays et tout ce qu’il contient, par la main des étrangers. Moi, Yahweh, j’ai parlé.
Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
13 Ainsi parle le Seigneur Yahweh: J’exterminerai les infâmes idoles, et je ferai disparaître de Noph les faux dieux, et il n’y aura plus de prince sorti du pays d’Égypte, et je répandrai la crainte dans le pays d’Égypte.
“‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
14 Je désolerai Pathros, je mettrai le feu à Tsoan, j’exercerai des jugements sur No;
Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
15 je répandrai mon courroux sur Sin, la forteresse de l’Égypte, et j’exterminerai la multitude de No.
Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
16 Je mettrai le feu à l’Égypte; Sin se tordra de douleur, No sera forcée, et Noph se verra assaillie en plein jour.
Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
17 Les jeunes hommes d’Aven et de Bubaste tomberont par l’épée, et elles-mêmes iront en captivité.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
18 A Taphnés le jour s’obscurcira, quand je briserai là le joug de l’Égypte, et que l’orgueil de sa force y prendra fin. Un nuage la couvrira, et ses filles iront en captivité.
Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
19 J’exercerai des jugements sur l’Égypte, et l’on saura que je suis Yahweh. »
Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
20 La onzième année, au premier mois, le sept du mois, la parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
21 « Fils de l’homme, le bras de Pharaon, roi d’Égypte, je l’ai brisé, et voici qu’on ne l’a pas pansé, en employant des remèdes, en appliquant des bandes, pour le panser et le rendre assez fort pour manier l’épée.
“Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
22 C’est pourquoi ainsi parle le Seigneur Yahweh: Voici que je viens à Pharaon, roi d’Égypte; je lui briserai les deux bras, celui qui est valide et celui qui est déjà brisé, et je ferai tomber l’épée de sa main.
Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
23 Je disperserai les Egyptiens parmi les nations, et les disséminerai dans les pays.
Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
24 Je fortifierai les bras du roi de Babylone; et je mettrai mon épée dans sa main; je briserai les bras de Pharaon, et il gémira devant lui, comme gémit un homme blessé à mort.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
25 Je fortifierai les bras du roi de Babylone, et les bras de Pharaon tomberont. Et l’on saura que je suis Yahweh, quand je mettrai mon épée dans la main du roi de Bablylone, et qu’il la tournera contre le pays d’Égypte.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
26 Je disperserai les Egyptiens parmi les nations, et je les disséminerai dans les pays, et l’on saura que je suis Yahweh. »
Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”